ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/00 ojú ìwé 1
  • “Àwọn Obìnrin Tí Ń Ṣiṣẹ́ Kára Nínú Olúwa”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Àwọn Obìnrin Tí Ń Ṣiṣẹ́ Kára Nínú Olúwa”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Awọn Obinrin Ti Wọn Nṣiṣẹ Kára Ninu Oluwa”
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Ẹ Máa Fún Àwọn Arábìnrin Níṣìírí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Ṣé Ojú Tí Jèhófà Fi Ń Wo Àwọn Obìnrin Lo Fi Ń Wò Wọ́n?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2024
  • Àwọn Obìnrin Kristẹni Olóòótọ́ Jẹ́ Ẹni Ọ̀wọ́n Tó Ń Sin Ọlọ́run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
km 1/00 ojú ìwé 1

“Àwọn Obìnrin Tí Ń Ṣiṣẹ́ Kára Nínú Olúwa”

1 Pọ́ọ̀lù lo àwọn ọ̀rọ̀ tó wà lókè yìí láti ṣàpèjúwe Tírífénà àti Tírífósà, àwọn arábìnrin méjì tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́kára nínú ìjọ Róòmù. Ó tún sọ nípa obìnrin mìíràn tí ń jẹ́ Pésísì pé: “Ó ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ òpò nínú Olúwa.” Bákan náà, ó sọ̀rọ̀ Fébè dáadáa pé ó jẹ́ “olùgbèjà fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.” (Róòmù 16:2, 12) Nínú Ìwé Mímọ́, a fi Dọ́káàsì hàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tó “pọ̀ gidigidi nínú àwọn iṣẹ́ rere àti àwọn ẹ̀bùn àánú.” (Ìṣe 9:36) Ìbùkún gidi mà ni irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀, tí wọ́n jẹ́ ẹni tẹ̀mí, jẹ́ fún ìjọ o!

2 Ǹjẹ́ a mọrírì àwọn arábìnrin tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ kára nínú ìjọ wa? Àwọn ló ń ṣe apá tó pọ̀ jù lọ nínú iṣẹ́ ìwàásù, àwọn ló ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó pọ̀ jù lọ, wọ́n sì ń ran ọ̀pọ̀ ẹni tuntun lọ́wọ́. Wọ́n tún ń lo àkókò púpọ̀ láti ran àwọn ọmọdé lọ́wọ́, kí wọ́n lè tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí. Àwọn obìnrin Kristẹni ń ṣe ipa tiwọn láti gbé ẹ̀mí ìfẹ́, ayọ̀, àlàáfíà, àti ìtara ró nínú ìjọ. Wọ́n máa ń ṣètìlẹ́yìn lọ́pọ̀lọpọ̀ ọ̀nà kí ọkọ wọn àti àwọn mẹ́ńbà ìdílé wọn lè ṣe púpọ̀ sí i nínú iṣẹ́ ìsìn Jèhófà.

3 Àwọn Arábìnrin Tó Ń Ṣe Iṣẹ́ Ìsìn Alákòókò Kíkún: Àwọn arábìnrin tí wọ́n jẹ́ míṣọ́nnárì wà lára àwọn tí ń ṣiṣẹ́ kára nínú Olúwa, ọ̀pọ̀ ti kópa nínú mímú kí iṣẹ́ náà gbèrú ní àwọn ilẹ̀ òkèèrè. Nínú àwọn ìjọ tí àwọn ọkọ wọn ń bẹ̀ wò, aya àwọn alábòójútó arìnrìn-àjò máa ń kún fún iṣẹ́ pẹrẹwu nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ pápá, wọ́n a sì máa fún ọ̀pọ̀ arábìnrin níṣìírí. A ò gbọ́dọ̀ gbàgbé àwọn arábìnrin tó wà ní Bẹ́tẹ́lì, tí wọ́n ń fi ìtara ṣe iṣẹ́ ìsìn ọlọ́wọ̀ ní ìtìlẹyìn fún ètò àjọ Jèhófà. Àwọn arábìnrin wa tí wọ́n jẹ́ aṣáájú ọ̀nà déédéé náà wà níbẹ̀ o, wọ́n ń ran ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyàn lọ́wọ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́, nípasẹ̀ ìsapá tí wọ́n ń fi òótọ́ ọkàn ṣe nínú yíyin Ọlọ́run.

4 Àwọn arábìnrin olùṣòtítọ́ wọ̀nyí ń rí ìtẹ́lọ́rùn púpọ̀ nínú ọ̀nà ìgbésí ayé ìfara-ẹni-rúbọ tí wọ́n ń tọ̀. (1 Tím. 6:6, 8) Wọ́n yẹ lẹ́ni tí a ń gbóríyìn fún, wọ́n sì yẹ fún ìṣírí àti ìtìlẹ́yìn èyíkéyìí tí a bá lè fún wọn.

5 Gbogbo obìnrin Kristẹni ló wúlò gidigidi fún ètò àjọ Jèhófà, wọ́n ń fi òótọ́ ọkàn ṣe iṣẹ́ ìsìn tó jẹ́ ìbùkún fún gbogbo wa. Ẹ jẹ́ kí a máa bá a nìṣó láti mọrírì irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀, kí a sì máa gbàdúrà pé kí ìbùkún Jèhófà máa bá wọn bí wọ́n ṣe ń bá a nìṣó láti máa “ṣiṣẹ́ kára nínú Olúwa.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́