ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 10/14 ojú ìwé 2
  • Bí A Ṣe Lè Ṣàlàyé Ohun Tá A Gbà Gbọ́ Nípa Ọdún 1914

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bí A Ṣe Lè Ṣàlàyé Ohun Tá A Gbà Gbọ́ Nípa Ọdún 1914
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìgbà Wo Ni Ìjọba Ọlọ́run Bẹ̀rẹ̀?—APÁ 2
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Ìgbà Wo Ni Ìjọba Ọlọ́run Bẹ̀rẹ̀?—Apá 1
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn Nígbà Gbogbo”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
km 10/14 ojú ìwé 2

ẸṢIN Ọ̀RỌ̀ OṢÙ YÌÍ: “WÀÁSÙ Ọ̀RỌ̀ NÁÀ, WÀ LẸ́NU RẸ̀ NÍ KÁNJÚKÁNJÚ.”—2 TÍM. 4:2.

Bí A Ṣe Lè Ṣàlàyé Ohun Tá A Gbà Gbọ́ Nípa Ọdún 1914

Ìwé Mímọ́ gbà wá níyànjú pé kí á “wà ní ìmúratán nígbà gbogbo láti ṣe ìgbèjà” ìgbàgbọ́ wa, ‘kí a sì máa ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú inú tútù àti ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀.’ (1 Pét. 3:15) Ká sòótọ́, ó lè máà rọrùn láti ṣàlàyé àwọn òtítọ́ Bíbélì tó jinlẹ̀, irú bí a ṣe mọ̀ pé Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso lọ́dún 1914. Ká lè mọ bí a ṣe lè ṣàlàyé ohun tá a gbà gbọ́, a ti ṣe ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ alápá méjì kan tá a pe àkòrí rẹ̀ ní, “Ìjíròrò Láàárín Ẹlẹ́rìí Jèhófà àti Ẹnì Kan—Ìgbà Wo Ni Ìjọba Ọlọ́run Bẹ̀rẹ̀?” Àwọn àpilẹ̀kọ yìí wà nínú ẹ̀dà Ilé Ìṣọ́ tá a máa fi lọni lóṣù October àti November. Bí o ṣe ń ṣàyẹ̀wò àwọn àpilẹ̀kọ yìí, wo àwọn ìbéèrè tó wà nísàlẹ̀ yìí nípa ọ̀nà tí Kọ́lá tó jẹ́ akéde nínú àpilẹ̀kọ náà gbà ṣàlàyé ohun tó gbà gbọ́.

Báwo ló ṣe . . .

  • gbóríyìn fún ẹni tó ń bá sọ̀rọ̀ lọ́nà tí yóò fi nífẹ̀ẹ́ sóhun tó fẹ́ sọ?—Ìṣe 17:22.

  • fi ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ hàn nígbà tó ń ṣàlàyé ohun tó gbà gbọ́?—Ìṣe 14:15.

Kí nìdí tó fi dáa bó ṣe ń . . .

  • ṣe àkópọ̀ ohun tó sọ lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan kí ó tó ṣe àwọn àlàyé míì?

  • dánu dúró lóòrèkóòrè tó sì ń béèrè bóyá onílé náà lóye àlàyé tó ń ṣe fún un?

  • ṣe àlàyé tó mọ níwọ̀n, tí kò máa da ọ̀rọ̀ sílẹ̀ wuuruwu nígbà tó ń bá onílé sọ̀rọ̀?—Jòh. 16:12.

A mà dúpẹ́ gan-an lọ́wọ́ Jèhófà ‘Olùkọ́ni wa Atóbilọ́lá’ o, fún bó ṣe ń kọ́ wa ní ọ̀nà tá a lè gbà ṣàlàyé àwọn òtítọ́ Bíbélì tó jinlẹ̀ fún àwọn tí ebi òtítọ́ ń pa!—Aísá. 30:20.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́