ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 9/1 ojú ìwé 6
  • Báwo la ṣe ń rówó bójú tó iṣẹ́ wa?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo la ṣe ń rówó bójú tó iṣẹ́ wa?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Báwo Ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Ṣe Ń Lo Àwọn Ọrẹ Tá À Ń Rí?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Báwo La Ṣe Ń Rí Owó fún Iṣẹ́ Wa Kárí Ayé?
    Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
  • Bí A Ṣe Ń Rí Owó Bójú Tó Iṣẹ́ Ìjọba Ọlọ́run
    Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
  • “Ẹ̀bùn Tá A Mú Dání Wá fún Jèhófà”
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 9/1 ojú ìwé 6
Ẹnì kan fi owó sínú àpótí ọrẹ

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | TA NI ÀWỌN ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ?

Báwo la ṣe ń rówó bójú tó iṣẹ́ wa?

Lọ́dọọdún, a máa ń tẹ ọ̀pọ̀ mílíọ̀nù Bíbélì àti àwọn ìwé tó ń ṣàlàyé Bíbélì, a sì máa ń pín in fún àwọn èèyàn. A máa ń kọ́ àwọn ẹ̀ka ọ́fíìsì àti àwọn ibi ìtẹ̀wé, a sì ń bójú tó iṣẹ́ tó ń lọ níbẹ̀. Ọgọ́rọ̀ọ̀rún àwọn ìjọ sì tún máa ń ṣe ìpàdé ní àwọn ibi ìjọsìn tó bójú mu, tó sì mọ níwọ̀n, èyí tí à ń pè ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Báwo la ṣe ń rówó ṣe gbogbo àwọn nǹkan yìí?

Ọrẹ tí àwọn èèyàn fínnú fíndọ̀ ṣe la fi ń ṣe àwọn iṣẹ́ yìí. (2 Kọ́ríńtì 9:7) Lọ́dún 1879, ìwé ìròyìn Zion’s Watch Tower tá à ń pè ní Ilé Ìṣọ́ báyìí sọ pé: “A gbà pé JÈHÓFÀ ni alátìlẹyìn ‘Zion’s Watch Tower,’ torí náà, ìwé ìròyìn yìí kò ní tọrọ ohunkóhun bẹ́ẹ̀ ni kò ní bẹ̀bẹ̀ láé pé káwọn èèyàn wá ṣètìlẹ́yìn fáwọn.” Ìlànà yẹn náà la ṣì ń tẹ̀ lé di báyìí.

A máa ń fi ọrẹ ránṣẹ́ sí ẹ̀ka ọ́fíìsì wa ní tààràtà tàbí ká fi sínú àpótí ọrẹ tó wà ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Àmọ́, a kì í gba ìdámẹ́wàá, a kì í gbégbá ọrẹ, a ò sì ń díye lé àwọn ìwé wa. A kì í gba owó fún iṣẹ́ ìwàásù tá à ń ṣe, àwọn tó ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ ní àwọn ìpàdé wa kì í gba owó, a ò sì ń gba owó tá a bá lọ kọ́ àwọn ibi tá a ti ń jọ́sìn. Ó ṣe tán, Jésù sọ pé: “Ọ̀fẹ́ ni ẹ̀yin gbà, ọ̀fẹ́ ni kí ẹ fúnni.” (Mátíù 10:8) Gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ní àwọn ẹ̀ka ọ́fíìsì àtàwọn tó ń ṣiṣẹ́ ní orílé-iṣẹ́ títí kan àwọn tó wà lára Ìgbìmọ̀ Olùdarí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà, kì í gba owó oṣù fún iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe.

“Ọrẹ táwọn èèyàn fínnú fíndọ̀ ṣe láwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi ń bójú tó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ ìjọsìn wọn, ẹnì kọ̀ọ̀kan ló máa ń pinnu iye tó máa fi ‘ṣètọrẹ’ fún iṣẹ́ Ọlọ́run àti ìgbà tó máa mú un wá.”​—Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù, ọdún 2011

A tún máa ń fi ọrẹ táwọn èèyàn ṣe ran àwọn tí jàǹbá ṣẹlẹ̀ sí lọ́wọ́. Inú àwọn Kristẹni ìjímìjí máa ń dùn láti ṣèrànwọ́ fún àwọn aláìní. (Róòmù 15:26) A máa ń bá àwọn tí jàǹbá ṣẹlẹ̀ sí tún ilé àti ibi ìjọsìn wọn ṣe. A máa ń fún wọn lóúnjẹ àti aṣọ, a sì tún máa ń tọ́jú àwọn tó fara pa.

Ọmọ kékeré kan ń rẹ́rìn-ín

Wo fídíò yìí, Philippines Typhoon​—Faith Conquers Adversity ní ìkànnì www.jw.org. (Wo abẹ́ ABOUT US > ACTIVITIES)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́