MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Ṣé O Máa Ń Rí Àwọn Ànímọ́ Ọlọ́run Tí A Kò Lè Rí?
Tó o bá wo àwọn òdòdó tó rẹwà, ìràwọ̀ ojú ọ̀run tàbí àrágbáyamúyamù omi tó ń tú yaa látinú àpáta, ṣé o máa ń rí i pé iṣẹ́ ọwọ́ Ẹlẹ́dàá ni wọ́n? Àwọn ìṣẹ̀dá tó yí wa ká jẹ́ ká rí àwọn ànímọ́ Jèhófà lọ́nà tó ṣe kedere. (Ro 1:20) Tá a bá ń ronú jinlẹ̀ lórí àwọn nǹkan tá à ń rí, a máa rí i pé alágbára ni Ọlọ́run, ó nífẹ̀ẹ́ wa, ó gbọ́n, onídàájọ́ òdodo ni, ọ̀làwọ́ sì ni.—Sm 104:24.
Àwọn iṣẹ́ ọwọ́ Jèhófà wo lo máa ń rí lójoojúmọ́? Kódà tó bá tiẹ̀ jẹ́ pé ibi tó ti lajú gan-an lò ń gbé, o ṣì máa rí àwọn ẹyẹ àtàwọn igi lóríṣiríṣi. Tá a bá ń wo àwọn nǹkan tí Jèhófà dá, àníyàn wa máa dín kù, àwọn ìṣòro wa ò ní gbà wá lọ́kàn jù, a sì máa túbọ̀ nígbàgbọ́ pé Jèhófà ò ní fi wá sílẹ̀ láé. (Mt 6:25-32) Tó o bá ní àwọn ọmọ, ràn wọ́n lọ́wọ́ kí àwọn náà lè máa rí àwọn ànímọ́ Jèhófà tí kò láfiwé. Bá a ṣe túbọ̀ ń mọyì àwọn nǹkan tí Ọlọ́run dá náà, làá máa túbọ̀ sún mọ́ Ẹlẹ́dàá wa.—Sm 8:3, 4.
WO FÍDÍÒ NÁÀ ÀWỌN ÌṢẸ̀DÁ ỌLỌ́RUN Ń FI ÒGO RẸ̀ HÀN—ÌMỌ́LẸ̀ ÀTI ÀWỌ̀, LẸ́YÌN NÁÀ, DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
Kí ló máa ń jẹ́ ká rí oríṣiríṣi àwọ̀?
Kí nìdí tí àwọn àwọ̀ kan ṣe máa ń yí pa dà tá a bá wò ó láti ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀?
Kí nìdí tá a fi máa ń rí oríṣiríṣi àwọ̀ lójú ọ̀run?
Àwọn àwọ̀ tó o fẹ́ràn wo lo ti rí lára àwọn ìṣẹ̀dá Ọlọ́run tó wà nítòsí ilé rẹ?
Kí nìdí tó fi yẹ ká máa wáyè wo àwọn nǹkan tí Ọlọ́run dá?
Kí ni ìmọ́lẹ̀ àti àwọ̀ jẹ́ ká mọ̀ nípa àwọn ànímọ́ Jèhófà?