ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w99 7/1 ojú ìwé 13-17
  • Kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Déédéé Gẹ́gẹ́ Bí Ìdílé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Déédéé Gẹ́gẹ́ Bí Ìdílé
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ète Tó Yẹ Ká Ní Lọ́kàn
  • Fi Ọgbọ́n Lo Àwọn Irinṣẹ́ Ẹ̀kọ́
  • Mú Un Bá Ìṣòro Ìdílé Rẹ Mu
  • Èrè Àìṣàárẹ̀
  • Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìdílé Tí Ń Mú Ìdùnnú Wá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìdílé—Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìdílé
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Títẹ́wọ́gba Ẹrù Iṣẹ́ Bíbójútó Ìdílé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
  • Ẹ̀yin Ìdílé, Ẹ Máa Yin Ọlọ́run Gẹ́gẹ́ Bí Apá kan Ìjọ Rẹ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
w99 7/1 ojú ìwé 13-17

Kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Déédéé Gẹ́gẹ́ Bí Ìdílé

“Ènìyàn kì yóò wà láàyè nípasẹ̀ oúnjẹ nìkan ṣoṣo, bí kò ṣe nípasẹ̀ gbogbo àsọjáde tí ń jáde wá láti ẹnu Jèhófà.”—MÁTÍÙ 4:4.

1. Kí ni Bíbélì sọ nípa ojúṣe àwọn olórí ìdílé láti kọ́ àwọn ọmọ wọn ní ọ̀nà Jèhófà?

LEMỌ́LEMỌ́ ni Jèhófà Ọlọ́run ń rán àwọn olórí ìdílé létí pé, kí wọ́n má ṣe gbàgbé ojúṣe wọn láti kọ́ àwọn ọmọ wọn lẹ́kọ̀ọ́. Irú ẹ̀kọ́ bẹ́ẹ̀ yóò mú àwọn ọmọ wọn gbára dì fún ìgbésí ayé ti ìsinsìnyí, ó sì tún lè múra wọn sílẹ̀ fún ìgbésí ayé tí ń bọ̀. Áńgẹ́lì kan tó ń ṣojú fún Ọlọ́run sọ fún Ábúráhámù pé ojúṣe rẹ̀ ni láti kọ́ agboolé rẹ̀ lẹ́kọ̀ọ́ kí wọn bàa lè “pa ọ̀nà Jèhófà mọ́.” (Jẹ́nẹ́sísì 18:19) A sọ fún àwọn òbí tí wọ́n jẹ́ ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n ṣàlàyé fáwọn ọmọ wọn, bí Ọlọ́run ṣe dá Ísírẹ́lì nídè kúrò lọ́wọ́ Íjíbítì àti bó ṣe fún wọn ní Òfin ní Òkè Sínáì, ní Hórébù. (Ẹ́kísódù 13:8, 9; Diutarónómì 4:9, 10; 11:18-21) A wá gba àwọn olórí ìdílé Kristẹni níyànjú láti tọ́ àwọn ọmọ wọn dàgbà “nínú ìbáwí àti ìlànà èrò orí Jèhófà.” (Éfésù 6:4) Kódà bó bá jẹ́ pé òbí kan ṣoṣo ló ń sin Jèhófà, ẹnì kan ṣoṣo yẹn gbọ́dọ̀ sapá láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ ní ọ̀nà Jèhófà.—2 Tímótì 1:5; 3:14, 15.

2. Ǹjẹ́ ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé wúlò rárá nínú ìdílé tí kò sọ́mọ? Ṣàlàyé.

2 Èyí kò túmọ̀ sí pé àwọn ìdílé tí wọ́n ní ọmọ nìkan ní ìkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ìdílé wà fún. Bí tọkọtaya bá ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé bí kò tiẹ̀ tíì sí ọmọ láàárín wọn, èyí ń fi hàn pé wọ́n mọrírì àwọn ohun tẹ̀mí gan-an.—Éfésù 5:25, 26.

3. Èé ṣe tó fi ṣe pàtàkì pé kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé jẹ́ èyí táa ń ṣe déédéé?

3 Kí nǹkan lè rí bó ti yẹ kó rí, ìkẹ́kọ̀ọ́ jẹ́ ohun táa gbọ́dọ̀ máa ṣe déédéé, èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú ẹ̀kọ́ tí Jèhófà kọ́ Ísírẹ́lì nínú aginjù pé: “Ènìyàn kì í tipa oúnjẹ nìkan ṣoṣo wà láàyè, bí kò ṣe nípasẹ̀ gbogbo gbólóhùn ọ̀rọ̀ ẹnu Jèhófà ni ènìyàn fi ń wà láàyè.” (Diutarónómì 8:3) Bí ipò ìdílé bá ṣe rí ni yóò pinnu bí ìkẹ́kọ̀ọ́ wọn yóò ṣe rí, àwọn ìdílé kan lè ṣètò pé ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ni ìkẹ́kọ̀ọ́ tàwọn; àwọn mìíràn sì lè gé àkókò ìkẹ́kọ̀ọ́ wọn kúrú ṣùgbọ́n kó jẹ́ lójoojúmọ́. Ètò èyíkéyìí tẹ́ẹ bá ṣe, ẹ má ṣe ní in lọ́kàn pé, ìgbà tí àyè bá wà la lè ṣèkẹ́kọ̀ọ́. ‘Ẹ ra àkókò padà’ nítorí ẹ̀. Bẹ́ẹ bá sa gbogbo ipá yín láti wá àkókò fún un, èrè rẹ̀ pọ̀ rẹpẹtẹ. Ìwàláàyè àwọn mẹ́ńbà ìdílé rẹ wà nínú ewu.—Éfésù 5:15-17; Fílípì 3:16.

Ète Tó Yẹ Ká Ní Lọ́kàn

4, 5. (a) Nípasẹ̀ Mósè, kí ni Jèhófà fi síwájú àwọn òbí pé ó jẹ́ ète pàtàkì tí wọ́n fi ń kọ́ àwọn ọmọ wọn? (b) Kí ni ìyẹn ń béèrè lónìí?

4 Nígbákigbà tẹ́ẹ bá fẹ́ ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé yín, yóò dáa púpọ̀ bẹ́ẹ bá láwọn ète pàtó lọ́kàn. Gbé díẹ̀ nínú àwọn ohun táa lè ṣe yẹ̀ wò.

5 Nígbàkigbà tẹ́ẹ bá fẹ́ ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́, wá ọ̀nà láti gbé ìfẹ́ fún Jèhófà Ọlọ́run ró. Nígbà táa pe àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù, kí wọ́n tó wọ Ilẹ̀ Ìlérí, Mósè darí àfiyèsí wọn sí ohun tí Jésù Kristi wá pè ní “àṣẹ títóbi jù lọ nínú Òfin.” Èwo ni? “Kí ìwọ nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn-àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti pẹ̀lú gbogbo èrò inú rẹ.” (Mátíù 22:36, 37; Diutarónómì 6:5) Mósè rọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yìí wọ̀ wọ́n lọ́kàn ṣinṣin, kí wọ́n sì fi kọ́ àwọn ọmọ wọn. Ìyẹn á béèrè pé kí wọ́n máa sọ ọ́ lásọtúnsọ, kí wọ́n pe àfiyèsí àwọn ọmọ wọn sí ìdí tí wọ́n fi ní láti nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, kí wọ́n jẹ́ kí wọ́n mọ àwọn ìwà àti ìṣe tó lè ṣèdíwọ́ fún fífi irú ìfẹ́ bẹ́ẹ̀ hàn, bákan náà wọn yóò jẹ́ kí wọ́n mọ bí wọ́n ṣe lè fi ìfẹ́ hàn fún Jèhófà nínú ìgbésí ayé wọn. Ǹjẹ́ àwọn ọmọ tiwá nílò irú ẹ̀kọ́ bẹ́ẹ̀? Wọ́n nílò rẹ̀ mọ̀nà! Àwọn náà nílò ìrànlọ́wọ́ láti lè ‘dá adọ̀dọ́ ọkàn-àyà wọn,’ ìyẹn ni pé, kí wọ́n yọ ohunkóhun tó bá máa ṣèdíwọ́ fún ìfẹ́ wọn fún Ọlọ́run kúrò lọ́kàn wọn. (Diutarónómì 10:12, 16; Jeremáyà 4:4) Lára irú àwọn ohun tó lè ṣèdíwọ́ bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ fún àwọn nǹkan ayé àti wíwá àǹfààní láti ri ara wa bọ inú àwọn ìgbòkègbodò rẹ̀. (1 Jòhánù 2:15, 16) Ìfẹ́ fún Jèhófà gbọ́dọ̀ jẹ́ èyí tó múná, ìfẹ́ táa fi hàn, èyí tí ń sún wa láti ṣe ohun tó wu Baba wa ọ̀run. (1 Jòhánù 5:3) Kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé rẹ lè ní àǹfààní tí yóò wà fún ìgbà pípẹ́, gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń ṣe é lẹ gbọ́dọ̀ ṣe é lọ́nà tí yóò gbà fún ìfẹ́ yìí lókun.

6. (a) Kí là ń béèrè láti lè gbin ìmọ̀ pípéye sínú àwọn ọmọ? (b) Báwo ni Ìwé Mímọ́ ṣe tẹnu mọ́ ìjẹ́pàtàkì ìmọ̀ pípéye?

6 Gbin Ìmọ̀ Pípéye tí Ọlọ́run Ń Béèrè Sí Wọn Lọ́kàn. Kí lèyí ń béèrè? Ohun tó ń béèrè ju pé ká kàn lè ka ìdáhùn jáde nínú ìwé ìròyìn tàbí ìwé kan. Ká tó lè lóye àwọn lájorí ọ̀rọ̀ àti àwọn èrò pàtàkì-pàtàkì lọ́nà tó ṣe kedere, ó sábà máa ń béèrè ìjíròrò tó kúnná. Ìmọ̀ pípéye ṣe pàtàkì gidigidi táa bá fẹ́ gbé àkópọ̀ ìwà tuntun wọ̀, ó tún ṣe pàtàkì fún pípọkànpọ̀ sórí àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù gan-an nígbà táa bá ń yanjú ìṣòro ìgbésí ayé, nípa bẹ́ẹ̀, ó ṣe pàtàkì táa bá fẹ́ ṣe ohun tó wu Ọlọ́run.—Fílípì 1:9-11; Kólósè 1:9, 10; 3:10.

7. (a) Àwọn ìbéèrè wo ló lè ran ìdílé lọ́wọ́ láti mọ bí wọn yóò ṣe fi ohun tí wọ́n kọ́ sílò? (b) Báwo ni Ìwé Mímọ́ ṣe tẹnu mọ́ ìníyelórí irú ète bẹ́ẹ̀?

7 Kọ́ wọn báa ṣe lè lo ohun táa kẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀. Pẹ̀lú ète yìí lọ́kàn, nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé, béèrè pé: ‘Báwo lohun táa ń kọ́ yìí ṣe lè nípa lórí ìgbésí ayé wa? Ǹjẹ́ ó ń béèrè pé ká ṣàtúnṣe àwọn ọ̀nà táa gbà ń ṣe nǹkan ní lọ́ọ́lọ́ọ́? Èé ṣe tó fi yẹ ká ṣàtúnṣe?’ (Òwe 2:10-15; 9:10; Aísáyà 48:17, 18) Báa bá ń fún àwọn ohun tí a ń kọ́ ní àfiyèsí tí ó tó, yóò jẹ́ kókó pàtàkì kan nínú ìdàgbàsókè tẹ̀mí àwọn mẹ́ńbà ìdílé.

Fi Ọgbọ́n Lo Àwọn Irinṣẹ́ Ẹ̀kọ́

8. Àwọn irinṣẹ́ wo ni ẹgbẹ́ ẹrú náà ti pèsè fún ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

8 “Ẹrú olóòótọ́ àti olóye” ti pèsè irinṣẹ́ rẹpẹtẹ táa lè fi kẹ́kọ̀ọ́. Ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́, táa lè lo pẹ̀lú Bíbélì, wà lédè mọ́kànléláàádóje [131]. Àwọn ìwé táa lè lò fún ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wà lédè mẹ́tàléláàádọ́jọ [153], a ní ìwé pẹlẹbẹ lédè igba ó lé ọgọ́rin àti mẹ́rin [284], kásẹ́ẹ̀tì àtẹ́tísí ń bẹ lédè mọ́kànlélọ́gọ́ta [61], fídíò wà lédè mọ́kànlélógójì [41], èyí tó tún pabanbarì ni ti ètò ìsọfúnni orí kọ̀ǹpútà tó wà fún ṣíṣèwádìí lórí Bíbélì lédè mẹ́sàn-án!—Mátíù 24:45-47.

9. Báwo la ṣe lè lo ìmọ̀ràn tó wà nínú àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí a yàn sínú ìpínrọ̀ yìí nígbà táa bá ń fi Ilé Ìṣọ́ ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé?

9 Ọ̀pọ̀ ìdílé ló ń fi àkókò ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé wọn múra sílẹ̀ fún Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ilé Ìṣọ́ ti ìjọ. Ìyẹn á mà ràn wọ́n lọ́wọ́ gan-an o! Torí pé inú ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ ni lájorí oúnjẹ tẹ̀mí tí a ń pèsè láti gbé àwọn ènìyàn Jèhófà ró kárí ayé wà. Nígbà tẹ́ẹ bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Ilé Ìṣọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé, ẹ má fi mọ́ sórí kíka àwọn ìpínrọ̀ àti dídáhùn àwọn ìbéèrè táa tẹ̀ jáde lásán. Ẹ fi tọkàntọkàn wá bí ẹ ó ṣe lóye rẹ̀. Ẹ wáyè láti wo àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí a yàn ṣùgbọ́n tí a kò fà yọ. Ké sí àwọn mẹ́ńbà ìdílé láti sọ̀rọ̀ lórí bí àwọn ẹsẹ wọ̀nyí ṣe kan kókó tó wà nínú ìpínrọ̀ tí à ń gbé yẹ̀ wò. Jẹ́ kí ó wọ̀ wọ́n lọ́kàn ṣinṣin.—Òwe 4:7, 23; Ìṣe 17:11.

10. Kí la lè ṣe láti jẹ́ kí àwọn ọmọ wa kópa nínú ìkẹ́kọ̀ọ́ àti láti jẹ́ kó jẹ́ àkókò tí yóò tù wọ́n lára?

10 Bí àwọn ọmọ bá wà nínú ìdílé rẹ, kí lẹ lè ṣe láti mú kí ìkẹ́kọ̀ọ́ yín má wulẹ̀ jẹ́ àṣà ìdílé lásán, ṣùgbọ́n kó jẹ́ àkókò tí ń gbéni ró, tó ń gbádùn mọ́ni, àti àkókò ayọ̀? Gbìyànjú láti jẹ́ kí olúkúlùkù kópa nínú ẹ̀, kí wọ́n bàa lè pọkàn pọ̀ sórí ohun tí ẹ̀ ń kọ́. Níbi tó bá ti ṣeé ṣe, ṣètò pé kí ọmọ kọ̀ọ̀kan ní Bíbélì àti ìwé ìròyìn tirẹ̀ tí ẹ óò fi ṣèkẹ́kọ̀ọ́. Ní ṣíṣàfarawé ìfẹ́ tí Jésù fi hàn, òbí kan lè jẹ́ kí ọmọ kékeré kan jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ òun, ó tilẹ̀ lè rọra fi ọwọ́ gbá ọmọ náà mọ́ra. (Fi wé Máàkù 10:13-16.) Olórí ìdílé lè sọ pé kí ọ̀dọ́mọdé kan ṣàlàyé àwòrán tó wà lójú ìwé tí à ń kẹ́kọ̀ọ́. Kí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà tó bẹ̀rẹ̀, a lè sọ fún ọmọ tó kéré pé òun ni yóò ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan. A lè sọ fún èyí tó dàgbà díẹ̀ láti mẹ́nu kan àwọn àǹfààní tó wà nínú fífi àwọn ohun táa kẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ sílò.

11. Àwọn irinṣẹ́ mìíràn tó wà fún kíkẹ́kọ̀ọ́ la ti pèsè, níbi tí wọ́n bá sì ti wà lárọ̀ọ́wọ́tó, báwo la ṣe lè lò wọ́n lọ́nà tí yóò ṣàǹfààní fún ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé?

11 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé o lè lo Ilé Ìṣọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpìlẹ̀ fún ìjíròrò rẹ, má ṣe gbàgbé àwọn irinṣẹ́ yòókù tó wà fún ìkẹ́kọ̀ọ́, táa ní ní ọ̀pọ̀ èdè. Bó bá jẹ́ kúlẹ̀kúlẹ̀ ìsọfúnni tàbí àlàyé lórí gbólóhùn kan nínú Bíbélì lo fẹ́ mọ̀, ìwé Insight on the Scriptures lè pèsè rẹ̀. A lè dáhùn àwọn ìbéèrè mìíràn nípa yíyẹ ìwé Watch Tower Publications Index wò tàbí nípa lílo ètò ìsọfúnni orí kọ̀ǹpútà tí Society ṣe. Kíkọ́ báa ṣe lè lo àwọn irinṣẹ́ wọ̀nyí, bí wọ́n bá wà lédè rẹ, lè jẹ́ apá ṣíṣeyebíye nínú ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé rẹ. Pẹ̀lú èrò àtiru ìfẹ́ àwọn èwe sókè, o tún lè ya àkókò pàtó sọ́tọ̀ láti wo díẹ̀ lára àwọn fídíò Society tó kún fún ẹ̀kọ́, tàbí láti tẹ́tí sílẹ̀ sí apá kan nínú àwòkẹ́kọ̀ọ́ tó wà nínú kásẹ́ẹ̀tì àtẹ́tísí, lẹ́yìn náà kẹ́ẹ wá jíròrò rẹ̀. Lílo àwọn irinṣẹ́ wọ̀nyí dáadáa fún ìkẹ́kọ̀ọ́ lè mú kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé rẹ gbádùn mọ́ni, kó sì ṣe gbogbo ìdílé láǹfààní.

Mú Un Bá Ìṣòro Ìdílé Rẹ Mu

12. Báwo ni ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé ṣe ń kó ipa pàtàkì nínú kíkojú àwọn ìṣòro tó ń fẹ́ àmójútó kánjúkánjú nínú ìdílé?

12 O lè jẹ́ pé àpilẹ̀kọ inú Ilé Ìṣọ́ tó jẹ́ ti ọ̀sẹ̀ kọ̀ọ̀kan ni ìdílé rẹ fi ń kẹ́kọ̀ọ́. Bó ti wù kó rí, rí i pé o mọ ìṣòro tó wà nínú ìdílé rẹ. Tó bá jẹ́ pé màmá wọn kì í lọ síbi iṣẹ́, ó lè ṣeé ṣe fún un láti lo àkókò pẹ̀lú àwọn ọmọ lójoojúmọ́ nígbà tí wọ́n bá ti ilé ìwé dé. Nípa bẹ́ẹ̀ ó lè yanjú àwọn ìṣòro kan; àwọn mìíràn sì lè túbọ̀ gba àfiyèsí. Nígbà tí àwọn ìṣòro tí ń fẹ́ àmójútó kánjúkánjú bá jẹ yọ nínú ìdílé, má ṣe pa wọ́n tì. (Òwe 27:12) Yàtọ̀ sí àwọn ìṣòro ilé ìwé, àwọn ìṣòro mìíràn tún lè wà lára ìwọ̀nyí. Wá àwọn ọ̀rọ̀ tó bá a mu táa ti tẹ̀ jáde, kí o sì fi ohun tí ẹ óò kẹ́kọ̀ọ́ tó ìdílé rẹ létí.

13. Èé ṣe tí ìjíròrò ìdílé nípa báa ṣe lè kojú ipò òṣì ṣe lè ṣàǹfààní?

13 Fún àpẹẹrẹ, apá tó pọ̀ jù lọ lórí ilẹ̀ ayé wà nínú ipò òṣì paraku; nítorí náà ní ọ̀pọ̀ ibi, ó lè pọndandan láti jíròrò báa ṣe lè kojú rẹ̀. Ǹjẹ́ ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé tí a gbé ka àwọn ipò nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ gan-an àti àwọn ìlànà Bíbélì lè ṣàǹfààní fun agboolé rẹ?—Òwe 21:5; Oníwàásù 9:11; Hébérù 13:5, 6, 18.

14. Àwọn ipò wo ló lè mú kí ìjíròrò ìdílé nípa ojú tí Jèhófà fi ń wo ìwà ipá, ogun, àti àìdásí-tọ̀túntòsì àwọn Kristẹni bọ́ sákòókò?

14 Kókó mìíràn tó yẹ kẹ́ jíròrò ni ìwà ipá. Gbogbo wa ló yẹ ká tẹ ojú ìwòye Jèhófà mọ́ lọ́kàn. (Jẹ́nẹ́sísì 6:13; Sáàmù 11:5) Ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé lórí kókó yìí lè fún wa láǹfààní láti jíròrò báa ṣe lè kojú àwọn abúmọ́ni nílé ẹ̀kọ́, bóyá ó yẹ ká kọ́ eré ìgbèjà ara-ẹni, àti báa ṣe lè yan eré ìnàjú tó dára. Yánpọnyánrin ti di ohun tó wà káàkiri; ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo orílẹ̀-èdè ni ogun abẹ́lé, ìjà òṣèlú tàbí ti ẹ̀yà, tàbí ogun àwọn àjọ ìpàǹpá ti ń jà. Ìyọrísí rẹ̀ ni pé, ìdílé rẹ lè nílò ìjíròrò nípa pípa ìwà rere Kristẹni mọ́ nígbà tí ẹ bá bára yín láàárín àwọn ẹgbẹ́ tí ń bára wọn jà.—Aísáyà 2:2-4; Jòhánù 17:16.

15. Báwo ló ṣe yẹ ká gbé ìtọ́ni nípa ìbálòpọ̀ àti ìgbéyàwó kalẹ̀ fáwọn ọmọ?

15 Báwọn ọmọ ti ń dàgbà, wọ́n nílò ẹ̀kọ́ nípa ìbálòpọ̀ àti ìgbéyàwó, èyí tó bá ọjọ́ orí wọn mu. Láwọn àwùjọ kan, èèwọ̀ ni, àwọn òbí kò jẹ́ jíròrò ọ̀ràn ìbálòpọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn. Àwọn ọmọ tí wọn kò mọ nǹkan kan nípa rẹ̀ tẹ́lẹ̀ sì lè gbọ́ ojú ìwòye òdì lọ́dọ̀ àwọn èwe mìíràn, àbájáde rẹ̀ sì lè burú jáì. Ǹjẹ́ kò ní dáa ká kúkú fara wé Jèhófà, ẹni tí kò pẹ́ ọ̀rọ̀ yìí sọ, ṣùgbọ́n tó fúnni nímọ̀ràn tó mọ́yán lórí nípa rẹ̀ nínú Bíbélì? Ìmọ̀ràn Ọlọ́run yóò ran àwọn ọmọ wa lọ́wọ́ láti ní ọ̀wọ̀ ara ẹni, kí wọ́n sì máa buyì fún àwọn ẹ̀yà òdìkejì. (Òwe 5:18-20; Kólósè 3:5; 1 Tẹsalóníkà 4:3-8) Kódà bó bá jẹ́ pé ẹ ti jíròrò àwọn ọ̀ràn yìí rí, má ṣe lọ́tìkọ̀ láti jíròrò ẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i. Bí ipò tuntun bá ti ń dìde, àsọtúnsọ ṣe pàtàkì.

16. (a) Nínú agboolé ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, nígbà wo ni wọ́n ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé? (b) Ọ̀nà wo lo gbà yanjú àwọn ìṣòro kan kí o bàa lè máa ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé déédéé?

16 Ìgbà wo lo dáa ká máa ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé? Ní títẹ̀lé àpẹẹrẹ àwọn ìdílé Bẹ́tẹ́lì yíká ayé, ọ̀pọ̀ ìdílé ṣètò ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ Monday fún ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé wọn. Àwọn mìíràn yan ọjọ́ tó yàtọ̀. Ní Ajẹntínà, ìdílé ẹlẹ́ni mọ́kànlá, tí wọ́n ní ọmọ mẹ́sàn-án, máa ń jí ní aago márùn-ún ìdájí láti ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé wọn. Nítorí àkókò iṣẹ́ wọn tó yàtọ̀ síra, kò sí àkókò mìíràn tí wọ́n lè fi sí. Lóòótọ́ kò rọrùn, ṣùgbọ́n ètò yìí jẹ́ káwọn ọmọ wọn mọ̀ pé ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé ṣe pàtàkì, ó ṣe kókó. Ní orílẹ̀-èdè Philippines, alàgbà kan darí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé déédéé pẹ̀lú aya rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta bí wọ́n ti ń dàgbà. Láàárín ọ̀sẹ̀, àwọn òbí tún máa ń bá ọmọ kọ̀ọ̀kan ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ tirẹ̀, káwọn ọmọ náà bàa lè sọ òtítọ́ di tiwọn lẹ́nì kọ̀ọ̀kan. Ní Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà, arábìnrin kan tí ọkọ rẹ̀ kì í ṣe Ẹlẹ́rìí máa ń mú àwọn ọmọ rẹ̀ lọ wọkọ̀ ilé ẹ̀kọ́ lárààárọ̀. Nígbà tí wọ́n bá ń dúró de ọkọ̀, wọ́n máa ń lo nǹkan bí ìṣẹ́jú mẹ́wàá pa pọ̀ láti ka àwọn ẹ̀kọ́ táa gbé ka Ìwé Mímọ́, tó bá ipò wọn mu, wọn á sì jíròrò rẹ́, lẹ́yìn náà màmá wọn á wá gbàdúrà ṣókí káwọn ọmọ náà tó wọkọ̀. Ní Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Kóńgò, obìnrin kan tí ọkọ rẹ̀ tó jẹ́ aláìgbàgbọ́ ti pa ìdílé náà tì, ní láti ṣiṣẹ́ àṣekára láti ṣèkẹ́kọ̀ọ́ nítorí pé kò fi bẹ́ẹ̀ mọ̀wé. Ọmọkùnrin rẹ̀ tó ti dàgbà ṣèrànwọ́ nípa bíbẹ ìdílé náà wò lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ láti lè darí ìkẹ́kọ̀ọ́ tí màmá rẹ̀ àti àwọn àbúrò rẹ̀ ọkùnrin yóò kópa nínú rẹ̀. Màmá náà fi àpẹẹrẹ rere lélẹ̀ nípa mímúra sílẹ̀ dáadáa. Ǹjẹ́ àwọn ipò kan wà tó mú kí ṣíṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé ṣòro nínú agboolé rẹ? Máà jẹ́ kó rẹ̀ ọ́. Máa fi taratara wá ìbùkún Jèhófà lórí ìsapá rẹ láti ní ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tí ẹ̀ ń ṣe déédéé.—Máàkù 11:23, 24.

Èrè Àìṣàárẹ̀

17. (a) Kí o bàa lè máa ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé tó ń lọ déédéé, kí là ń béèrè? (b) Ìrírí wo ló ṣàkàwé ìníyelórí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé tí à ń ṣe déédéé lọ́nà tí Jèhófà fẹ́?

17 Ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé tí a ń ṣe déédéé ń béèrè ìwéwèé. Ó béèrè pé ká má ṣàárẹ̀. Ṣùgbọ́n àǹfààní tí ń wá láti inú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀, ó tún jù bẹ́ẹ̀ lọ. (Òwe 22:6; 3 Jòhánù 4) Franz àti Hilda, tí wọ́n wà ní Germany, tọ́ ìdílé ọlọ́mọ mọ́kànlá dàgbà. Ọdún díẹ̀ lẹ́yìn náà, ọmọbìnrin wọn tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Magdalena wí pé: “Ohun tí mo gbà pé ó ṣe pàtàkì jù lọ lónìí ni pé ilẹ̀ ọjọ́ kan kò ní mọ́ ká má gba ìtọ́ni nípa tẹ̀mí.” Nígbà tí ẹ̀mí ìfẹ́ orílẹ̀-èdè ẹni di èyí tó gbóná janjan lábẹ́ ìjọba Adolf Hitler, baba Magdalena lo Bíbélì láti mú kí ìdílé rẹ̀ gbára dì fún ìdánwò tó mọ̀ pé ó ń bọ̀. Kò pẹ́ púpọ̀, àwọn aláṣẹ fipá kó àwọn ọmọ kéékèèké inú ilé náà kúrò lọ́dọ̀ àwọn òbí wọn, wọ́n kó wọn lọ sí ilé ẹ̀kọ́ atúnniṣe; wọ́n fàṣẹ ọba mú àwọn tó ṣẹ́ kù, wọ́n tì wọ́n mọ́ ọgbà ẹ̀wọ̀n àti àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́. Wọ́n pa díẹ̀ lára wọn. Gbogbo wọn ló di ìgbàgbọ́ wọn mú—kì í ṣe lákòókò inúnibíni gbígbóná janjan yẹn nìkan ṣoṣo ṣùgbọ́n, láwọn ọdún tó tẹ̀ lé e pàápàá, àwọn tó là á já lára wọn kò sọ ìgbàgbọ́ nù.

18. Báwo la ṣe san èrè fún ìsapá àwọn òbí kan tí wọ́n jẹ́ anìkàntọ́mọ?

18 Ọ̀pọ̀ òbí anìkàntọ́mọ, àti àwọn mìíràn tí ọkọ tàbí aya wọn kò tẹ́wọ́ gba ẹ̀sìn wọn, máa ń kọ́ àwọn ọmọ wọn lẹ́kọ̀ọ́ déédéé láti inú Bíbélì. Obìnrin opó kan ní Íńdíà, tó jẹ́ anìkàntọ́mọ, ṣíṣẹ kára láti gbin ìfẹ́ fún Jèhófà sínú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì. Àmọ́ ṣá o, nígbà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin kọ̀, tí kò dara pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn Jèhófà mọ́, ọkàn rẹ̀ gbọgbẹ́. Ó bẹ Jèhófà pé kó dákun kó dárí ji òun fún àṣìṣe èyíkéyìí tóun ti lè ṣe lọ́nà tí òun gba tọ́ ọmọ náà. Ṣùgbọ́n kì í ṣe pé ọmọ náà ti gbà gbé ohun tó ti kọ́ pátápátá. Lẹ́yìn ohun tó lé lọ́dún mẹ́wàá, ọmọkùnrin táà ń wí yìí padà wá, ó tẹ̀ síwájú gan-an nípa tẹ̀mí, ó sì di alàgbà nínú ìjọ. Ní báyìí, aṣáájú-ọ̀nà alákòókò kíkún ni òun àtìyàwó ẹ̀. Ayọ̀ ńláǹlà ló máa ń jẹ́ fún irú àwọn òbí yìí, àwọn tí wọ́n fi ìmọ̀ràn Jèhófà àti ti ètò àjọ rẹ̀ sọ́kàn láti máa pèsè ìtọ́ni Bíbélì fún agbo ìdílé wọn déédéé! Ǹjẹ́ ò ń fi ìmọ̀ràn yìí sílò nínú ìdílé rẹ?

Ǹjẹ́ O Lè Ṣàlàyé?

◻ Èé ṣe tí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé fi ṣe pàtàkì?

◻ Kí ló yẹ kó jẹ́ ète wa nígbàkigbà táa bá fẹ́ ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé?

◻ Àwọn irinṣẹ́ wo ló wà lárọ̀ọ́wọ́tó fún wa, táa lè fi ṣèkẹ́kọ̀ọ́?

◻ Báwo la ṣe lè mú kí ìkẹ́kọ̀ọ́ bá ìṣòro ìdílé mu?

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 15]

Níní ète pàtó lọ́kàn yóò mú kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé rẹ̀ sunwọ̀n sí i

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́