ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 10/01 ojú ìwé 8
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
km 10/01 ojú ìwé 8

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ilé Ìṣọ́ Oct. 15

“Kí la máa ṣe láti sọ ayé di ibi kan tó sàn jù, tí ayọ̀ kún inú rẹ̀? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Ẹ̀dá èèyàn ti gbìyànjú ìjọba kan tẹ̀ lé òmíràn láti mú nǹkan sunwọ̀n sí i. Ṣùgbọ́n kíyè sí èrò Ọlọ́run nípa èyí. [Ka Jeremáyà 10:23.] Àpilẹ̀kọ yìí sọ ‘Ohun Náà Gan-an Tó Máa Mú Ayé Aláyọ̀ Wá,’ ó sì fi bí èyí ṣe máa tó wáyé hàn.”

Jí! Nov. 8

“Ǹjẹ́ o gbà pé pákáǹleke túbọ̀ ń bá aráyé lónìí ju ti ìgbàkígbà rí lọ? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Bíbélì sọ àsọtẹ́lẹ̀ èyí. [Ka 2 Tímótì 3:1.] Ọ̀pọ̀ èèyàn ni ìgbésí ayé máa ń ṣòro fún débi pé wọ́n máa ń sọ̀rètí nù. Ìwé ìròyìn yìí fúnni ní ìṣírí gan-an ni. Ó ṣàlàyé béèyàn ṣe lè bọ́ lọ́wọ́ àìnírètí kí ó sì jẹ́ kí ìgbésí ayé gbádùn mọ́ òun.”

Ilé Ìṣọ́ Nov. 1

Lẹ́yìn tí o bá ti sọ ìròyìn kan tó ń dani láàmù, béèrè pé: “Kí nìdí táwọn èèyàn fi ń ṣe irú ohun búburú bẹ́ẹ̀? Gbogbo wa ló yẹ ká mọ ìyàtọ̀ láàárín rere àti búburú, ṣùgbọ́n àwọn èèyàn ṣì ń ṣe àwọn nǹkan búburú síbẹ̀. Kí ló fà á? [Lẹ́yìn tí ó bá fèsì, ka Ìṣípayá 12:9.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bí a ṣe lè dáàbò bo ara wa nípa fífi ìṣọ́ ṣọ́ ẹ̀rí ọkàn wa.”

Jí! Nov. 8

“Ìwọ náà á gbà pé àkókò oníwà ipá la ń gbé yìí. [Lẹ́yìn tí ó bá fèsì, ka 2 Tímótì 3:3.] Ọ̀pọ̀ ìgbà ni ìwà ‘òǹrorò’ máa ń wáyé kódà nínú agbo ìdílé pàápàá. Àpilẹ̀kọ yìí tí a pè ní, ‘Ìrànwọ́ fún Àwọn Obìnrin Tí Ọkọ Wọn Ń Lù,’ sọ ọ̀rọ̀ tó kún fún ìrètí. Ó ṣeé ṣe kí o mọ ẹni tó lè jàǹfààní látinú rẹ̀.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́