ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb22 July ojú ìwé 5
  • Lọ Síbi Tí Àìní Pọ̀ Sí

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Lọ Síbi Tí Àìní Pọ̀ Sí
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Là Ń Ṣe ní Àwọn Ẹ̀ka Ọ́fíìsì Wa?
    Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
  • Àwọn Ọ̀nà Tó O Lè Gbà Mú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Gbòòrò Sí I
    A Ṣètò Wa Láti Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà
  • Ǹjẹ́ O Lè ‘Ré Kọjá Lọ Sí Makedóníà’?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • “Ṣé Kí N Ṣí Lọ Síbòmíràn?”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
mwb22 July ojú ìwé 5
Àwọn àwòrán tí wọ́n yọ látinú fídíò “Jẹ́ Kí Ìgbàgbọ́ Mú Kó O Ṣe Púpọ̀ Sí I​—Lọ Síbi Tí Àìní Pọ̀ Sí.” Fọ́tò: 1. Gabriel ń ṣèwádìí. 2. Ó ń bá alàgbà kan sọ̀rọ̀ nípa bó ṣe máa kọ̀wé sí ẹ̀ka ọ́fíìsì. 3. Òun àti Samuel ọ̀rẹ́ ẹ̀ jọ kópa nínú àkànṣe ìwàásù kan.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI | OHUN TÓ O LÈ FI ṢE ÀFOJÚSÙN NÍ ỌDÚN IṢẸ́ ÌSÌN TÓ Ń BỌ̀

Lọ Síbi Tí Àìní Pọ̀ Sí

Ó gba ìgbàgbọ́ kéèyàn tó lè fi àdúgbò tó ti mọ́ ọn lára sílẹ̀ kó sì lọ síbòmíì kó lè ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. (Heb 11:8-10) Tó bá wù ẹ́ láti lọ sìn níbi tí àìní pọ̀ sí, sọ fáwọn alàgbà ìjọ ẹ. Àmọ́ àwọn nǹkan pàtó wo lo lè ṣe kó o lè mọ̀ bóyá àfojúsùn tọ́wọ́ ẹ̀ lè bà ni? Ka àwọn àpilẹ̀kọ tó sọ̀rọ̀ nípa ohun tó yẹ kéèyàn fi sọ́kàn tó bá fẹ́ lọ sìn níbi tí àìní pọ̀ sí. Yàtọ̀ síyẹn, fọ̀rọ̀ lọ àwọn tó ń sìn níbi tí àìní wà. (Owe 15:22) Bákan náà, gbàdúrà pé kí Jèhófà tọ́ ẹ sọ́nà. (Jem 1:5) Ṣèwádìí nípa ibi tó o fẹ́ lọ, tó bá sì ṣeé ṣe, lọ lo ọjọ́ mélòó kan níbẹ̀ kó o tó pinnu láti kó lọ pátápátá.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ JẸ́ KÍ ÌGBÀGBỌ́ MÚ KÓ O ṢE PÚPỌ̀ SÍ I​—LỌ SÍBI TÍ ÀÌNÍ PỌ̀ SÍ, KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Kí ló mú kó ṣòro fún Gabriel láti lọ síbi tí àìní wà, kí ló sì ràn án lọ́wọ́?

Tó o bá fẹ́ mọ àwọn ìjọ tí àìní wà lágbègbè ẹ, béèrè lọ́wọ́ alábòójútó àyíká yín. Tó bá jẹ́ pé àwọn ìjọ tó jìnnà sọ́dọ̀ yín lo fẹ́ lọ, kọ lẹ́tà sí ẹ̀ka ọ́fíìsì, kó o sì fún Ìgbìmọ̀ Iṣẹ́ Ìsìn ìjọ rẹ. Tó bá jẹ́ pé orílẹ̀-èdè míì lo ti fẹ́ lọ sìn, kọ̀wé sí ẹ̀ka ọ́fíìsì tó ń bójú tó orílẹ̀-èdè náà. Tó bá sì jẹ́ pé o ti ní ibi pàtó tó wù ẹ́ láti lọ, o lè kọ ọ́ sínú lẹ́tà rẹ.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́