ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/05 ojú ìwé 1
  • Jèhófà ‘Ń Fi Àwọn Ọ̀rọ̀ Ìgbàgbọ́ Bọ́ Wa’

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jèhófà ‘Ń Fi Àwọn Ọ̀rọ̀ Ìgbàgbọ́ Bọ́ Wa’
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Tí A Mú Gbára Dì Pátápátá fún Iṣẹ́ Rere Gbogbo”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1998
  • Ìpàdé Máa Ń Ṣe Àwọn Ọ̀dọ́ Láǹfààní
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Ìwọ Ha Ń Jẹun Kánú Nípa Tẹ̀mí Bí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • “Ó Ń Fi Agbára fún Ẹni Tí Ó Ti Rẹ̀”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
km 1/05 ojú ìwé 1

Jèhófà ‘Ń Fi Àwọn Ọ̀rọ̀ Ìgbàgbọ́ Bọ́ Wa’

1 Ó gba ìsapá gidi kéèyàn tó lè jẹ́ olùbẹ̀rù Ọlọ́run kó sì máa bá a lọ bẹ́ẹ̀ nígbèésí ayé. (1 Tím. 4:7-10) Bí a bá gbójú lé agbára wa, kò ní pẹ́ tó fi máa rẹ̀ wá tá a ó sì ṣubú. (Aísá. 40:29-31) Ọ̀nà kan tá a fi lè gba okun látọ̀dọ̀ Jèhófà ni pé ká jẹ́ ẹni “tí a fi àwọn ọ̀rọ̀ ìgbàgbọ́ bọ́.”—1 Tím. 4:6.

2 Oúnjẹ Tẹ̀mí Tó Ń Fúnni Lókun: Jèhófà ń tipasẹ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ àti “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” pèsè oúnjẹ tẹ̀mí tó ń fúnni lókun. (Mát. 24:45) Ǹjẹ́ à ń ṣe ohun tó yẹ ká ṣe káwọn oúnjẹ yẹn lè ṣe wá lóore? Ṣé a kì í jẹ́ kí ọjọ́ kan lọ láìjẹ́ pé a ka Bíbélì? Ǹjẹ́ a ní àkókò kan tá a yà sọ́tọ̀ láti máa fi dá kẹ́kọ̀ọ́ àti láti máa fi ṣàṣàrò? (Sm. 1:2, 3) Irú àwọn oúnjẹ tẹ̀mí tó ń fúnni lókun yìí máa ń fún wa lókun, kì í sì í jẹ́ kí ayé Sátánì rí wa gbéṣe. (1 Jòh. 5:19) Tí a bá ń fọkàn wa ro àwọn ohun tó tọ́ tá a sì ń hù ú níwà nígbà gbogbo, Jèhófà á dúró tì wá.—Fílí. 4:8, 9.

3 Ìpàdé ìjọ tún jẹ́ ọ̀nà mìíràn tí Jèhófà gbà ń fún wa lókun. (Héb. 10:24, 25) Ìtọ́ni tẹ̀mí tá a ń rí gbà láwọn ìpàdé wọ̀nyí àti ìbákẹ́gbẹ́pọ̀ tó gbámúṣé tá a ń ní níbẹ̀ ń jẹ́ ká lè dúró ṣinṣin lásìkò ìṣòro. (1 Pét. 5:9, 10) Ọ̀dọ́ kan tó jẹ́ Kristẹni sọ pé: “Kò sọ́jọ́ tí mo lọ síléèwé tí kì í ṣe pé ìrẹ̀wẹ̀sì ni màá bá bọ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ìpàdé ìjọ wa yàtọ̀, ńṣe ló dà bí ibòji nínú oòrùn ọ̀sán ganrínganrín, nítorí ó ń jẹ́ kí n ní ìbàlẹ̀ ọkàn láti lè kojú wàhálà iléèwé lọ́jọ́ kejì.” Ẹ ò rí i pé ìbùkún ńlá gbáà là ń rí gbà bá a ti ń sapá láti wà ní gbogbo ìpàdé!

4 Máa Polongo Òtítọ́: Iṣẹ́ ìwàásù dà bí oúnjẹ lójú Jésù, nítorí pé ó máa ń fún un lókun. (Jòh. 4:32-34) Lọ́nà kan náà, ara wa máa ń yá gágá nígbà tá a bá ń sọ àwọn àgbàyanu ìlérí Ọlọ́run fáwọn ẹlòmíràn. Dídí tọ́wọ́ wa ń dí nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ tún ń jẹ́ ká lè túbọ̀ pọkàn pọ̀ sórí Ìjọba Ọlọ́run àti àwọn ìbùkún tó máa mú wá fún wa láìpẹ́. Ká sòótọ́, ó máa ń sọ agbára wa dọ̀tun.—Mát. 11:28-30.

5 Àǹfààní ńlá la ní o pé à ń jẹ oúnjẹ tẹ̀mí tó ń fúnni lókun tí Jèhófà ń pèsè fáwọn èèyàn rẹ̀ lónìí! Nítorí náà, títí láé ni kẹ́ ẹ jẹ́ ká máa fi ìdùnnú polongo òtítọ́ láti fi yìn ín.—Aísá. 65:13, 14.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́