ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 September ojú ìwé 3
  • Ṣọ́ra Kó O Má Bàa Tan Irọ́ Kálẹ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣọ́ra Kó O Má Bàa Tan Irọ́ Kálẹ̀
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Òpè Eniyan A Máa Gba Ohun Gbogbo Gbọ́”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpọ̀jù Ìsọfúnni
    Jí!—1998
  • Máa Fi Ohun Tó o Ti Kọ́ Sílò
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Máa Rí Àrídájú Ọ̀rọ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 September ojú ìwé 3

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ṣọ́ra Kó O Má Bàa Tan Irọ́ Kálẹ̀

Obìnrin kan tó ń rajà rí ohun kan tó yà á lẹ́nu lórí fóònù.

Lónìí, kíákíá ni ìròyìn máa ń tàn kálẹ̀. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń gba ìròyìn látorí rédíò, tẹlifíṣọ̀n, íńtánẹ́ẹ̀tì àti lórí àwọn ìwé tí wọ́n tẹ̀ jáde. Àwa tá à ń sin “Ọlọ́run òtítọ́” kì í fẹ́ tan irọ́ kálẹ̀, kódà a kì í fẹ́ kó ṣèèṣì ṣẹlẹ̀. (Sm 31:5; Ẹk 23:1) Ó léwu gan-an téèyàn bá fi ìsọfúnni tí kì í ṣòótọ́ ránṣẹ́ sáwọn míì. Tó o bá fẹ́ mọ̀ bóyá ọ̀rọ̀ kan jóòótọ́, o lè bi ara rẹ̀ pé:

  • ‘Ṣé mo gbà pé ẹni tó sọ̀rọ̀ yìí ò lè parọ́ fún mi?’ Ẹni tó ń sọ ọ̀rọ̀ yẹn lè má mọ kúlẹ̀kúlẹ̀ ohun tó ṣẹlẹ̀. Àwọn èèyàn sábà máa ń fi kún ọ̀rọ̀ bó bá ṣe ń lọ látọ̀dọ̀ ẹnì kan sí òmíì, torí náà ṣọ́ra tó ò bá ti mọ ibi tọ́rọ̀ náà ti wá. Àwọn tó ń múpò iwájú nínú ìjọ máa ń ní ọ̀pọ̀ ìsọfúnni lọ́wọ́, torí náà ó yẹ kí wọ́n ṣọ́ra gan-an kí wọ́n má bàa tan ìsọfúnni tí kì í ṣòótọ́ kálẹ̀

  • ‘Ṣé ọ̀rọ̀ náà lè ba ẹnì kan lórúkọ jẹ́?’ Tọ́rọ̀ náà bá máa mú káwọn èèyàn máa fojú tí ò dáa wo ẹnì kan tàbí àwọn kan, á dáa kó o má sọ̀rọ̀ náà fún ẹnikẹ́ni.​—Owe 18:8; Flp 4:8

  • ‘Ṣé ọ̀rọ̀ náà ṣeé gbà gbọ́?’ Ṣọ́ra tó o bá ń gbọ́ ìròyìn tàbí àwọn ìrírí tó ń ṣeni ní kàyéfì

WO FÍDÍÒ NÁÀ BÁWO NI MO ṢE LÈ YẸRA FÚN ÒFÓFÓ? LẸ́YÌN NÁÀ, DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Wọ́n so ọmọ kan mọ́ ara pákó róbótó kan ọ̀bẹ sì gún pákó náà káàkiri.

    Bó ṣe wà nínú Òwe 12:​18, ewu wo ni ọ̀rọ̀ ẹnu wa lè fà?

  • Àwọn kan kóra jọ, wọ́n sì ń ṣe òfófó.

    Báwo ni Fílípì 2:4 ṣe jẹ́ ká mọ ohun tó yẹ ká ṣe tá a bá ń sọ̀rọ̀ àwọn míì?

  • Ọkùnrin kan kẹ̀yìn sí ẹni kan tó fẹ́ ṣòfófó fún un.

    Kí ló yẹ ká ṣe táwọn èèyàn bá ń sọ̀rọ̀ ẹnì kan láìdáa?

  • Ọkùnrin kan ń sọ ohun tí kò jẹ́ òótọ́, oníròyìn kan sì ń kọ ọ́ sílẹ̀.

    Kó o tó sọ̀rọ̀ ẹnì kan lẹ́yìn, àwọn ìbéèrè wo ló yẹ kó o bi ara rẹ̀?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́