ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb18 November ojú ìwé 7
  • “Ẹ̀bùn Tá A Mú Dání Wá fún Jèhófà”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Ẹ̀bùn Tá A Mú Dání Wá fún Jèhófà”
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • A Dúpẹ́ Lọ́wọ́ Jèhófà Torí Ìfẹ́ Tẹ́ Ẹ̀ Ń Fi Hàn
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Ibo Làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Ti Ń Rówó Tí Wọ́n Ń Ná?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Ẹ̀bùn Wo La Lè Fún Jèhófà?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
  • ‘Ẹyọ Owó Kéékèèké Méjì’ Tó Níye Lórí
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
mwb18 November ojú ìwé 7

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ẹ̀bùn Tá A Mú Dání Wá fún Jèhófà

Ẹnì kan ń fi owó sínú àpótí ìjọ; ẹnì kan ń fi owó ṣètìlẹyìn látorí ìkànnì

Báwo lẹ́nì kan ṣe lè mú ẹ̀bùn dání wá fún Jèhófà lónìí? (1Kr 29:​5, 9, 14) Tá a bá fẹ́ fí ọrẹ àtinúwá ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń ṣe bóyá fún ìjọ tàbí fún iṣẹ́ kárí ayé, oríṣiríṣi ọ̀nà tó wà nísàlẹ̀ yìí la lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀.

ỌRẸ TÁ A FI RÁNṢẸ́ LÓRÍ ÌKÀNNÌ TÀBÍ ÈYÍ TÁ A FI SÍNÚ ÀPÓTÍ:

  • Ọrẹ fún iṣẹ́ kárí ayé

    IṢẸ́ KÁRÍ AYÉ

    a máa ń fi kọ́ ẹ̀ka ọ́fíìsì, ọ́fíìsì àwọn atúmọ̀ èdè, a sì máa ń fi tún wọn ṣe

    àwọn ilé ẹ̀kọ́ ètò Ọlọ́run

    àwọn tó wà nínú àkànṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún

    ìrànwọ́ fáwọn tí àjálù bá

    títẹ ìwé, fídíò àti àwọn ìtẹ̀jáde orí ìkànnì

  • Ọrẹ fún ìnáwó ìjọ

    ỌRẸ FÚN ÌNÁWÓ ÌJỌ

    àwọn ìnáwó ìjọ, irú bí owó iná, owó omi àti àtúnṣe Gbọ̀ngàn Ìjọba

    àwọn ìpinnu tí ìjọ ti ṣe láti fi iye owó kan pàtó ránṣẹ́ sí ètò Ọlọ́run fún:

    • kíkọ́ Gbọ̀ngàn Ìjọba àti Gbọ̀ngàn Àpéjọ kárí ayé

    • Ètò Ìrànwọ́ Kárí Ayé

    • àwọn iṣẹ́ kárí ayé míì

ÀWỌN ÀPÉJỌ ÀYÍKÁ ÀTI ÀGBÈGBÈ

A máa ń fi àwọn ọrẹ tá a ṣe nígbà àpéjọ àgbègbè ránṣẹ́ fún iṣẹ́ kárí ayé. Inú ọrẹ kárí ayé la ti máa ń mú owó tá a ná lórí àpéjọ àgbègbè, àkànṣe àpéjọ àti àpéjọ àgbáyé.

Àwọn ọrẹ tá a ṣe nígbà àpéjọ àyíká la máa ń fi sanwó ibi tá a ti ń ṣe àpéjọ, a máa ń fi tún ibẹ̀ ṣe, a sì fi ń ṣe àwọn nǹkan míì tó bá yẹ. Àyíká kan sì lè pinnu láti fi owó tó bá ṣẹ́ kù ránṣẹ́ sí ètò Ọlọ́run fún iṣẹ́ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà kárí ayé.

donate.jw.org

MỌ PÚPỌ̀ SÍI LÓRÍ ÌKÀNNÌ

Tó o bá fẹ́ mọ bó o ṣe lè ṣètọrẹ, lo ọ̀kan lára àwọn àbá tó wà nísàlẹ̀ yìí:

  • lọ sí ìkànnì yìí, donate.jw.org

  • yan “Ṣe Ìtọrẹ” ní abala Nípa Wa lórí ìkànnì jw.org/⁠yo

  • tẹ ìlujá “Donations” tó wà nísàlẹ̀ ètò ìṣiṣẹ́ JW Library

Láwọn orílẹ̀-èdè kan, àpilẹ̀kọ kan wà tá a pè ní “Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Máa Ń Béèrè.” Àpilẹ̀kọ yẹn dáhùn àwọn ìbéèrè táwọn èèyàn sábà máa ń béèrè nípa ọrẹ.

Fídíò náà, Bá A Ṣe Lè Fi Owó Ṣètìlẹ́yìn Látorí Íńtánẹ́ẹ̀tì, fún wa láwọn ìsọfúnni nípa oríṣiríṣi ọ̀nà tá a lè gbà ṣe ọrẹ.

ỌRẸ TÉÈYÀN WÉWÈÉ

Tẹ́nì kan bá fẹ́ ṣe àwọn ọrẹ kan fún iṣẹ́ kárí ayé, ó gba pé kó wéwèé ṣáájú tàbí kó mọ òfin tó wà fún irú ọrẹ bẹ́ẹ̀. Àwọn ọrẹ bíi:

  • ìwé ìhágún àti ohun ìní téèyàn fi síkàáwọ́ onígbọ̀wọ́

  • ilé àti ilẹ̀, ìpín ìdókòwò, ẹ̀tọ́ orí owó ìdókòwò àti ti ètò ẹ̀yáwó, àti owó ìbánigbófò

  • ọrẹ tó ṣeé gbà pa dà

Tó o bá fẹ́ lo ọ̀nà èyíkéyìí nínú wọn láti ṣe ọrẹ, lọ sí ìkànnì yìí, donate.jw.org, wà á rí bó o ṣe lè kàn sí ẹ̀ka ọ́fíìsì níbẹ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́