ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/03 ojú ìwé 8
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
km 1/03 ojú ìwé 8

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ilé Ìṣọ́ Jan. 15

“Lójú gbogbo ìtàjẹ̀sílẹ̀ tó ń ṣẹlẹ̀ báyìí, ǹjẹ́ o ronú pé ibi ti borí ire? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Gbọ́ ohun tí Bíbélì sọ nípa Ọlọ́run. [Ka Sáàmù 83:18b.] Níwọ̀n bí Ọlọ́run ti jẹ́ Ẹni Gíga Jù Lọ lórí ilẹ̀ ayé, ṣé lóòótọ́ ni ibi lè borí? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Ìtẹ̀jáde Ilé Ìṣọ́ yìí pèsè ìdáhùn tí ń tẹ́ni lọ́rùn sí ìbéèrè yẹn.”

Ilé Ìṣọ́ Feb. 1

“Ọ̀pọ̀ èèyàn lónìí ló ń ṣàníyàn nítorí àìníṣẹ́lọ́wọ́, ìnira tí àwọn mìíràn sì ń rí lẹ́nu iṣẹ́ kì í ṣe kékeré rárá. Ǹjẹ́ o rò pé ó ṣeé ṣe láti ní ìfọ̀kànbalẹ̀ àti ayọ̀ lẹ́nu iṣẹ́? [Jẹ́ kí ó fèsì. Lẹ́yìn náà ka Aísáyà 65:21-23.] Ìtẹ̀jáde Ilé Ìṣọ́ yìí sọ̀rọ̀ nípa àkókò kan nígbà tí gbogbo èèyàn yóò máa ṣe iṣẹ́ tó lérè nínú.”

Jí! Feb. 8

“Kò tíì sí ìgbà kankan nínú ìtàn tí ààbò àwa èèyàn wà nínú ewu tó ti àkókò yìí. Ohun kan tó tún ń ba àwọn èèyàn lẹ́rù báyìí ni ìṣòro bí wọ́n ṣe máa ń jí àwọn nǹkan ìdánimọ̀ ẹni. Ǹjẹ́ o ti gbọ́ nípa ìyẹn? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Bíbélì ṣèlérí pé lọ́jọ́ kan, ayé wa yìí máa bọ́ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ohun tí kò jẹ́ ká ní ìfọ̀kànbalẹ̀. [Ka Aísáyà 11:9.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bí èyí yóò ṣe rí bẹ́ẹ̀.”

“Ìtẹ̀jáde Jí! yìí sọ̀rọ̀ nípa nǹkan ìbànújẹ́ kan tó ń ṣẹlẹ̀ lákòókò wa yìí, ìyẹn ni kí àwọn ọmọdé máa ṣe iṣẹ́ aṣẹ́wó. Lílo àwọn ọmọdé lọ́nà tó ń bani nínú jẹ́ yìí jẹ́ ohun kan tí Bíbélì ṣèlérí pé ó máa tó dópin. [Ka Òwe 2:21, 22.] Ìwé ìròyìn yìí sọ ohun tó ń mú kí àwọn èèyàn máa ṣe àwọn ọmọdé níṣekúṣe bẹ́ẹ̀ àti bí òpin yóò ṣe dé bá a.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́