ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb19 April ojú ìwé 8
  • Ẹ̀kọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ni Kó O Máa Lé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹ̀kọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ni Kó O Máa Lé
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bí A Ṣe Ń Dá Àwọn Òjíṣẹ́ Ìjọba Náà Lẹ́kọ̀ọ́
    Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
  • Àwọn Ìdálẹ́kọ̀ọ́ Wo Ló Ń Mú Káwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Já Fáfá Lẹ́nu Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Wa?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Ṣé Wàá Fẹ́ Lọ Sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere?
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Sapá Kó O Lè Lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
mwb19 April ojú ìwé 8

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ẹ̀kọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ni Kó O Máa Lé

ÌDÍ TÓ FI ṢE PÀTÀKÌ: Olùkọ́ Atóbilọ́lá ni Jèhófà, ó ń fún wa ní ẹ̀kọ́ tó dáa jù lọ. Ó ń kọ́ wa bá a ṣe lè gbé ìgbésí ayé tó nítumọ̀, ó sì ń múra wa sílẹ̀ fún ọjọ́ iwájú aláyọ̀ tá à ń retí, gbogbo èyí ló ń ṣe fún wa lọ́fẹ̀ẹ́! (Ais 11:​6-9; 30:​20, 21; Ifi 22:17) Jèhófà tún ń lo ẹ̀kọ́ àtọ̀runwá yìí láti múra wa sílẹ̀ fún iṣẹ́ tó ń gbẹ̀mí là tá à ń ṣe lónìí.​—2Kọ 3:5.

BÓ O ṢE LÈ ṢE É:

  • Sapá láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti oníwà pẹ̀lẹ́.​—Sm 25:​8, 9

  • Máa gba ìdálẹ́kọ̀ọ́ tó wà lárọ̀ọ́wọ́tó rẹ báyìí, irú bí iṣẹ́ ọmọ ilé ẹ̀kọ́, ní ìpàdé àárín ọ̀sẹ̀

  • Ní àwọn àfojúsùn tẹ̀mí.​—Flp 3:13

  • Yááfì àwọn nǹkan, kó o bàa lè tóótun láti gba ìdálẹ́kọ̀ọ́ síwájú sí i.​—Flp 3:8

WO FÍDÍÒ NÁÀ Ẹ̀KỌ́ JÈHÓFÀ SỌ WÁ DI ỌLỌ́RỌ̀ NÍPA TẸ̀MÍ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Irú àwọn ìṣòro wo ni àwọn akéde kan ti borí kí wọ́n lè lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run?

  • Irú ìdálẹ́kọ̀ọ́ wo ni àwọn tó lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run máa ń rí gbà?

  • Nígbà tí àwọn tó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ yìí dé ibi iṣẹ́ àyànfúnni wọn, báwo ni àwọn ará ìjọ ibẹ̀ ṣe ràn wọ́n lọ́wọ́?

  • Kí ni ẹni tó bá fẹ́ lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run gbọ́dọ̀ dójú ìlà ẹ̀? (kr 189)

  • Èwo nínú àwọn ìdálẹ́kọ̀ọ́ míì tí ètò Ọlọ́run pèsè lo tún lè fi ṣe àfojúsùn rẹ?

Àwọn tó lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run ń sìn ní Namibia, Norway, Amẹ́ríkà àti Japan

Àwọn ìbùkún wo lo máa rí tó o bá fi ṣe àfojúsùn rẹ láti lọ sí ilé ẹ̀kọ́ ètò Ọlọ́run?

ILÉ Ẹ̀KỌ́ ÈTÒ ỌLỌ́RUN TÍ MO TI JÀǸFÀÀNÍ LÁTINÚ Ẹ̀

  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni

  • Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nà

  • Ilé Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́

  • Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Alàgbà Ìjọ

  • Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run

ILÉ Ẹ̀KỌ́ ÈTÒ ỌLỌ́RUN WO NI MO ṢÌ FẸ́ LỌ?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́