ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 11/10 ojú ìwé 4
  • Àpótí Ìbéèrè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àpótí Ìbéèrè
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Ìbùkún Tó Wà Nínú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Aṣáájú Ọ̀nà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Wọ́n Ti Fi Àpẹẹrẹ Ìṣòtítọ́ Lélẹ̀
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ìyípadà Nínú Iye Wákàtí Tí A Ń Béèrè Lọ́wọ́ Àwọn Aṣáájú Ọ̀nà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
  • Ẹ Máa Rántí Àwọn Tó Ń Ṣe Iṣẹ́ Ìsìn Alákòókò Kíkún
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
km 11/10 ojú ìwé 4

Àpótí Ìbéèrè

◼ Kí la lè ṣe láti ran àwọn aṣáájú-ọ̀nà lọ́wọ́?

Kárí ayé, ní ọdún iṣẹ́ ìsìn 2009, àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin tó ṣiṣẹ́ sìn gẹ́gẹ́ bí aṣáájú-ọ̀nà déédéé àti aṣáájú-ọ̀nà àkànṣe fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ogójì ọ̀kẹ́ [800,000]. Àwọn òjíṣẹ́ alákòókò-kíkún yìí ti yọ̀ǹda ohun tá a lè pè ní àkọ́so nínú àkókò, okun àtàwọn ohun ìní wọn, kí wọ́n bàa lè tan ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run kálẹ̀. (Òwe 3:9) Ó dájú pé inú Jèhófà ń dùn sí wọn gan-an bí wọ́n ṣe ń sapá yìí. Àwọn ọ̀nà wo làwa náà lè gbà fi hàn pé inú wa dùn sí àwọn aṣáájú-ọ̀nà, ká sì tipa bẹ́ẹ̀ fi kún ayọ̀ àti ìfaradà wọn lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn?

Ó dájú pé bá a bá ń sọ̀rọ̀ tó ń gbéni ró, èyí lè fún wọn ní ìṣírí táá jẹ́ kí wọ́n lè máa bá iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà nìṣó. (Òwe 25:11) Ǹjẹ́ a lè ṣe àwọn ìyípadà kan nínú ìgbòkègbodò wa ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ká bàa lè ṣiṣẹ́ pẹ̀lú wọn lóde ẹ̀rí? Láwọn ìgbà míì, a lè fi ọkọ̀ wa gbé wọn tàbí ká san owó ọkọ̀ wọn. (1 Kọ́r. 13:5; Fílí. 2:4) Ọ̀nà míì tá a tún lè gbà fi hàn pé tìfẹ́tìfẹ́ la fi ń ṣètìlẹ́yìn fún wọn ni pé, ká máa pe àwọn aṣáájú-ọ̀nà wá sílé wa lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan láti wá bá wa jẹun.—1 Pét. 4:8, 9.

Ìwé Mímọ́ fi dá wa lójú pé Jèhófà máa pèsè àwọn ohun kòṣeémánìí fún àwọn tó bá wá Ìjọba rẹ̀ lákọ̀ọ́kọ́. (Sm. 37:25; Mát. 6:33) Ọ̀kan lára ọ̀nà tí Jèhófà gbà ń ṣe èyí ni pé ó máa ń lo ẹgbẹ́ ará Kristẹni láti ṣèrànwọ́. (1 Jòh 3:16-18) Ohun kan ni pé, àwọn aṣáájú-ọ̀nà kò retí pé kí àwọn ẹlòmíì máa gbọ́ bùkátà àwọn. Ó sì ṣeé ṣe kí wọ́n má sọ ohun tí wọ́n nílò fáwọn ẹlòmíì. Síbẹ̀, a lè bá àwọn aṣáájú-ọ̀nà tó ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ sìn yìí “dí àìnító wọn” láwọn ọ̀nà tó gbéṣẹ́ tá a bá ń wà lójúfò tá a sì lákìíyèsí.—2 Kọ́r. 8:14, 15.

Nígbà tí Fébè ajíhìnrere onítara kan ní ìjọ Kẹnkíríà ọ̀rúndún kìíní rìnrìn àjò lọ sí ìlú Róòmù, Pọ́ọ̀lù gba àwọn ará tó wà ní ìlú Róòmù níyànjú pé: ‘Ẹ fi inú dídùn tẹ́wọ́ gbà á nínú Olúwa lọ́nà tí ó yẹ àwọn ẹni mímọ́, kí ẹ sì ṣèrànwọ́ fún un nínú ọ̀ràn èyíkéyìí tí ó ti lè nílò yín.’ (Róòmù 16:1, 2) Àǹfààní ló jẹ́ fún àwa pẹ̀lú láti fi ìfẹ́ ṣètìlẹ́yìn fún àwọn tó wà nínú ìjọ wa tí wọ́n ń wàásù ìhìn rere láìdábọ̀, ìyẹn àwọn aṣáájú-ọ̀nà déédéé àtàwọn aṣáájú-ọ̀nà àkànṣe.—Ìṣe 5:42.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́