ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w94 11/1 ojú ìwé 28-31
  • Bí A Ṣe Lè Ṣètò Àkójọ-Ìwé Ti Ìṣàkóso Ọlọrun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bí A Ṣe Lè Ṣètò Àkójọ-Ìwé Ti Ìṣàkóso Ọlọrun
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Àkójọ-Ìwé kan Kìí Ṣe Ọ̀ṣọ́ Àfitolé”
  • Àwọn Ìwé Wo Ni Mo Nílò?
  • Ṣètò Àkójọ-Ìwé Rẹ!
  • Àkójọ-Ìwé kan Lè Ṣèrànwọ́ Láti Gbé Ipò Tẹ̀mí Ró
  • Báwo Ni Ibi Ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba Ṣe Ń Ṣe Wá Láǹfààní?
    Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
  • Àpótí Ìbéèrè
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Ìṣètò Tuntun fún Àwọn Ibi Ìkówèésí Tó Wà Nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Máa Lo Àwọ́n Ìtẹ̀jáde Tí Ọjọ́ Wọn Ti Pẹ́ Tí Ìjọ Ní Lọ́wọ́
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
Àwọn Míì
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
w94 11/1 ojú ìwé 28-31

Bí A Ṣe Lè Ṣètò Àkójọ-Ìwé Ti Ìṣàkóso Ọlọrun

SHEREZADE, ọmọdébìnrin kékeré kan tí ó lóye tí ó sì jẹ́ ọmọ ilẹ̀ Spania, jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rin nígbà tí olùkọ́ rẹ̀ sọ fún kíláàsì pé wọn yóò kún àwọn àwòrán “Bàbá Kérésìmesì.” Ní kíámọ́sá, Sherezade sọ pé kí a yọ̀ọ̀da òun. Ó ṣàlàyé pé ẹ̀rí-ọkàn òun kí yóò yọ̀ọ̀da fún òun láti ṣe bẹ́ẹ̀.

Bí ìkọ̀jálẹ̀ yìí ti yà á lẹ́nu, olùkọ́ náà sọ fún un pé ṣe ni ó wulẹ̀ dàbí kíkun àwòrán ọmọlangidi kan àti pé kò sí ohun tí ó burú nínú ìyẹn. Sherezade fèsì pé: “Bí ó bá jẹ́ pé ọmọlangidi kan lásán ni, èmi yóò kúkú yàn láti ya ọmọlangidi kan fúnraami bí ẹ bá gbà bẹ́ẹ̀.”

Ní àkókò mìíràn a sọ fún kíláàsì náà láti kun àsíá orílẹ̀-èdè. Lẹ́ẹ̀kan síi Sherezade béèrè bí ohun bá lè ṣe ohun mìíràn tí ó yàtọ̀. Gẹ́gẹ́ bí àlàyé, ó sọ ìtàn Ṣadraki, Meṣaki, àti Abednego fún olùkọ́ náà.​—⁠Danieli 3:​1-⁠28.

Láìpẹ́ lẹ́yìn náà olùkọ́ náà késí ìyá Sherezade lórí tẹlifóònù láti sọ fún un nípa ìyàlẹ́nu tí ó ní. Ó wí pé: “Ní ọ̀pọ̀ ìgbà ni ọmọbìnrin rẹ ti ń sọ fún mi nípa ẹ̀rí-ọkàn rẹ̀. Ìwọ ha lè fojú-inú wo ìyẹn bí? Ọmọdébìnrin kan ní iye ọjọ́-orí yẹn tí ń ṣàlàyé fún mi nípa ìdí ti ẹ̀rí-ọkàn òun fi ń da òun láàmú! Ṣe ó ríi, èmi kò faramọ́ ohun tí o fi ń kọ́ ọ, ṣùgbọ́n mo mú un dá ọ́ lójú pé o ti ń kẹ́sẹjárí. Mo sì fẹ́ kí o mọ̀ pé mo gbóṣùbà fún ọmọbìnrin rẹ.”

Báwo ni ọmọdébìnrin ọlọ́dún-mẹ́rin ṣe lè jèrè ẹ̀rí-ọkàn kan tí a fi Bibeli kọ́? Ìyá rẹ̀, Marina, ṣàlàyé pé Sherezade ní àkójọ-ìwé tirẹ̀ nínú iyàrá tirẹ̀. Àkójọ-ìwé náà ni ẹ̀dà Ilé-Ìṣọ́nà tirẹ̀ nínú, tí ó ti fa ìlà sí nídìí, ìwé-ìkẹ́kọ̀ọ́ tirẹ̀ fún wíwàásù, àti gbogbo ìtẹ̀jáde Watchtower Society tí a ti mújáde láti ìgbà tí a ti bí i. Ohun àyànláàyò jùlọ tí ó wà nínú ibi àkójọ-ìwé rẹ̀ ni téèpù àgbohùnsí ti Iwe Itan Bibeli Mi, tí ó máa ń tẹ́tísí ní alaalẹ́ bí ó ti ń fojú bá a nìṣó nínú ẹ̀dà tirẹ̀. Ìròyìn ìṣẹ̀lẹ̀ inú Bibeli yìí ni ó ti mú kí ó ṣeéṣe fún un láti ṣe àwọn ìpinnu tí a mẹ́nukàn lókè.

Àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun tí ó wà létòlétò dáradára ha lè ran ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ lọ́wọ́ bí? Èéṣe ti ibi àkójọ-ìwé kan nínú ilé fi pọndandan?

“Àkójọ-Ìwé kan Kìí Ṣe Ọ̀ṣọ́ Àfitolé”

Henry Ward Beecher sọ pé, “Àkójọ-ìwé kan kìí ṣe ọ̀ṣọ́ àfitolé, bíkòṣe ọ̀kan lára àwọn ohun kòṣeémánìí nínú ìgbésí-ayé.” Láìsí iyèméjì, ó fẹ́rẹ̀ jẹ́ pé gbogbo wa ni a ní ọ̀kan lára “àwọn ohun kòṣeémánìí nínú ìgbésí-ayé” wọ̀nyí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a lè má mọ̀. Báwo ni ó ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀? Nítorí pé bí gbogbo ohun tí a ní kò bá ju Bibeli lọ, a ti ní oríṣi àkójọ-ìwé kan.

Níti tòótọ́ ni Bibeli jẹ́ àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun tí ó dára jùlọ. Ní ọ̀rúndún kẹrin, Jerome hùmọ̀ àpólà-ọ̀rọ̀ Latin náà Bibliotheca Divina (Àkójọ-Ìwé Àtọ̀runwá) láti ṣàpèjúwe gbogbo àkópọ̀ àwọn ìwé onímìísí tí a ń pè ní Bibeli. Jehofa pèsè àkójọ-ìwé mímọ́-ọlọ́wọ̀ yìí fún wa láti fún wa ní ìrànlọ́wọ́, ìtọ́ni, àti ìtọ́sọ́nà gbígbéṣẹ́. Ó jẹ́ ohun kan tí a kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ dẹngbẹrẹ mú. Wíwulẹ̀ ní odidi Bibeli lọ́wọ́ túmọ̀sí pé a ní àkójọ-ìwé kan tí ó gbòòrò ju èyí tí ọ̀pọ̀ jùlọ lára àwọn ìránṣẹ́ Ọlọrun ní ní àwọn ìgbà àtijọ́.

Nígbà tí ó jẹ́ pé kìkì àwọn ìwé-àfọwọ́kọ gbígbówólórí ni ó ṣì wà lárọ̀ọ́wọ́tó, ìwọ̀nba àwọn ilé àdáni, bí ó bá wà rárá, ni a ti lè rí odidi Bibeli. Nígbà tí Paulu fẹ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Mímọ́ nígbà ìfisẹ́wọ̀n rẹ̀ tí ó gbẹ̀yìn ní Romu, ó níláti sọ pé kí Timoteu kó àwọn àkájọ-ìwé díẹ̀ wá fún òun láti Asia Minor​—⁠bóyá ó ṣeéṣe kí ó jẹ́ apákan àwọn Ìwé Mímọ́ Lédè Heberu. (2 Timoteu 4:13) Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn sinagọgu máa ń ní ìkójọpọ̀ àwọn àkájọ-ìwé, Jesu Kristi àti aposteli Paulu sì ló àǹfààní àwọn àkójọ-ìwé wọ̀nyí nínú iṣẹ́ ìwàásù wọn. (Luku 4:​15-⁠17; Iṣe 17:​1-⁠3) A láyọ̀ pé, Ìwé Mímọ́ ti túbọ̀ wà lárọ̀ọ́wọ́tó nísinsìnyí ju bí ó ti rí ní ọ̀rúndún kìn-⁠ín-ní lọ.

Ọpẹ́lọpẹ́ ìhùmọ̀ ẹ̀rọ ìtẹ̀wé, lónìí ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo àwọn ìránṣẹ́ Ọlọrun​—⁠ohun yòówù kí èdè wọn jẹ́⁠—​lè rí odidi Bibeli rà ní iye owó tí ó mọníwọ̀n. Àwa pẹ̀lú ní àǹfààní aláìlẹ́gbẹ́ ti fífikún “àkójọ-ìwé” mímọ́-ọlọ́wọ̀ yìí. Fún ohun tí ó ti ju ọ̀rúndún kan lọ báyìí, “olùṣòtítọ́ ati ọlọ́gbọ́n-inú ẹrú” náà ti ń pèsè oúnjẹ tẹ̀mí ní àkókò tí ó bẹ́tọ̀ọ́mu.​—⁠Matteu 24:​45-⁠47, NW.

Ṣùgbọ́n kò dàbí ẹni pé àwa yóò lo àǹfààní ṣíṣeyebíye yìí ní kíkún bí a kò bá ṣètò àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun kan tí ó jẹ́ tiwa. Báwo ni a ṣe lè ṣe ìyẹn? Ìgbésẹ̀ àkọ́kọ́, gẹ́gẹ́ bi a ti lè retí, ni láti ní àwọn ìwé tí ó yẹ kí ó wà nínú irúfẹ́ àkójọ-ìwé bẹ́ẹ̀. Ó yẹ gidigidi fún ìsapá náà, níwọ̀n bí yóò ti mú kí ó ṣeéṣe fún wa láti ní àwọn ìsọfúnni pàtó tí a nílò lárọ̀ọ́wọ́tó láti bójútó àwọn ìṣòro kí a sì dáhùn àwọn ìbéèrè Bibeli.

Àwọn Ìwé Wo Ni Mo Nílò?

Ó ha ti ṣe kàyéfì rí nípa bí o ṣe lè yanjú ìṣòro ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ nínú ìgbéyàwó rẹ tàbí bí o ṣe lè ran àwọn ọmọ rẹ lọ́wọ́ láti sọ pé bẹ́ẹ̀kọ́ sí lílo oògùn ní ìlòkulò? Báwo ni o ṣe lè ran ọ̀rẹ́ kan tí ń jìyà ìsoríkọ́ lọ́wọ́? O ha lè ṣàlàyé ẹ̀rí tí a ní pé Ọlọrun wà àti ìdí tí ó fi fàyègba ìwà-burúkú ní kedere bí? Kí ni ẹranko aláwọ̀ rírẹ̀dòdò inú ìwé Ìṣípayá orí 17 dúró fún?

Ìwọ̀nyí àti àìníye àwọn ìbéèrè mìíràn ni o lè dáhùn bí o bá ní àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun tí ó péye tó. Watchtower Society ti tẹ àwọn ìwé, àwọn ìwé-pẹlẹbẹ, àti àwọn ọ̀rọ̀-ẹ̀kọ́ ìwé ìròyìn tí ó jíròrò ẹ̀kúnwọ́ àwọn kókó ẹ̀kọ́ inú Ìwé Mímọ́. Síwájú síi, àwọn ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ wọ̀nyí ń jíròrò àwọn ọ̀ràn ìdílé, wọ́n ń gbé ìgbàgbọ́ wa ró nínú Ọlọrun àti Bibeli, wọ́n ń mú kí ó ṣeéṣe fún wa láti mú òye ìwàásù wa sunwọ̀n síi, wọ́n sì ń ràn wá lọ́wọ́ láti lóye àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bibeli.

Ọ̀pọ̀ jùlọ lára àwọn ìtẹ̀jáde náà ti Society tẹ̀ ní 20 ọdún tí ó ti kọjá sẹ́yìn ṣì wà lárọ̀ọ́wọ́tó. Bí o bá ṣẹ̀ṣẹ̀ wà sínú òtítọ́ ní lọ́ọ́lọ́ọ́ yìí, yóò jẹ́ ohun tí ó yẹ fún ọ láti ra gbogbo irú àwọn ìwé bẹ́ẹ̀ tí ó bá wà lárọ̀ọ́wọ́tó ní èdè rẹ. Ó lè jẹ́ pé àwọn ìdìpọ̀ Ilé-Ìṣọ́nà ti àwọn ọdún tí ó ti kọjá wà lárọ̀ọ́wọ́tó ní èdè rẹ. Àwọn ìwé ìtọ́kasí títayọ, bí Insight on the Scriptures àti Comprehensive Concordance, ni a tún ti tẹ̀ jáde ní onírúurú èdè. Bí ó ti wù kí ó rí, kìkì ìgbésẹ̀ àkọ́kọ́ ni níní àwọn ìwé wọ̀nyí jẹ́.

Ṣètò Àkójọ-Ìwé Rẹ!

Ohun kan ni ó jẹ́ láti mọ̀ pé o ní àwọn ìwé náà, ṣùgbọ́n ohun mìíràn ni pé kí o rí èyí tí o nílò. Bí a bá níláti fi ọ̀pọ̀ àkókò ṣòfò ní wíwá àwọn ìwé ìtọ́kasí tí a nílò kiri, ṣíṣeéṣe náà wà pé kí a pàdánù ọkàn-ìfẹ́ tí a ní nínú ọ̀ràn náà. Ní ìdàkejì ẹ̀wẹ̀, bí a bá ṣètò àwọn ìwé wa dáradára, sí ibìkan tí ó rọrùn, àwa yóò ní ìtẹ̀sí tí ó túbọ̀ pọ̀ síi láti ṣe ìwádìí jinlẹ̀ fúnraawa.

Bí ó bá ṣeéṣe, ó máa ń ṣèrànwọ́ pé kí a kó gbogbo ìwé ìṣàkóso Ọlọrun sí ojú kan náà. A lè ṣe àwọn àpótí ìkówèésí, ní ọ̀pọ̀ ìgbà pẹ̀lú owó pọ́ọ́kú, bí a kò bá lè ra èyí tí wọ́n ń ṣe tà, kò sì pọndandan kí wọ́n gba àyè tí ó pọ̀ jù. Mímú kí àkójọ-ìwé wà ní ibi tí ọwọ́ ti lè tètè tó o tún ṣe pàtàkì. Àwọn ìwé tí a kó pamọ́ sábẹ́ àjà wulẹ̀ máa ń kún fún eruku ni.

Ìgbésẹ̀ tí ó tẹ̀lé e ni láti ṣètò àwọn ìwé náà. Ìwọ̀nba àkókò kúkúrú tí a bá lò láti ṣètò àwọn ìwé lọ́nà tí ó bọ́gbọ́nmu máa ń mú èrè wá.

Bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé àwọn tí ó pọ̀ jùlọ nínú ìdílé rẹ kìí ṣe Ẹlẹ́rìí Jehofa ńkọ́? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lè má ṣeéṣe fún ọ láti ṣètò àkójọ-ìwé gẹ́gẹ́ bí ìwọ yóò ti fẹ́ láti ṣe, nínú yàrá tìrẹ o lè ní ibi ìkówèésí kan nínú èyí tí ó kérétán àwọn ìtẹ̀jáde tí a gbékarí Ìwé Mímọ́ wà.

Àkójọ-Ìwé kan Lè Ṣèrànwọ́ Láti Gbé Ipò Tẹ̀mí Ró

Lẹ́yìn tí a bá ti ṣètò àwọn ìwé wa tán, a nílò ìṣètò kan láti ràn wá lọ́wọ́ láti wá ìsọfúnni rí. Agbára ìrántí wa lè kùnà, àwa fúnraawa sì lè ṣàìmọ ohun tí ó wà nínú gbogbo ìwé ti ń bẹ lára àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun wa. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, gbogbo ìsọfúnni tí ń bẹ́ nínú àkójọ-ìwé náà ni ọwọ́ lè tètè tó. Bí ó bá wà lárọ̀ọ́wọ́tó ní èdè wa, ìwé Watch Tower Publications Index lè mú kí ó ṣeéṣe fún wa láti wá àwọn ìsọfúnni pàtó rí lórí èyí tí ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ gbogbo kókó ẹ̀kọ́ ní àárín àkókò kúkúrú.

Julián, tí ó ti ṣiṣẹ́sìn gẹ́gẹ́ bí aṣáájú-ọ̀nà àkànṣe àti alàgbà fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, ṣàlàyé pé Index náà ṣeyebíye gidigidi fún kíkọ́ ọmọkùnrin òun tí ó kéré jùlọ láti dákẹ́kọ̀ọ́. “Jairo, tí ó jẹ́ ọmọ ọdún méje, ti ilé-ẹ̀kọ́ dé láìpẹ́ yìí ó sì bi mí pé, ‘Dádì, kí ni Society ti sọ nípa àwọn ẹranko dinosaur?’ Ní tààràtà ni a lọ sínú Index tí a sì wo ọ̀rọ̀ náà ‘dinosaurs.’ A fẹ́rẹ̀ má tíì ṣí i nígbà tí a rí ọ̀wọ́ àwọn ọ̀rọ̀-ẹ̀kọ́ Jí! kan tí ó sọ̀rọ̀ nípa kókó-ẹ̀kọ́ náà. [August 8, 1990] Ní ọjọ́ yẹn kan náà, Jairo bẹ̀rẹ̀ síí kà á. Ó ti mọ̀ pé àkójọ-ìwé wa ní àwọn ìsọfúnni wíwúlò lórí èyí tí ó fẹ́rẹ̀ jẹ́ gbogbo kókó ẹ̀kọ́. Ní tèmi, ó dá mi lójú pé nígbà tí àwọn ọmọ wa bá kọ́ láti lo àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun lọ́nà rere, ó máa ń ràn wọ́n lọ́wọ́ láti dàgbà nípa tẹ̀mí. Wọ́n á kọ́ láti ronú, àti síwájú síi, wọ́n a rí i pé ìdákẹ́kọ̀ọ́ lè gbádùnmọ́ni.”

Fausto, bàbá Sherezade tí a mẹ́nukàn ní ìbẹ̀rẹ̀, gbàgbọ́ pé kíkọ́ àwọn ọmọ láti lo àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun ni a níláti bẹ̀rẹ̀ bí ó bá ti lè ṣeéṣe kí ó yá tó. Ó ṣàlàyé pé, “A ti ń fihàn Sherezade, tí ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́fà nísinsìnyí, bí ó ṣe lè lo Index. Níwọ̀n bí ìrètí nípa Paradise ilẹ̀-ayé ti fà á mọ́ra, a bẹ̀rẹ̀ síí fi ọ̀rọ̀ náà ‘paradise’ hàn án nínú Index tí a sì bẹ̀rẹ̀ síí wo ọ̀rọ̀-ẹ̀kọ́ náà nínú Ilé-Ìṣọ́nà tí a mẹ́nukàn. Lọ́pọ̀ ìgbà a wulẹ̀ ń fi àwọn àwòrán náà hàn án. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, ní ọ̀nà tí a gbé e gbà yìí ó kẹ́kọ̀ọ́ pé Index ni kọ́kọ́rọ́ náà sí wíwá ìsọfúnni rí láti inú àkójọ-ìwé wa ní ilé. A mọ̀ pé ó ti lóye kókó náà nígbà tí ó dárí dé láti ilé-ẹ̀kọ́ ní ọjọ́ kan pẹ̀lú ìbéèrè nípa ayẹyẹ Easter. Ó béèrè lọ́wọ́ ìyá rẹ̀ pé, ‘Èéṣe tí a kò kúkú wò ó nínú Index?’”

Ohun yòówù kí ọjọ́ orí wa jẹ́, Bibeli fún wa níṣìírí láti “wádìí ohun gbogbo dájú; . . . di ohun tí ó dára lọ́pọ̀lọpọ̀ mú ṣinṣin.” (1 Tessalonika 5:21, NW) Èyí béèrè pé kí a ṣàyẹ̀wò ohun ti Ìwé Mímọ́ sọ. (Iṣe 17:11) Bí a bá ni àkójọ-ìwé kan tí a ṣètò dáradára, irú ìwádìí jinlẹ̀ bẹ́ẹ̀ lè jẹ́ ohun tí ó gbádùnmọ́ni. Ní ìgbà kọ̀ọ̀kan tí a bá ti lò àkójọ-ìwé wa lọ́nà yíyọrísírere láti múra ọ̀rọ̀-àsọyé kan sílẹ̀, láti wá ìmọ̀ràn gbígbéṣẹ́ kan rí lórí ọ̀nà tí a lè gbà bójútó ìṣòro kan, tàbí láti wo àwọn ìsọfúnni fífanimọ́ra, yóò tẹ ìníyelórí ìgbéṣẹ́ àkójọ-ìwé wa mọ́ wa lọ́kàn.

Àwọn òbí Sherezade ṣàlàyé pé: “Nínú agboolé Kristian kan, ó dájú pé àkójọ-ìwé kan kìí ṣe ọ̀ṣọ́ àfitolé!”

[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 30]

BÁWO NI O ṢE LÈ ṢÈTÒ ÀWỌN ÌWÉ RẸ?

Kò sí ìlànà kan tí kò ṣeé yípadà lórí bí ó ṣe yẹ kí o ṣètò àwọn ìwé rẹ. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, àwọn ìṣètò bíbọ́gbọ́nmu tí ó tẹ̀lé e yìí jẹ́ àpẹẹrẹ ọ̀nà kan tí o lè gbà ṣètò àwọn ìwé rẹ ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí ń bẹ nínú wọn.

1. Àwọn ìwé tí wọ́n ní kúlẹ̀kúlẹ̀ ìjíròrò ẹlẹ́sẹẹsẹ ti àwọn apákan nínu Bibeli

(Àpẹẹrẹ: Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí, Revelation​—⁠Its Grand Climax At Hand!, “The Nations Shall Know That I Am Jehovah”​—⁠How?, “Ifẹ Tirẹ Ni Ki A Ṣe Li Aiye”)

2. Àwọn ìwé tí wọ́n jẹmọ́ ìgbésí-ayé ìdílé

(Àpẹẹrẹ: Mimu Ki Igbesi Ayé Idile Rẹ Jẹ Alayọ; Igba Ewe rẹ​—⁠Bi o ṣe le Gbadun rẹ Julọ, Iwe Itan Bibeli Mi)

3. Bibeli àti àwọn ìwé ìtọ́kasí

(Àpẹẹrẹ: New World Translation of the Holy Scriptures​—⁠With References, àwọn Bibeli mìíràn, àwọn Watch Tower Publications Index, Comprehensive Concordance, Insight on the Scriptures, The Kingdom Interlinear Translation of the Greek Scriptures, ìwé atúmọ̀-èdè tí ó dára)

4. Àwọn ìwé tí a ń lò lọ́wọ́ fún Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ àti Ilé-Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́-Òjíṣẹ́ Ìṣàkóso Ọlọrun

5. Àwọn kásẹ́ẹ̀tì tí a gbohùnsí àti àwọn fídíò

6. Àwọn ìdìpọ̀ Ilé-Ìṣọ́nà àti Jí!

7. Ọ̀rọ̀-ìtàn àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa

(Àpẹẹrẹ: Àwọn Yearbook of Jehovah’s Witnesses, Jehovah’s Witnesses​—⁠Proclaimers of God’s Kingdom)

8. Àwọn ìwé àti ìwé-pẹlẹbẹ tí a ń lò déédéé nínú iṣẹ́-òjísẹ́ wa

(Àpẹẹrẹ: Iwọ Le Walaaye Titilae ninu Paradise lori Ilẹ Aye, Reasoning From the Scriptures, Life​—⁠How Did It Get Here? By Evolution or by Creation?, Mankind’s Search for God, Isopọṣọkan ninu Ijọsin Ọlọrun Tootọ Kanṣoṣo Naa)

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 31]

Sherezade ti di akẹ́kọ̀ọ́ Bibeli dáradára báyìí

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 31]

Bí ó tilẹ̀ kéré lọ́jọ́ orí, ọmọdékùnrin yìí ń lo àkójọ-ìwé ti ìṣàkóso Ọlọrun

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́