ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 82 ojú ìwé 192-ojú ìwé 193 ìpínrọ̀ 2
  • Jésù Kọ́ Àwọn Ọmọ Ẹ̀yìn Ẹ̀ Bí Wọ́n Á Ṣe Máa Gbàdúrà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jésù Kọ́ Àwọn Ọmọ Ẹ̀yìn Ẹ̀ Bí Wọ́n Á Ṣe Máa Gbàdúrà
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Nípa Àwọn Àdúrà Tí Ọlọ́run Ń Gbọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Àǹfààní Pàtàkì Ni Àdúrà Jẹ́
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Ṣé Jésù Ló Yẹ Ká Máa Gbàdúrà Sí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Máa Gbàdúrà Kó O Lè Túbọ̀ Sún Mọ́ Ọlọ́run
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 82 ojú ìwé 192-ojú ìwé 193 ìpínrọ̀ 2
Farisí kan ń gbàdúrà níta gbangba, àwọn èèyàn sì ń wò ó

Ẹ̀KỌ́ 82

Jésù Kọ́ Àwọn Ọmọ Ẹ̀yìn Ẹ̀ Bí Wọ́n Á Ṣe Máa Gbàdúrà

Àwọn Farisí máa ń ṣe nǹkan torí káwọn èèyàn lè máa yìn wọ́n. Tí wọ́n bá ṣoore fáwọn èèyàn, ojú ayé lásán ni. Kódà, wọ́n tún máa ń gbàdúrà níta gbangba. Yàtọ̀ síyẹn, wọ́n máa ń há àwọn àdúrà tó gùn sórí, wọ́n á wá máa gba àdúrà yẹn sókè lójú ọ̀nà àti nínú sínágọ́gù. Ìdí nìyẹn tẹ́nu fi ya àwọn èèyàn nígbà tí Jésù sọ fún wọn pé: ‘Ẹ má ṣe gbàdúrà bí àwọn Farisí. Wọ́n rò pé Ọlọ́run á gbọ́ àdúrà wọn torí bí wọ́n ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ tó pọ̀, àmọ́ ọ̀rọ̀ ò rí bẹ́ẹ̀. Tó o bá ń gbàdúrà, Jèhófà lò ń bá sọ̀rọ̀, kì í ṣe èèyàn. Má ṣe máa sọ ohun kan náà ṣáá tó o bá ń gbàdúrà. Ohun tí Jèhófà fẹ́ ni pé kó o sọ ohun tó wà lọ́kàn ẹ gangan.’

Ọmọkùnrin kan kúnlẹ̀, ó sì ń gbàdúrà

Jésù wá sọ pé, ‘Bó ṣe yẹ kẹ́ ẹ máa gbàdúrà nìyí: “Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí orúkọ rẹ di mímọ́. Kí Ìjọba rẹ dé. Kí ìfẹ́ rẹ ṣẹ ní ayé, bíi ti ọ̀run.” ’ Jésù tún sọ fún wọn pé kí wọ́n máa gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wọn lóúnjẹ tí wọ́n máa jẹ ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan, pé kí Jèhófà dárí jì wọ́n, kó sì fún wọn láwọn nǹkan míì.

Jésù sọ pé: ‘Ẹ má ṣe dákẹ́ àdúrà. Gbogbo ìgbà ni kẹ́ ẹ máa bẹ Jèhófà Bàbá yín pé kó fún yín láwọn nǹkan rere. Gbogbo òbí ló máa ń fẹ́ fún àwọn ọmọ wọn lóhun tó dáa. Torí náà, tọ́mọ ẹ bá ní kó o fún òun ní búrẹ́dì, ṣé wàá fún un ní òkúta? Àbí tó bá ní kó o fún òun ní ẹja, ṣé wàá fún un ní ejò?’

Jésù wá sọ ẹ̀kọ́ tó fẹ́ kí wọ́n kọ́, ó ní: ‘Tẹ́ ẹ bá mọ bẹ́ ẹ ṣe ń fún àwọn ọmọ yín lẹ́bùn rere, ṣẹ́ ẹ wá rò pé Jèhófà, Bàbá yín tó wà lọ́run ò ní fún yín ní ẹ̀mí mímọ́ tẹ́ ẹ bá ní kó fún yín? Tiyín ni pé kẹ́ ẹ ṣáà ti béèrè lọ́wọ́ ẹ̀.’ Ṣó o máa ń tẹ̀ lé ìmọ̀ràn Jésù? Àwọn nǹkan wo lo máa ń gbàdúrà pé kí Jèhófà ṣe fún ẹ?

“Ẹ máa béèrè, a sì máa fún yín; ẹ máa wá kiri, ẹ sì máa rí; ẹ máa kan ilẹ̀kùn, a sì máa ṣí i fún yín.”​—Mátíù 7:7

Ìbéèrè: Báwo ni Jésù ṣe ní káwọn ọmọ ẹ̀yìn òun máa gbàdúrà? Ṣó o máa ń gbàdúrà nípa àwọn nǹkan tó ṣe pàtàkì sí ẹ?

Mátíù 6:2-18; 7:7-11; Lúùkù 11:13

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́