ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb17 June ojú ìwé 3
  • Gbogbo Ọ̀rọ̀ Jèhófà Máa Ń Ṣẹ Láìkù Síbì Kan

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Gbogbo Ọ̀rọ̀ Jèhófà Máa Ń Ṣẹ Láìkù Síbì Kan
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìsìn Èké—Ìran Fi Hàn Pé Yóò Lọ Láú
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
  • Jèhófà Tẹ́ Ìlú Agbéraga
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
  • Ìwé Àsọtẹ́lẹ̀
    Ìwé kan tí ó Wà fún Gbogbo Ènìyàn
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
mwb17 June ojú ìwé 3

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | JEREMÁYÀ 51-52

Gbogbo Ọ̀rọ̀ Jèhófà Máa Ń Ṣẹ Láìkù Síbì Kan

Jèhófà sọ bí àwọn nǹkan ṣe máa rí gẹ́lẹ́ lọ́jọ́ iwájú

Èṣọ́ ààfin Páṣíà kan tó jẹ́ tafàtafà

Èṣọ́ ààfin Páṣíà kan tó jẹ́ tafàtafà

“Ẹ dán ọfà”

51:11, 28

  • Tafàtafà tó jẹ́ atamátàsé làwọn ará Mídíà àti Páṣíà, ọrun sì ni olórí ohun ìjà wọn. Wọ́n máa ń dán ọfà wọn dáadáa kó bàa lè rọrùn láti wọlé síni lára

“Àwọn alágbára ńlá Bábílónì ti ṣíwọ́ ìjà”

51:30

  • Ìwé ìtàn kan tó ń jẹ́ Nabonidus Chronicle sọ pé: “Wọ́ọ́rọ́wọ́ ni àwọn ọmọ ogun Kírúsì wọnú ìlú Bábílónì.” Ó ṣeé ṣe kí èyí túmọ̀ sí pé àwọn ará Bábílónì kò bá wọn fa wàhálà, èyí sì bá àsọtẹ́lẹ̀ Jeremáyà mu

Ìwé ìtàn Nabonidus Chronicle

Ìwé ìtàn Nabonidus Chronicle

‘Bábílónì yóò sì di ìtòjọpelemọ òkúta, yóò di ahoro fún àkókò tí ó lọ kánrin’

51:37, 62

  • Láti ọdún 539 ṣáájú Sànmánì Kristẹni ni ògo Bábílónì ti bẹ̀rẹ̀ sí í wọmi. Alẹkisáńdà Ńlá gbèrò láti fi ìlú Bábílónì ṣe olú ìlú rẹ̀, àmọ́ ńṣe ló kú lójijì. Nígbà tí ẹ̀sìn Kristẹni bẹ̀rẹ̀, àwọn Júù kan ń gbé Bábílónì, ìyẹn ló mú kí àpọ́sítélì Pétérù máa lọ ṣèbẹ̀wò síbẹ̀. Àmọ́ nígbà tó fi máa di ọgọ́rùn-ún ọdún kẹrin Sànmánì Kristẹni, ìlú yẹn ti pa run pátápátá, ó sì ti ròkun ìgbàgbé

    Àtẹ kan tó jẹ́ ká rí ìgbà tí wọ́n pa Bábílónì run, ìgbà tí Alẹkisáńdà Ńlá kú, ìgbà tí Pétérù wà ní Bábílónì, àti ìgbà tí Bábílónì dahoro

Ipa wo ló yẹ kí àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì tó ṣẹ ní lórí mi?

Kí ni mo lè kọ́ àwọn míì nípa àwọn àsọtẹ́lẹ̀ yìí?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́