ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp23 No. 1 ojú ìwé 6-7
  • 1 | Àdúrà—“Ẹ Máa Kó Gbogbo Àníyàn Yín Lọ Sọ́dọ̀ Rẹ̀”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • 1 | Àdúrà—“Ẹ Máa Kó Gbogbo Àníyàn Yín Lọ Sọ́dọ̀ Rẹ̀”
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2023
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó Túmọ̀ Sí
  • Àǹfààní Tó Máa Ṣe Ẹ́
  • Kó Gbogbo Àníyàn Rẹ lé Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Borí Àníyàn?
    Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
  • Ẹ Kó Gbogbo Àníyàn Yín Lé Jehofa
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
  • Báwo Ni Bíbélì Ṣe Lè Ran Àwọn Ọkùnrin Tó Ń Ṣàníyàn Lọ́wọ́?
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2023
wp23 No. 1 ojú ìwé 6-7
Ọ̀dọ́kùnrin kan tó ní ìdààmú ọkàn di àyà rẹ̀ mú bó ṣe ń gbàdúrà.

1 | Àdúrà “Ẹ Máa Kó Gbogbo Àníyàn Yín Lọ Sọ́dọ̀ Rẹ̀”

BÍBÉLÌ SỌ PÉ: “Ẹ máa kó gbogbo àníyàn yín lọ sọ́dọ̀ [Ọlọ́run], torí ó ń bójú tó yín.”​—1 PÉTÉRÙ 5:7.

Ohun Tó Túmọ̀ Sí

Jèhófà Ọlọ́run ní ká bá òun sọ ohunkóhun tó dà bí ẹrù ìnira fún ọkàn àti ọpọlọ wa. (Sáàmù 55:22) Kò sí ìṣòro tó tóbi jù tàbí tó kéré jù láti gbàdúrà nípa ẹ̀. Tá a bá wà nínú ìṣòro, ó máa ń wu Jèhófà gan-an láti ràn wá lọ́wọ́. Tá a bá fẹ́ kí ọkàn wa balẹ̀, ó ṣe pàtàkì gan-an pé ká máa gbàdúrà sí Ọlọ́run.​—Fílípì 4:6, 7.

Àǹfààní Tó Máa Ṣe Ẹ́

Tẹ́nì kan bá ní àárẹ̀ ọpọlọ, gbogbo bó ṣe ń ṣe ẹni náà kì í sábà yé àwọn míì. (Òwe 14:10) Àmọ́ tó bá sọ gbogbo bó ṣe ń ṣe é fún Ọlọ́run láìfi ohunkóhun pa mọ́, Ọlọ́run máa ṣàánú ẹ̀ torí pé ọ̀rọ̀ ẹ̀ yé e. Jèhófà rí wa tán, ó mọ àwọn ohun tó ń fa ìnira fún wa, ó sì fẹ́ ká gbàdúrà sí òun nípa ohunkóhun tó ń kó ìdààmú bá wa.​—2 Kíróníkà 6:29, 30.

Tá a bá ń gbàdúrà sí Jèhófà, á túbọ̀ dá wa lójú pé ó nífẹ̀ẹ́ wa, ó sì máa ràn wá lọ́wọ́. Àwa náà lè wá ṣe bíi ti onísáàmù tó sọ fún Jèhófà pé: “O ti rí ìpọ́njú mi; o mọ ìdààmú ńlá tó bá mi.” (Sáàmù 31:7) Tá a bá ń rántí pé Jèhófà mọ gbogbo bó ṣe ń ṣe wá, ìyẹn ò ní jẹ́ ká sọ̀rètí nù nígbà ìṣòro. Kì í ṣe pé Jèhófà rí àwọn ìṣòro wa nìkan, àmọ́ ó tún mọ bí ohun tí ìṣòro náà ń fà ṣe rí lára wa ju ẹnikẹ́ni míì lọ, ó sì ń lo Bíbélì láti fún wa ní ìṣírí àti ìtùnú.

Bíbélì Ran Julian Lọ́wọ́

Mo Máa Ń Ṣàníyàn Gan-an

Julian.

“Ọ̀pọ̀ ìgbà ni mo máa ń ní ìdààmú ọkàn, mo sì ní àárẹ̀ ọpọlọ tí wọ́n ń pè ní obsessive-compulsive disorder (OCD). Àníyàn kì í jẹ́ kí n gbádùn ara mi rárá. Ara mi lè yá gágá báyìí, àmọ́ kí n tó mọ̀, màá ti bẹ̀rẹ̀ sí í ní ìdààmú ọkàn tó pọ̀, mi ò sì ní lè sọ pé ohun báyìí ló fà á. Ọkàn mi kì í balẹ̀ rárá tí mo bá wà láàárín àwọn èèyàn. Ṣe ni màá máa ṣàníyàn nípa ohun tí wọ́n ń rò nípa mi.

“Àwọn tó mọ ohun tó ń ṣe mí máa ń ràn mí lọ́wọ́ gan-an. Síbẹ̀, àwọn ìgbà míì wà tí wọ́n máa ń sọ ohun tí kò bá mi lára mu. Àmọ́ mo mọyì bí wọ́n ṣe ń fìfẹ́ hàn sí mi.

“Ohun tó ń ṣe mí yìí máa ń jẹ́ kó ṣòro fún mi láti gbàdúrà nígbà míì. Kì í rọrùn rárá fún mi láti pọkàn pọ̀ tí mo bá fẹ́ gbàdúrà sí Jèhófà. Oríṣiríṣi èrò tí kò jọra wọn ló máa ń rọ́ sí mi lọ́pọlọ débi pé ṣe ló máa ń kà mí láyà. Tọ́rọ̀ bá sì ti rí bẹ́ẹ̀, mi ò ní lè bá Jèhófà sọ ohun tí mò ń rò àti bí nǹkan ṣe rí lára mi.”

Bíbélì Ràn Mí Lọ́wọ́

“Nígbà tí mo kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, mo rí i pé kò dìgbà tí àdúrà wa bá gùn tàbí tọ́rọ̀ dùn lẹ́nu wa kí Ọlọ́run tó lè gbọ́ àdúrà wa. Nígbà míì, tí mi ò bá mọ ohun tí màá sọ, ṣe ni màá kàn sọ pé: ‘Jèhófà jọ̀ọ́, ràn mí lọ́wọ́.’ Lákòókò yẹn, mo máa ń mọ̀ ọ́n lára pé ọ̀rọ̀ mi yé Jèhófà, ó sì máa ń ṣe ohun tí mo fẹ́ fún mi. Yàtọ̀ sí pé mo máa ń gbàdúrà, mo tún máa ń gba ìtọ́jú lọ́dọ̀ àwọn dókítà. Inú mi dùn pé àwọn nǹkan méjì tí mò ń ṣe yìí ràn mí lọ́wọ́ débi pé nǹkan ti yàtọ̀ gan-an. Ọkàn mi balẹ̀ gan-an bí mo ṣe ń gbàdúrà sí Bàbá mi ọ̀run, tí mo sì ń rí bó ṣe ń fìfẹ́ ràn mí lọ́wọ́.”

Ìrànlọ́wọ́ fún Àwọn Ọ̀dọ́

Fídíò “Di Ọ̀rẹ́ Jèhófà​—Gbàdúrà Nígbà Gbogbo.”

Tó o bá lọ sórí jw.org, wàá rí àwọn ohun tó máa jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà ń gbọ́ àdúrà ẹ.

Wo fídíò náà Di Ọ̀rẹ́ Jèhófà​—Gbàdúrà Nígbà Gbogbo.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́