ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb19 September ojú ìwé 7
  • “Ẹ Máa Ronú Lórí Àwọn Nǹkan Yìí”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Ẹ Máa Ronú Lórí Àwọn Nǹkan Yìí”
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Fílípì 4:8—“Ohunkóhun Tó Jẹ́ Òótọ́, . . . Ẹ Máa Ronú Lórí Àwọn Nǹkan Yìí”
    Àlàyé Àwọn Ẹsẹ Bíbélì
  • Jẹ́ Olóòótọ́ Nínú Èrò Rẹ
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2023
  • Àṣàrò Ọkàn Mi
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Bawo Ni a Se Lè Fi Iwafunfun Kún Igbagbọ Wa?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1993
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
mwb19 September ojú ìwé 7
Arákùnrin kan ń wo nǹkan kan lórí kọ̀ǹpútà ẹ̀ lálẹ́, kìnnìún tó ń ké ramúramù tó ṣàpẹẹrẹ Sátánì sì wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

“Ẹ Máa Ronú Lórí Àwọn Nǹkan Yìí”

Àwọn nǹkan wo nìyẹn? Fílípì 4:8 sọ pé ká máa ronú lórí ohun tó jẹ́ òótọ́, tó ṣe pàtàkì, tó jẹ́ òdodo, tó jẹ́ mímọ́, tó yẹ ní fífẹ́, tí à ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ dáadáa, tó dára, tó sì yẹ fún ìyìn. Ìyẹn ò túmọ̀ sí pé àwọn ọ̀rọ̀ Bíbélì nìkan ni Kristẹni kan á máa rò ṣáá. Síbẹ̀, ohun tó máa múnú Jèhófà dùn ló yẹ ká máa rò. Kò yẹ ká máa ro ohun táá mú kó ṣòro fún wa láti jẹ́ olóòótọ́ sí i.​—Sm 19:14.

Kò rọrùn láti gbé èròkerò kúrò lọ́kàn. Bá a ṣe ń wọ̀yá ìjà pẹ̀lú àìpé ara wa, bẹ́ẹ̀ la tún gbọ́dọ̀ wọ̀yá ìjà pẹ̀lú Sátánì tó jẹ́ “ọlọ́run ètò àwọn nǹkan yìí.” (2Kọ 4:4) Torí pé Sátánì ló ń darí ayé, èyí tó pọ̀ jù lára ohun tó ń jáde nínú tẹlifíṣọ̀n, rédíò, Íńtánẹ́ẹ̀tì àtàwọn ìwé ìròyìn ló burú jáì. Torí náà, ó yẹ ká ṣọ́ ohun tá à ń wò, tá à ń gbọ́, tá a sì ń kà. Tá ò bá ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn nǹkan yìí lè mú ká máa ro èròkerò, ìyẹn sì lè mú ká hùwàkiwà.​—Jem 1:​14, 15.

JẸ́ KÍ ÀWỌN ARÁ WO FÍDÍÒ NÁÀ YẸRA FÚN OHUN TÓ LÈ BA ÌDÚRÓṢINṢIN RẸ JẸ́​—ERÉ ÌNÀJÚ TÍ KÒ BÓJÚ MU, LẸ́YÌN NÁÀ, Ẹ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Arákùnrin kan ń wo àwòrán ìṣekúṣe lórí fóònù ẹ̀ lálẹ́

    Kí ni arákùnrin yìí ń wò lórí fóònù ẹ̀, àkóbá wo nìyẹn sì ṣe fún un?

  • Arákùnrin kan jáwọ́ nínú lílo ìkànnì àjọlò kan

    Báwo ni ọ̀rọ̀ tó wà nínú Gálátíà 6:​7, 8 àti Sáàmù 119:37 ṣe ràn án lọ́wọ́?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́