ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Friday, July 18

Ó mú ká di ìjọba kan, àlùfáà fún Ọlọ́run àti Baba rẹ̀.—Ìfi. 1:6.

Ọlọ́run fi ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ yan díẹ̀ lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn Kristi, wọ́n sì ní àjọṣe tó ṣàrà ọ̀tọ̀ pẹ̀lú Jèhófà. Àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) yìí máa jẹ́ àlùfáà pẹ̀lú Jésù. (Ìfi. 14:1) Ibi Mímọ́ tó wà nínú àgọ́ ìjọsìn náà ṣàpẹẹrẹ bí Ọlọ́run ṣe fẹ̀mí yàn wọ́n láti jẹ́ ọmọ ẹ̀ nígbà tí wọ́n wà láyé. (Róòmù 8:​15-17) Ibi Mímọ́ Jù Lọ tó wà nínú àgọ́ ìjọsìn náà ṣàpẹẹrẹ ọ̀run, ibi tí Jèhófà ń gbé. “Aṣọ ìdábùú” tó pín Ibi Mímọ́ àti Ibi Mímọ́ Jù Lọ sọ́tọ̀ọ̀tọ̀ ṣàpẹẹrẹ ara Jésù tí ò jẹ́ kó lè wọlé sọ́run láti ṣiṣẹ́ Àlùfáà Àgbà nínú tẹ́ńpìlì tẹ̀mí. Jésù fi ara ẹ̀ rúbọ nítorí aráyé, ohun tó ṣe yìí mú kó ṣeé ṣe fáwọn Kristẹni tí Ọlọ́run fẹ̀mí yàn láti gba ìyè lọ́run. Kí wọ́n lè gba èrè wọn lọ́run, àwọn náà ò ní gbé ẹran ara wọn lọ sọ́run.—Héb. 10:​19, 20; 1 Kọ́r. 15:50. w23.10 28 ¶13

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, July 19

Àkókò ò ní tó tí n bá ní kí n máa sọ̀rọ̀ nípa Gídíónì.—Héb. 11:32.

Nígbà táwọn ọmọ Éfúráímù bínú sí Gídíónì gidigidi, kò gbaná jẹ, kò sì fìbínú sọ̀rọ̀ sí wọn. (Oníd. 8:​1-3) Ó fi hàn pé òun nírẹ̀lẹ̀ torí ó fara balẹ̀ tẹ́tí sí wọn, ó sì fọgbọ́n yanjú ọ̀rọ̀ náà. Àwọn alàgbà tó gbọ́n máa ń fara wé Gídíónì. Táwọn èèyàn bá ṣàríwísí wọn, wọ́n máa ń fara balẹ̀ tẹ́tí sí wọn, wọn kì í sì í gbaná jẹ. (Jém. 3:13) Ohun tí wọ́n ń ṣe yìí ló ń mú kí àlàáfíà wà nínú ìjọ. Nígbà táwọn èèyàn ń yin Gídíónì torí pé ó ṣẹ́gun àwọn ará Mídíánì, Jèhófà ló fìyìn fún. (Oníd. 8:​22, 23) Báwo lẹ̀yin alàgbà ṣe lè fara wé Gídíónì? Ẹ lè ṣe bẹ́ẹ̀ tẹ́ ẹ bá ń jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé Jèhófà ló ń ràn yín lọ́wọ́ láti ṣe àwọn nǹkan tẹ́ ẹ̀ ń ṣe. (1 Kọ́r. 4:​6, 7) Bí àpẹẹrẹ, tí wọ́n bá gbóríyìn fún alàgbà kan torí àsọyé tó sọ, ó yẹ kó jẹ́ káwọn ará mọ̀ pé inú Bíbélì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lòun ti mú ohun tóun sọ tàbí kó sọ pé àwọn ìdálẹ́kọ̀ọ́ tí ètò Ọlọ́run ń fún wa ló ran òun lọ́wọ́. Ó yẹ kẹ́yin alàgbà máa kíyè sára tẹ́ ẹ bá ń kọ́ni, kó má jẹ́ pé ẹ̀yin làwọn èèyàn á máa kan sárá sí, dípò kí wọ́n fògo fún Jèhófà. w23.06 4 ¶7-8

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, July 20

Èrò mi yàtọ̀ sí èrò yín.—Àìsá. 55:8.

Tá ò bá rí àwọn nǹkan tá à ń béèrè nínú àdúrà wa gbà, ó yẹ ká bi ara wa láwọn ìbéèrè kan. Àkọ́kọ́ ni pé ‘Ṣé ohun tó tọ́ ni mò ń béèrè?’ Lọ́pọ̀ ìgbà, a máa ń ronú pé a mọ ohun tó dáa jù fún wa. Àmọ́ àwọn ohun tá à ń béèrè yẹn lè má ṣe wá láǹfààní. Tá a bá ń gbàdúrà nípa ìṣòro kan, ó ṣeé ṣe kí ọ̀nà míì wà láti gbà yanjú ìṣòro náà tó dáa ju ohun tá a rò lọ. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn nǹkan míì tá a béèrè lè má bá ìfẹ́ Jèhófà mu. (1 Jòh. 5:14) Bí àpẹẹrẹ, ẹ jẹ́ ká wo àwọn òbí tí wọ́n ń bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kí ọmọ àwọn dúró sínú òtítọ́. Àdúrà tó dáa nìyẹn. Síbẹ̀, Jèhófà ò ní fipá mú ẹnikẹ́ni nínú wa láti jọ́sìn òun. Ó fẹ́ kí gbogbo wa títí kan àwọn ọmọ wa pinnu pé òun làá máa sìn. (Diu. 10:​12, 13; 30:​19, 20) Torí náà, ohun tó yẹ kí wọ́n bẹ Jèhófà ni pé kó jẹ́ káwọn kọ́ ọmọ àwọn lọ́nà tá á fi nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tá á sì jọ́sìn ẹ̀.—Òwe 22:6; Éfé. 6:4. w23.11 21 ¶5; 23 ¶12

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́