ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp17 No. 1 ojú ìwé 4
  • Ibo Ni Mo Ti Fẹ́ Bẹ̀rẹ̀?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ibo Ni Mo Ti Fẹ́ Bẹ̀rẹ̀?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bó O Ṣe Lè Jàǹfààní Púpọ̀ Látinú Bíbélì
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Fi Ara Rẹ fún Ìwé Kíkà
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Jíjàǹfààní Láti Inú Bibeli Kíkà Lójoojúmọ́
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
  • Ìdí Tó Fi Ṣe Pàtàkì Pé Káwọn Ọmọdé Máa Kàwé—Apá Kìíní: Ìwé Kíkà Tàbí Ìran Wíwò?
    Ìrànlọ́wọ́ fún Ìdílé
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
wp17 No. 1 ojú ìwé 4

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | BÓ O ṢE LÈ RÍ Ẹ̀KỌ́ KỌ́ LÁTINÚ KÍKA BÍBÉLÌ

Ibo Ni Mo Ti Fẹ́ Bẹ̀rẹ̀?

Obìnrin tó ń gbàdúrà kó tó bẹ̀rẹ̀ síní ka Bíbélì

Àwọn ìgbésẹ̀ wo lo lè gbé táá jẹ́ kó o gbádùn Bíbélì kíkà, kó o sì jàǹfààní nínú rẹ̀? Wo àwọn àbá márùn-ún yìí tó ti ran ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́wọ́.

Jẹ́ kí ibi tó o wà tù ẹ́ lára. Wá ibi tó pa rọ́rọ́, kó o sì dín ohun tó lè pín ọkàn rẹ níyà kù, kó o lè pọkàn pọ̀ sórí ohun tí ò ń kà. Ó tún ṣe pàtàkì pé kí ìmọ́lẹ̀ àti afẹ́fẹ́ tó tura wà níbẹ̀, kí ohun tí ò ń kà lè wọ̀ ẹ́ lọ́kàn.

Ní èrò tó tọ́. Ọ̀dọ̀ Baba wa ọ̀run ni Bíbélì ti wá, torí náà kó o lè jàǹfààní nínú rẹ̀, á dára kó o ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ bí ọmọdé tó fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ látọ̀dọ̀ òbí tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀. Tó o bá ti ní èrò òdì nípa Bíbélì tẹ́lẹ̀, o ní láti gbé èrò náà tì sẹ́gbẹ̀ẹ́ kan, kí Ọlọ́run lè kọ́ ẹ.​—Sáàmù 25:4.

Kọ́kọ́ Gbàdúrà. Èrò Ọlọ́run ló wà nínú Bíbélì, ìdí nìyẹn tá a fi nílò ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ ká lè lóye ohun tí à ń kà. Ọlọ́run ti ṣèlérí láti “fi ẹ̀mí mímọ́ fún àwọn tí ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.” (Lúùkù 11:13) Ẹ̀mí mímọ́ yìí lè mú kó o mọ èrò Ọlọ́run lórí àwọn nǹkan. Tó bá yá, ẹ̀mí mímọ́ á ṣí ọkàn rẹ payá láti mọ “àwọn ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run.”​—1 Kọ́ríńtì 2:10.

Kà á lọ́nà tó fi máa yé ẹ. Má kàn máa ka Bíbélì lọ gbuurugbu. Máa dánu dúró kó o lè ronú lórí ohun tó o kà. Bí ara rẹ láwọn ìbéèrè bíi: ‘Ẹ̀kọ́ wo ni mo kọ́ lára ẹni tí mò ń kà nípa rẹ̀ yìí? Báwo ni mo ṣe lè fi ẹ̀kọ́ náà sílò nígbèésí ayé mi?’

Ní àfojúsùn kan. Kí Bíbélì kíkà tó lè ṣe ẹ́ láǹfààní, o yẹ kó o ní ohun kan lọ́kàn tó o fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀ tó máa wúlò fún ẹ nígbèésí ayé. O lè fi ṣe àfojúsùn rẹ pé: ‘Mo fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ sí i nípa Ọlọ́run fúnra rẹ̀.’ ‘Mo fẹ́ túbọ̀ ní ìwà tó dáa, táá jẹ́ kí n jẹ́ ọkọ tàbí ìyàwó rere.’ Lẹ́yìn náà, yan ẹsẹ Bíbélì tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ lórí kókó náà.a

Àwọn àbá márùn-ún tá a ti jíròrò yìí máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti bẹ̀rẹ̀ sí i kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Àmọ́, báwo lo ṣe lè mú kí Bíbélì kíkà náà gbádùn mọ́ ẹ? Àpilẹ̀kọ tó kàn máa ṣèrànwọ́.

a Tí o kò bá mọ ẹsẹ Bíbélì tó o máa kà lórí kókó kàn, inú àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa dùn láti ràn ẹ́ lọ́wọ́.

BÓ O ṢE LÈ JÀǸFÀÀNÍ PÚPỌ̀ SÍ I

  • Fara balẹ̀, kó o má sì kánjú

  • Jẹ́ kí ohun tí ò ń kà jinlẹ̀ lọ́kàn rẹ​—fọkàn yàwòrán pé o wà níbẹ̀

  • Gbìyànjú láti wo bí àwọn ẹsẹ náà ṣe bára mu

  • Wo ẹ̀kọ́ tó wà nínú ibi tó o kà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́