ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 6/98 ojú ìwé 1
  • “Tí A Mú Gbára Dì Pátápátá fún Iṣẹ́ Rere Gbogbo”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Tí A Mú Gbára Dì Pátápátá fún Iṣẹ́ Rere Gbogbo”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1998
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jèhófà ‘Ń Fi Àwọn Ọ̀rọ̀ Ìgbàgbọ́ Bọ́ Wa’
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Àwọn Ìpàdé Tó Ń Fún “Wa Níṣìírí Láti Ní Ìfẹ́ àti Láti Ṣe Àwọn Iṣẹ́ Rere”
    A Ṣètò Wa Láti Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà
  • Ǹjẹ́ O Ń Ṣe Ara Rẹ Láǹfààní?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Máa Jẹ Oúnjẹ Tẹ̀mí Tí Jèhófà Ń Pèsè fún Wa Lájẹyó
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1998
km 6/98 ojú ìwé 1

“Tí A Mú Gbára Dì Pátápátá fún Iṣẹ́ Rere Gbogbo”

1 Àwọn ènìyàn Jèhófà lónìí ni a fi ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ oúnjẹ dídọ́ṣọ̀ nípa tẹ̀mí bù kún. (Aísá. 25:6) Ọ̀pọ̀ àkójọ ọ̀rọ̀ tí a mú jáde láti inú Ìwé Mímọ́ ni ó wà tí a lè gbádùn nípasẹ̀ ìdákẹ́kọ̀ọ́ àti ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé àti ní àwọn ìpàdé ìjọ, àpéjọ, àti àpéjọpọ̀. Ṣùgbọ́n, a ha ń lo àǹfààní àwọn ìpèsè yìí lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ pẹ̀lú ète dídi ẹni tí ó “pegedé ní kíkún, tí a mú gbára dì pátápátá fún iṣẹ́ rere gbogbo” bí?—2 Tím. 3:17.

2 Ṣáà ronú nípa ìtòlẹ́sẹẹsẹ oúnjẹ tẹ̀mí fún ọdún 1998, èyí tí ó ti kọjá ìlàjì! Nípasẹ̀ àwọn ìpàdé ìjọ tí a ń ṣe lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀, a ń jíròrò mélòó kan nínú àwọn kókó ìtẹnumọ́ láti inú ìwé 23 nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì, a ń ṣàtúnyẹ̀wò ìsọfúnni tí ó wà nínú Awọn Akori Ọrọ Bibeli fun Ijiroro, a sì ń gbé àwọn kókó ẹ̀kọ́ tí a yàn láti inú àwọn ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ ti 1996 yẹ̀ wò. A tún ti ṣàtúnyẹ̀wò ìdá mẹ́ta ìwé Ìmọ̀, a ti fẹ́rẹ̀ẹ́ kárí ìwé Ayọ̀ Ìdílé, a sì ti kárí ìwé pẹlẹbẹ náà, Ète Igbesi-Aye àti Ọlọrun Ha Bikita Nipa Wa Niti Gidi Bi? látòkè délẹ̀. Ní àfikún sí i, a ń fi ìtẹ̀jáde Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa 12, àwọn àpilẹ̀kọ fún ìkẹ́kọ̀ọ́ Ilé Ìṣọ́ 52, àti onírúurú ọ̀rọ̀ àsọyé lórí kókó ẹ̀kọ́ inú Bíbélì tí ó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó 52 bọ́ wa. Àwọn ìtòlẹ́sẹẹsẹ àpéjọpọ̀ àti àpéjọ dídọ́ṣọ̀ tún jẹ́ àfikún sí gbogbo èyí. Àwọn ohun rere nípa tẹ̀mí tí a pèsè fún wa mà pọ̀ jaburata o!

3 Fi Ìmọrírì Hàn Fún Àwọn Ìpèsè Jèhófà: Kí a lè jàǹfààní lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́, ó yẹ kí a lóye ìdí tí Jèhófà fi pèsè ohun rẹpẹtẹ bẹ́ẹ̀ nípa tẹ̀mí. Fífi àwọn ohun rere wọ̀nyí bọ́ ara wa ń gbé ìgbàgbọ́ wa ró, ó sì ń fún ipò ìbátan wa pẹ̀lú rẹ̀ lókun. (1 Tím. 4:6) Àmọ́ ṣá o, a kò pèsè oúnjẹ tẹ̀mí kìkì fún ìtọ́ni wa nìkan. Ó ń sún wa láti ṣàjọpín òtítọ́ pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, ó sì ń mú wa gbára dì láti jẹ́ ẹni tí ó jáfáfá ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òjíṣẹ́ ìhìn rere.—2 Tím. 4:5.

4 Ẹ má ṣe jẹ́ kí a ṣàìnáání àìní wa nípa tẹ̀mí, ṣùgbọ́n kí a máa yán hànhàn nígbà gbogbo fún àwọn ìpèsè tẹ̀mí tí ó dọ́ṣọ̀, tí ó sì ń tẹ́ni lọ́rùn, tí ń wá láti orí tábìlì Jèhófà. (Mát. 5:3; 1 Pét. 2:2) Láti jàǹfààní lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ ń béèrè pé kí a ya àkókò tí ó pọ̀ tó sọ́tọ̀ fún irú àwọn nǹkan pàtàkì bí ìdákẹ́kọ̀ọ́ àti ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ìdílé àti lílọ sí ìpàdé déédéé. (Éfé. 5:15, 16) Àwọn èrè tí ń múni láyọ̀ fún ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìṣírí tí a mí sí tí Pọ́ọ̀lù kọ sí àwọn Hébérù olùṣòtítọ́ tí wọ́n jẹ́ Kristẹni, gẹ́gẹ́ bí a ṣe kọ ọ́ sínú Hébérù 13:20, 21.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́