ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
Ìfilọ̀
Èdè tuntun tó wà: Shan
  • Òní

Friday, October 3

Ẹ máa wá ire àwọn ẹlòmíì, kì í ṣe tiyín nìkan.—Fílí. 2:4.

Ẹ̀mí Ọlọ́run darí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù láti gba àwọn Kristẹni níyànjú pé kí wọ́n máa ṣe ohun tó máa ṣe àwọn èèyàn láǹfààní. Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé ìmọ̀ràn yìí tá a bá wà nípàdé? Bá a ṣe lè tẹ̀ lé e ni pé ká máa rántí pé àwa nìkan kọ́ ló máa dáhùn nípàdé, ká jẹ́ káwọn ẹlòmíì náà dáhùn. Rò ó wò ná. Tí ìwọ àti ọ̀rẹ́ ẹ kan bá jọ ń sọ̀rọ̀, ṣé ìwọ nìkan ni wàá máa sọ̀rọ̀ ṣáá àbí wàá fún òun náà láǹfààní láti sọ̀rọ̀? Rárá o, wàá jẹ́ kóun náà sọ̀rọ̀! Lọ́nà kan náà, tá a bá wà nípàdé, dípò ká máa nawọ́ ṣáá, á dáa ká jẹ́ káwọn ẹlòmíì náà dáhùn. Kódà, ọ̀kan lára ohun tá a lè ṣe láti gba àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa níyànjú ni pé, ká fún wọn láǹfààní láti dáhùn kí wọ́n lè sọ ohun tí wọ́n gbà gbọ́. (1 Kọ́r. 10:24) Jẹ́ kí ìdáhùn ẹ ṣe ṣókí, káwọn ẹlòmíì lè dáhùn. Tí ìdáhùn ẹ bá tiẹ̀ ṣe ṣókí, má sọ kókó tó pọ̀. Tó o bá sọ gbogbo kókó tó wà nínú ìpínrọ̀ náà, àwọn ará ò ní rí nǹkan kan sọ mọ́. w23.04 22-23 ¶11-13

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, October 4

Mò ń ṣe ohun gbogbo nítorí ìhìn rere, kí n lè sọ ọ́ fún àwọn ẹlòmíì.—1 Kọ́r. 9:23.

Ó yẹ ká rántí pé ó ṣe pàtàkì ká máa ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, pàápàá jù lọ ká máa wàásù fún wọn. Ó yẹ ká mọ bá a ṣe máa bá onírúurú èèyàn sọ̀rọ̀ tá a bá ń wàásù. Lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, a máa ń pàdé àwọn tó wá láti ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, tí ìwà wọn àti ohun tí wọ́n gbà gbọ́ sì yàtọ̀ síra. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù máa ń bá onírúurú èèyàn sọ̀rọ̀ lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, ó sì yẹ ká kẹ́kọ̀ọ́ lára ẹ̀. Jésù yàn án pé kó jẹ́ “àpọ́sítélì fún àwọn orílẹ̀-èdè.” (Róòmù 11:13) Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń ṣe iṣẹ́ tí Jésù gbé fún un yìí, ó wàásù fáwọn Júù, àwọn Gíríìkì, àwọn ọ̀mọ̀wé, àwọn tálákà, àwọn èèyàn pàtàkì láwùjọ àtàwọn ọba. Kí Pọ́ọ̀lù lè wàásù fún gbogbo àwọn tá a sọ yìí, ó “di ohun gbogbo nítorí gbogbo èèyàn.” (1 Kọ́r. 9:​19-22) Ó kíyè sí ibi tí wọ́n ti wá, àṣà ìbílẹ̀ wọn àtohun tí wọ́n gbà gbọ́. Ìyẹn jẹ́ kó lè wàásù fún wọn lọ́nà tó wọ̀ wọ́n lọ́kàn. Táwa náà bá jẹ́ kí ọ̀nà tá à ń gbà wàásù dáa sí i, àá lè wàásù fún onírúurú èèyàn. w23.07 23 ¶11-12

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, October 5

Kò yẹ kí ẹrú Olúwa máa jà, àmọ́ ó yẹ kó máa hùwà jẹ́jẹ́ sí gbogbo èèyàn.—2 Tím. 2:24.

Àwọn tó bá níwà tútù kì í ṣe ojo. Ó gba sùúrù gan-an ká tó lè hùwà jẹ́jẹ́ tí wọ́n bá múnú bí wa. Ìwà tútù jẹ́ ọ̀kan lára “èso ti ẹ̀mí.” (Gál. 5:​22, 23) Nígbà míì, wọ́n sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí wọ́n tú sí “ìwà tútù” fún ẹṣin kan tó burú, àmọ́ tí wọ́n ti kápá ẹ̀. Fojú inú wo ẹṣin kan tó burú gan-an, àmọ́ tó ti wá ń ṣe jẹ́jẹ́. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ẹṣin náà ti ń ṣe jẹ́jẹ́, ó ṣì lágbára. Báwo làwa náà ṣe lè jẹ́ oníwà tútù, síbẹ̀ ká jẹ́ alágbára? Ká sòótọ́, kì í ṣe ohun tá a lè dá ṣe fúnra wa. Ohun tó máa ràn wá lọ́wọ́ ni pé ká gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀, ká sì sọ fún un pé kó jẹ́ ká níwà tútù. Ọ̀pọ̀ èèyàn ti fi hàn pé èyí ṣeé ṣe. Ọ̀pọ̀ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló ti fi hàn pé a níwà tútù nígbà táwọn èèyàn ta kò wá tàbí tí wọ́n múnú bí wa, ìyẹn sì ti jẹ́ káwọn èèyàn ní èrò tó tọ́ nípa wa.—2 Tím. 2:​24, 25. w23.09 15 ¶3

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́