ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 June ojú ìwé 8
  • Bá A Ṣe Lè Lo Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bá A Ṣe Lè Lo Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
  • Bá A Ṣe Lè Lo Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
  • Bá A Ṣe Lè Fi Àṣàrò Kúkúrú Bẹ̀rẹ̀ Ìjíròrò
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 June ojú ìwé 8

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Bá A Ṣe Lè Lo Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ

Láti January 2018 ni apá tá a pè ní ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ ti máa ń wà níwájú Ìwé Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni. Báwo la ṣe lè lò ó?

Arábìnrin kan ń ṣiṣẹ́ ọmọ ilé ẹ̀kọ́ ní ìpàdé àárín ọ̀sẹ̀.

Tó O Bá Níṣẹ́ Ọmọ Ilé Ẹ̀kọ́: Lo ìbéèrè, Bíbélì àti ìbéèrè fún ìgbà míì bó ṣe wà nínú ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ. Àmọ́, ìyẹn ò túmọ̀ sí pé ọ̀rọ̀ tí wọ́n lò nínú fídíò ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ ni ìwọ náà gbọ́dọ̀ lò. O lè lo ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ míì tàbí kó o lo ìnasẹ̀ ọ̀rọ̀ tó yàtọ̀. Ó sì lè jẹ́ pé kókó míì ló máa tẹnu mọ́ nínú iṣẹ́ náà. Ó tún lè fún onílé ní ọ̀kan lára àwọn ìtẹ̀jáde tó wà nínú Àpótí Ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́, kódà tí ìtọ́ni fún iṣẹ́ náà ò bá sọ pé kó o ṣe bẹ́ẹ̀.

Arábìnrin náà wà lóde ẹ̀rí, ó ń ka Bíbélì fún obìnrin kan.

Tá A Bá Wà Lóde Ẹ̀rí: A ṣètò apá ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ ká lè mọ onírúurú ọ̀nà tá a lè gbà bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀. Tẹ́nì kan bá nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ wa, tó sì fẹ́ ká pa dà wá, a lè lo ìbéèrè tá a máa bi onílé nígbà ìpadàbẹ̀wò. A lè ṣàtúnṣe díẹ̀ sí ìbéèrè yìí tàbí ká tiẹ̀ lo ìbéèrè míì tó yàtọ̀ pátápátá. Ṣé àwọn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín máa nífẹ̀ẹ́ sí kókó míì tàbí ẹsẹ Bíbélì kan tẹ́ ẹ ti lò láwọn oṣù tó ti kọjá? Ṣé àwọn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín máa ń fẹ́ sọ̀rọ̀ nípa àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lágbègbè wọn? Ọ̀nà yòówù ká gbà lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ, ohun tó yẹ kó jẹ wá lọ́kàn ni bá a ṣe máa ‘ṣe ohun gbogbo nítorí ìhìn rere, ká lè sọ ọ́ fún àwọn ẹlòmíì.’​—1Kọ 9:22, 23.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́