ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb19 June ojú ìwé 8
  • Jẹ́ Kí Ìdákẹ́kọ̀ọ́ Rẹ Túbọ̀ Máa Mérè Wá

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jẹ́ Kí Ìdákẹ́kọ̀ọ́ Rẹ Túbọ̀ Máa Mérè Wá
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìkẹ́kọ̀ọ́ Lérè
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Kíkẹ́kọ̀ọ́—Ó Ṣàǹfààní, Ó Sì Gbádùn Mọ́ni
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Máa Ṣe Bí Ọba
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Bí A Ṣe Lè Wà ní Ìbárẹ́ Tímọ́tímọ́ Pẹ̀lú Jèhófà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
mwb19 June ojú ìwé 8

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Jẹ́ Kí Ìdákẹ́kọ̀ọ́ Rẹ Túbọ̀ Máa Mérè Wá

ÌDÍ TÓ FI ṢE PÀTÀKÌ: Ìdákẹ́kọ̀ọ́ látinú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run máa jẹ́ ká “lóye ní kíkún ohun tí ìbú àti gígùn àti gíga àti jíjìn” òtítọ́ jẹ́. (Ef 3:18) Ó tún máa ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́ aláìlábàwọ́n àti aláìlẹ́bi nínú ayé burúkú yìí, ó sì máa ràn wá lọ́wọ́ láti “di ọ̀rọ̀ ìyè mú ṣinṣin.” (Flp 2:​15, 16) Àwa fúnra wa la máa yan ìtẹ̀jáde tá a fẹ́ lò nígbà tá a bá fẹ́ ṣe ìdákẹ́kọ̀ọ́ látinú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Kí la lè ṣe láti jàǹfààní ní kíkún bá a ṣe ń ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tá a sì ń kẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀?

BÓ O ṢE LÈ ṢE É:

  • O lè fàlà sí àwọn ẹsẹ Bíbélì, kó o sì kọ àlàyé sínú Bíbélì tó o fi ń ṣe ìdákẹ́kọ̀ọ́, ó tiẹ̀ lè lo Bíbélì tó wà lórí ẹ̀rọ

  • Bó o ṣe ń ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, bi ara rẹ láwọn ìbéèrè yìí: ‘Ta ni? Kí ni? Ìgbà wo? Ibo? Kí nìdí? Báwo?’

  • Ṣe ìwádìí. Tó o bá fẹ́ ṣèwádìí, o lè ṣèwádìí lórí ẹsẹ Bíbélì tàbí àkòrí ọ̀rọ̀ kan

  • Ronú jinlẹ̀ lórí ohun tó o kà, kó o lè mọ bó o ṣe lè fi wọ́n sílò

  • Fi ohun tó ò ń kọ́ sílò lójoojúmọ́ ayé rẹ.​—Lk 6:​47, 48

WO FÍDÍÒ NÁÀ Ẹ DI “Ọ̀RỌ̀ ÌYÈ MÚ ṢINṢIN”​—Ẹ MÁA ṢE ÌDÁKẸ́KỌ̀Ọ́ TÓ JÍIRE, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Kí ni àwọn kan sọ pé a lè fi ìdákẹ́kọ̀ọ́ wé?

  • Kí nìdí tó fi yẹ ká gbàdúrà ní gbogbo ìgbà tá a bá fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ìdákẹ́kọ̀ọ́?

  • Kí ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti túbọ̀ lóye àwọn ẹsẹ Bíbélì dáadáa?

  • Irú àwọn àmì wo la lè fi sínú Bíbélì tá a fi ń ṣe ìdákẹ́kọ̀ọ́?

  • Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa ṣàṣàrò nígbà tá a bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run?

  • Kí ló yẹ ká ṣe sí ohun tá à ń kọ́?

Arábìnrin kan ń ṣe ìdákẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó jíire; arákùnrin kan ń fa ilà sí Bíbélì rẹ̀; arábìnrin kan ń sọ ohun tó kọ́ nínú Bíbélì fún àwọn ọkùnrin méjì; arákùnrin kan ń gbàdúrà

“Mo mà nífẹ̀ẹ́ òfin rẹ o! Àtàárọ̀ ṣúlẹ̀ ni mò ń ronú lé e lórí.”​—Sm 119:97

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́