ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w05 5/15 ojú ìwé 3
  • Ǹjẹ́ Ọmọ Èèyàn Lè Fòpin Sí Ipò Òṣì?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Ọmọ Èèyàn Lè Fòpin Sí Ipò Òṣì?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Tí Òṣì Dì Nígbèkùn
    Jí!—1998
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Ìsapá Àwọn Èèyàn Láti Fòpin sí Ipò Òṣì
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Òṣì Yóò Dópin Láìpẹ́
    Jí!—1998
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
w05 5/15 ojú ìwé 3

Ǹjẹ́ Ọmọ Èèyàn Lè Fòpin Sí Ipò Òṣì?

ÀÌMỌYE èèyàn ni kò mọ ohun tó ń jẹ́ òṣì láyé wọn, tó jẹ́ pé ebi ò pa wọ́n sùn rí, tí wọn ò sì ráre rí. Ọ̀pọ̀ àwọn wọ̀nyí ni wọ́n máa ń ṣàánú àwọn aláìní, tí wọ́n sì máa ń sa gbogbo ipá wọn láti ràn wọ́n lọ́wọ́.

Àmọ́ ogun, omíyalé, ọ̀dá àtàwọn ìṣòro míì bẹ́ẹ̀ ṣì ń sọ àwọn èèyàn di òtòṣì. Àwọn ìṣòro wọ̀nyí ń han àwọn àgbẹ̀ arokojẹ nílẹ̀ Áfíríkà léèmọ̀ gan-an ni. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ti lé àwọn àgbẹ̀ kan kúrò ní abúlé lọ sí ìlú ńlá tàbí kó sọ wọ́n dẹni tó ń ráágó lórílẹ̀-èdè mìíràn. Àwọn mìíràn láti àrọko máa ń ṣí lọ sílùú ńlá lérò pé nǹkan á túbọ̀ rọ̀ṣọ̀mù fáwọn níbẹ̀.

Láwọn ìlú ńlá térò máa ń rọ́ sí jù, àtijẹ-àtimu máa ń ṣòro fáwọn èèyàn. Ìdí ni pé ibi gbogbo máa ń há gádígádí, kì í sì í fi bẹ́ẹ̀ sí ilẹ̀ láti fi dáko. Kì í sábà rọrùn láti ríṣẹ́. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tí ìyà ti pá lórí á wá di jàǹdùkú sígboro. Àwọn aráàlú ké gbàjarè títí síjọba nítorí nǹkan wọ̀nyí àmọ́ ọ̀rọ̀ àìríná-àìrílò kì í ṣe ohun tí ìjọba èèyàn lè yanjú, kódà ńṣe ló ń burú sí i. Nígbà tí ìwé ìròyìn The Independent ti ìlú London ń sọ̀rọ̀ nípa ìròyìn kan tí àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè gbé jáde ní oṣù November 2003, ó ní: “Ńṣe làwọn tí ò rí jẹ tí ò rí mu túbọ̀ ń pọ̀ sí i láyé.” Ó tún fi kún un pé: “Nínú ayé lónìí, nǹkan bí ẹgbẹ̀rin ó lé méjìlélógójì mílíọ̀nù èèyàn ni kì í róúnjẹ jẹ kánú, ọdọọdún la sì ń rí mílíọ̀nù márùn-ún èèyàn tébi ń hàn léèmọ̀ yàtọ̀ sáwọn wọ̀nyí.”

Lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, ẹ̀ka ọ́fíìsì àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà lórílẹ̀-èdè Gúúsù Áfíríkà máa ń gba lẹ́tà látọ̀dọ̀ àwọn tí ìṣẹ́ ń ṣẹ́. Bí àpẹẹrẹ, ọkùnrin kan tó ń gbé nílùú Bloemfontein kọ̀wé pé: “Mi ò níṣẹ́ lọ́wọ́, ńṣe ni mo máa ń jalè nígbà míì. Bí mi ò bá jalè, inú ebi la máa wà fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ ti òtútù tó máa ń mú wa gan-an lóru. Kò síṣẹ́ láti ṣe rárá ni o. Ńṣe lọ̀pọ̀ èèyàn ń rìn kiri ìgboro bóyá wọ́n á lè ríṣẹ́ tàbí bóyá wọ́n á kàn tiẹ̀ rí nǹkan fi sẹ́nu. Mo mọ àwọn kan tó jẹ́ pé ńṣe ni wọ́n máa ń ṣa oúnjẹ jẹ káàkiri orí ààtàn. Àwọn mìíràn tiẹ̀ ti fọwọ́ ara wọn para wọn. Ọ̀pọ̀ èèyàn layé ti sú bíi tèmi, tí wọ́n ti gbà pé àwọn ò lè rí bá ti ṣé mọ́ láé. Ó jọ pé ọmọ èèyàn ò lè rọ́nà gbé e gbà mọ́ láé. Ṣé Ọlọ́run tó dá ẹnu fún wa pé ká máa fi jẹun tó sì dá ara tá à ń wọṣọ sí ò rí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni?”

Ìdáhùn tó ń tuni nínú wà fún ìbéèrè tó ń jẹ ọkùnrin yìí lọ́kàn. Inú Bíbélì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni ìdáhùn náà sì wà gẹ́gẹ́ bí àpilẹ̀kọ tó kàn yóò ṣe jẹ́ ká mọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́