ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 7 ojú ìwé 24-ojú ìwé 25 ìpínrọ̀ 1
  • Ilé Gogoro Bábélì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ilé Gogoro Bábélì
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Èèyàn Kọ́ Ilé Gogoro
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Ṣé “Ilé Gogoro Bábélì” Ni Èdè Wa Ti Bẹ̀rẹ̀?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Nóà Kan Áàkì
    Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Wọn Kò Ṣe Orúkọ Lílókìkí fún Ara Wọn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 7 ojú ìwé 24-ojú ìwé 25 ìpínrọ̀ 1
Lẹ́yìn tí Jèhófà da èdè wọn rú, àwọn èèyàn ò lè ṣiṣẹ́ pọ̀ láti kọ́ Ilé Gogoro Bábélì mọ́

Ẹ̀KỌ́ 7

Ilé Gogoro Bábélì

Lẹ́yìn tí Ọlọ́run fi omi pa àwọn èèyàn búburú run, àwọn ọmọ Nóà bẹ̀rẹ̀ sí í bímọ, àwọn ọmọ wọn sì pọ̀ gan-an. Bí wọ́n ṣe ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń tàn káàkiri ayé. Ohun tí Jèhófà sì fẹ́ kí wọ́n ṣe nìyẹn.

Ṣùgbọ́n, àwọn kan wà lára àwọn èèyàn náà tí kò ṣègbọràn sí Jèhófà. Wọ́n sọ pé: ‘Ẹ jẹ́ ká kọ́ ìlú ńlá kan síbí, ká sì máa gbé ibẹ̀. A máa kọ́ ilé gogoro kan, tó máa ga gan-an tí orí ẹ̀ sì máa kan ọ̀run. Tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn èèyàn á mọ̀ wá níbi gbogbo.’

Bí wọ́n ṣe bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́lé nìyẹn, àmọ́ inú Jèhófà ò dùn sóhun táwọn èèyàn yẹn ń ṣe, torí náà Jèhófà dá iṣẹ́ yẹn dúró. Ǹjẹ́ o mọ ohun tí Jèhófà ṣe fún wọn? Jèhófà mú kí wọ́n máa sọ èdè ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Lójijì, nǹkan yí pa dà, wọn ò gbọ́ èdè ara wọn mọ́, bó ṣe di pé wọn ò lè kọ́ ilé náà mọ́ nìyẹn. Orúkọ ìlú tí wọ́n ń kọ́ nígbà yẹn la wá mọ̀ sí Bábélì, tó túmọ̀ sí “Ìdàrúdàpọ̀.” Àwọn èèyàn náà tú ká, wọ́n sì lọ ń gbé níbi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ káàkiri ayé. Àmọ́, ìwà burúkú tó ti mọ́ wọn lára náà ni wọ́n ń hù ní gbogbo ibi tí wọ́n lọ. Ṣé gbogbo èèyàn tó wà láyé nígbà yẹn ló ń hùwà burúkú àbí àwọn kan wà tó ń ṣe ìfẹ́ Jèhófà? Inú orí tó kàn la ti máa mọ̀.

“Gbogbo ẹni tó bá gbé ara rẹ̀ ga, a máa rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀, àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, a máa gbé e ga.”​—Lúùkù 18:14

Ìbéèrè: Kí làwọn èèyàn tó ń gbé ní Bábélì ṣe? Báwo ni Jèhófà ṣe dá iṣẹ́ yẹn dúró?

Jẹ́nẹ́sísì 11:1-9

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́