Saturday, October 4
Mò ń ṣe ohun gbogbo nítorí ìhìn rere, kí n lè sọ ọ́ fún àwọn ẹlòmíì.—1 Kọ́r. 9:23.
Ó yẹ ká rántí pé ó ṣe pàtàkì ká máa ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, pàápàá jù lọ ká máa wàásù fún wọn. Ó yẹ ká mọ bá a ṣe máa bá onírúurú èèyàn sọ̀rọ̀ tá a bá ń wàásù. Lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, a máa ń pàdé àwọn tó wá láti ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, tí ìwà wọn àti ohun tí wọ́n gbà gbọ́ sì yàtọ̀ síra. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù máa ń bá onírúurú èèyàn sọ̀rọ̀ lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, ó sì yẹ ká kẹ́kọ̀ọ́ lára ẹ̀. Jésù yàn án pé kó jẹ́ “àpọ́sítélì fún àwọn orílẹ̀-èdè.” (Róòmù 11:13) Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń ṣe iṣẹ́ tí Jésù gbé fún un yìí, ó wàásù fáwọn Júù, àwọn Gíríìkì, àwọn ọ̀mọ̀wé, àwọn tálákà, àwọn èèyàn pàtàkì láwùjọ àtàwọn ọba. Kí Pọ́ọ̀lù lè wàásù fún gbogbo àwọn tá a sọ yìí, ó “di ohun gbogbo nítorí gbogbo èèyàn.” (1 Kọ́r. 9:19-22) Ó kíyè sí ibi tí wọ́n ti wá, àṣà ìbílẹ̀ wọn àtohun tí wọ́n gbà gbọ́. Ìyẹn jẹ́ kó lè wàásù fún wọn lọ́nà tó wọ̀ wọ́n lọ́kàn. Táwa náà bá jẹ́ kí ọ̀nà tá à ń gbà wàásù dáa sí i, àá lè wàásù fún onírúurú èèyàn. w23.07 23 ¶11-12
Sunday, October 5
Kò yẹ kí ẹrú Olúwa máa jà, àmọ́ ó yẹ kó máa hùwà jẹ́jẹ́ sí gbogbo èèyàn.—2 Tím. 2:24.
Àwọn tó bá níwà tútù kì í ṣe ojo. Ó gba sùúrù gan-an ká tó lè hùwà jẹ́jẹ́ tí wọ́n bá múnú bí wa. Ìwà tútù jẹ́ ọ̀kan lára “èso ti ẹ̀mí.” (Gál. 5:22, 23) Nígbà míì, wọ́n sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí wọ́n tú sí “ìwà tútù” fún ẹṣin kan tó burú, àmọ́ tí wọ́n ti kápá ẹ̀. Fojú inú wo ẹṣin kan tó burú gan-an, àmọ́ tó ti wá ń ṣe jẹ́jẹ́. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ẹṣin náà ti ń ṣe jẹ́jẹ́, ó ṣì lágbára. Báwo làwa náà ṣe lè jẹ́ oníwà tútù, síbẹ̀ ká jẹ́ alágbára? Ká sòótọ́, kì í ṣe ohun tá a lè dá ṣe fúnra wa. Ohun tó máa ràn wá lọ́wọ́ ni pé ká gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀, ká sì sọ fún un pé kó jẹ́ ká níwà tútù. Ọ̀pọ̀ èèyàn ti fi hàn pé èyí ṣeé ṣe. Ọ̀pọ̀ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló ti fi hàn pé a níwà tútù nígbà táwọn èèyàn ta kò wá tàbí tí wọ́n múnú bí wa, ìyẹn sì ti jẹ́ káwọn èèyàn ní èrò tó tọ́ nípa wa.—2 Tím. 2:24, 25. w23.09 15 ¶3
Monday, October 6
Mo gbàdúrà nípa rẹ̀, Jèhófà sì fún mi ní ohun tí mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.—1 Sám. 1:27.
Nínú ìran àgbàyanu kan, àpọ́sítélì Jòhánù rí àwọn àgbààgbà mẹ́rìnlélógún (24) tí wọ́n ń jọ́sìn Jèhófà lọ́run. Wọ́n ń yin Ọlọ́run, wọ́n sì ń sọ pé òun ló tọ́ sí láti gba “ògo àti ọlá àti agbára.” (Ìfi. 4:10, 11) Bákan náà, ọ̀pọ̀ nǹkan ló ń mú káwọn áńgẹ́lì olóòótọ́ máa yin Jèhófà, kí wọ́n sì máa bọlá fún un. Ọ̀run làwọn áńgẹ́lì yìí ń gbé pẹ̀lú Jèhófà, ìyẹn sì jẹ́ kí wọ́n mọ Jèhófà dáadáa. Wọ́n máa ń rí bí àwọn ànímọ́ Jèhófà ṣe ń hàn nínú gbogbo ohun tó ń ṣe. Àwọn nǹkan tí Jèhófà ń ṣe yìí ń mú kí wọ́n máa yìn ín. (Jóòbù 38:4-7) Ó yẹ káwa náà máa yin Jèhófà tá a bá ń gbàdúrà, ká jẹ́ kó mọ ìdí tá a fi nífẹ̀ẹ́ ẹ̀ àti ìdí tá a fi mọyì àwọn ohun tó ṣe fún wa. Bó o ṣe ń ka Bíbélì tó o sì ń kẹ́kọ̀ọ́ ẹ̀, kíyè sí àwọn ànímọ́ Jèhófà tó wù ẹ́. (Jóòbù 37:23; Róòmù 11:33) Lẹ́yìn náà, sọ ìdí táwọn ànímọ́ náà fi wù ẹ́ fún Jèhófà. A tún lè yin Jèhófà torí pé ó ń ran ẹnì kọ̀ọ̀kan wa lọ́wọ́ àti gbogbo àwọn ará wa kárí ayé.—1 Sám. 2:1, 2. w23.05 3-4 ¶6-7