Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
Ile Iṣọ Jan. 15
“Gbogbo wa là ń fẹ́ kí ayé wa àti tàwọn ọmọ wa dùn bí oyin ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ èèyàn rò pé èyí kọjá agbára àwọn láti ṣe. Ǹjẹ́ o gbà pé a lè pinnu bí ọjọ́ ọ̀la wa yóò ṣe rí? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí fi hàn wá látinú Bíbélì pé ọwọ́ wa ló wà, nítorí ohun tá a bá fòní ṣe ló máa pinnu bí ọjọ́ ọ̀la wa á ṣe rí.” Ka Diutarónómì 30:19.
Ile Iṣọ Feb. 1
“Ǹjẹ́ kì í bani lọ́kàn jẹ́ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ni wọ́n ń rẹ́ jẹ tí wọ́n sì ń fojú wọn gbolẹ̀? [Mẹ́nu kan ohun kan tó ṣẹlẹ̀ lágbègbè yín láìpẹ́ yìí, kó o sì jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí sọ̀rọ̀ nípa ojú tí Ọlọ́run fi ń wo ẹ̀mí èèyàn. Ó tún ṣàlàyé bó ṣe máa gbà wá lọ́wọ́ ìyà tó ń jẹ aráyé lónìí.” Ka Sáàmù 72:12-14.
Jí Feb. 8
“Gbogbo wa la máa ń mọyì dókítà tó bá fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lé tọ́jú wa nígbà tá a bá ń ṣàìsàn. Ṣùgbọ́n ńjẹ́ o ró pé ọ̀pọ̀ aláìsàn ń ro ti àwọn dókítà mọ́ tiwọn? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí sọ̀rọ̀ nípa ìṣòro àwọn dókítà àti ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí iṣẹ́ ìṣègùn lọ́jọ́ iwájú.” Ka Aísáyà 33:24.
“Lóde òní, ọ̀kan lára ohun tó jẹ́ ìṣòro ńlá fáwọn èèyàn ni bí wọ́n ṣe máa dín pákáǹleke kù. Àbí o ò gbà bẹ́ẹ̀? [Jẹ́ kó fèsì.] Bíbélì ti sọ pé bó ṣe máa rí nìyẹn. [Ka 2 Tímótì 3:1.] Ìwé ìròyìn yìí dá àwọn àbá kan tó lè ran ìwọ àti ìdílé rẹ lọ́wọ́ láti dín pákáǹleke kù.”