ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 9/1 ojú ìwé 7
  • Kí nìdí tá a fi ń wàásù?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí nìdí tá a fi ń wàásù?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Míì Tó Máa Ran Ìdílé Lọ́wọ́
    Jí!—2018
  • Ibo La Ti Lè Rí Ìdáhùn sí Àwọn Ìbéèrè Pàtàkì Nípa Ìgbésí Ayé?
    Ibo La Ti Lè Rí Ìdáhùn sí Àwọn Ìbéèrè Pàtàkì Nípa Ìgbésí Ayé?
  • Ohun Tó Máa Ràn Ẹ́ Lọ́wọ́ Láti Lóye Bíbélì
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I​—Bá A Ṣe Lè Lo Ìkànnì JW.ORG
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 9/1 ojú ìwé 7
Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà méjì ń wàásù ní àdúgbò táwọn èèyàn ń gbé

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | TA NI ÀWỌN ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ?

Kí nìdí tá a fi ń wàásù?

Ohun tí àwọn èèyàn fi ń dá àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà mọ̀ yàtọ̀ ni iṣẹ́ ìwàásù wa. A máa ń wàásù láti ilé dé ilé, níbi táwọn èèyàn pọ̀ sí àti níbikíbi tá a bá ti pàdé àwọn èèyàn. Kí nìdí tá a fi ń ṣe bẹ́ẹ̀?

Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń wàásù ká lè fi ògo fún Ọlọ́run, ká sì jẹ́ kí àwọn èèyàn mọ orúkọ rẹ̀. (Hébérù 13:15) A tún ń tẹ̀ lé àṣẹ Jésù Kristi pé: “Nítorí náà, ẹ lọ, kí ẹ sì máa sọ àwọn ènìyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn, . . . ẹ máa kọ́ wọn láti máa pa gbogbo ohun tí mo ti pa láṣẹ fún yín mọ́.”​—Mátíù 28:​19, 20.

Yàtọ̀ síyẹn, a tún nífẹ̀ẹ́ àwọn aládùúgbò wa. (Mátíù 22:39) A mọ̀ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ló ní ẹ̀sìn tiwọn àti pé kì í ṣe gbogbo èèyàn ló máa fẹ́ gbọ́ ọ̀rọ̀ wa. Àmọ́, ó dá wa lójú pé ọ̀rọ̀ Bíbélì ló máa jẹ́ ká rí ìgbàlà. Ìdí nìyẹn tí a fi ń bá a lọ “láìdábọ̀ ní kíkọ́ni àti pípolongo ìhìn rere nípa Kristi,” bíi tàwọn Kristẹni ìgbà ìjímìjí.​—Ìṣe 5:​41, 42.

Ọ̀gbẹ́ni Antonio Cova Maduro, sọ nípa “ìsapá àti akitiyan àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà pé wọ́n máa ń lo gbogbo okun wọn . . . , kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lè dé ibi gbogbo lórí ilẹ̀ ayé.”​—Ìwé ìròyìn El Universal, lórílẹ̀-èdè Venezuela

Ọ̀pọ̀ àwọn tó ń ka àwọn ìwé wa kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Ọ̀pọ̀ àwọn tá a sì ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló ní ẹ̀sìn tiwọn. Síbẹ̀, wọ́n mọyì bí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ń wá sọ́dọ̀ wọn.

Òótọ́ ni pé o lè ní àwọn ìbéèrè míì nípa àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà. A rọ̀ ẹ́ pé kó o wá ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè náà nípa ṣíṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí:

  • Béèrè lọ́wọ́ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà.

  • Lọ sórí ìkànnì wa, www.jw.org/yo.

  • Lọ sí àwọn ìpàdé wa. Gbogbo èèyàn ló lè wá, a kì í sì gbégbá owó.

Jésù rán àwọn ọmọlẹ́yìn méjì jáde láti wàásù
Òkè ńlá tí yìnyín ti bò

Tó o bá ń fẹ́ ìsọfúnni sí i nípa àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà, wo fídíò yìí Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà​—A Ṣètò Wa Láti Wàásù Ìhìn Rere, lórí ìkànnì www.jw.org/yo. (Wo abẹ́ ÀWỌN ÌTẸ̀JÁDE > ÀWỌN FÍDÍÒ)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́