ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Monday, July 21

Ẹ máa . . . tu ara yín nínú.—1 Tẹs. 4:18.

Tá a bá ń tu àwọn èèyàn nínú, báwo nìyẹn ṣe máa fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ wọn? Ìwé kan tó ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù lò tí wọ́n tú sí ‘tù nínú’ nínú ẹsẹ ojúmọ́ wa tòní túmọ̀ sí “kí ẹnì kan dúró sẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹni tó níṣòro tó le gan-an, kó sì fún un níṣìírí.” Tá a bá tu arákùnrin tàbí arábìnrin kan nínú, ńṣe là ń ràn án lọ́wọ́ kó lè máa rìn ní ọ̀nà ìyè nìṣó. Torí náà, gbogbo ìgbà tá a bá dúró ti àwọn ará là ń fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ wọn. (2 Kọ́r. 7:​6, 7, 13) Ẹni tó lójú àánú àti ẹni tó máa ń tu àwọn èèyàn nínú ò fi bẹ́ẹ̀ yàtọ̀ síra. Kí nìdí tá a fi sọ bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé ẹni tó lójú àánú máa ń tu àwọn èèyàn nínú, ó sì máa ń fẹ́ yanjú ìṣòro wọn. Torí náà, tá a bá lójú àánú, àá máa tu àwọn èèyàn nínú. Pọ́ọ̀lù jẹ́ ká mọ̀ pé olójú àánú ni Jèhófà, ìdí nìyẹn tó fi máa ń tu àwọn èèyàn nínú. Ó pe Jèhófà ní “Baba àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ àti Ọlọ́run ìtùnú gbogbo.”—2 Kọ́r. 1:3. w23.11 9-10 ¶8-10

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Tuesday, July 22

Ẹ jẹ́ ká máa yọ̀ nígbà tí a bá wà nínú ìpọ́njú.—Róòmù 5:3.

Gbogbo àwa ọmọlẹ́yìn Kristi la máa rí ìpọ́njú. Ẹ jẹ́ ká wo nǹkan tó ṣẹlẹ̀ sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù. Ó sọ fáwọn tó wà ní Tẹsalóníkà pé: “Nígbà tí a wà lọ́dọ̀ yín, a máa ń sọ fún yín pé a máa ní ìpọ́njú, ohun tó sì ṣẹlẹ̀ nìyẹn.” (1 Tẹs. 3:4) Ó sì sọ fáwọn ará Kọ́ríńtì pé: “A fẹ́ kí ẹ mọ̀ nípa ìpọ́njú tó bá wa . . . a ò tiẹ̀ mọ̀ pé ẹ̀mí wa ò ní bọ́.” (2 Kọ́r. 1:8; 11:​23-27) Àwa Kristẹni lónìí náà mọ̀ pé ìgbàkigbà ni ìpọ́njú lè dé bá wa. (2 Tím. 3:12) Àwọn ọ̀rẹ́ àtàwọn mọ̀lẹ́bí ẹ lè máa gbógun tì ẹ́ torí pé o nígbàgbọ́ nínú Jésù, o sì ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ẹ̀. Ṣé àwọn ará ibi iṣẹ́ ẹ ti ń fúngun mọ́ ẹ torí pé o jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun gbogbo? (Héb. 13:18) Àbí àwọn aláṣẹ ìjọba ń ta kò ẹ́ torí pé ò ń wàásù? Láìka ìpọ́njú yòówù kó dé bá wa sí, Pọ́ọ̀lù sọ pé ká máa yọ̀. w23.12 10-11 ¶9-10

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Wednesday, July 23

Wàhálà ńlá lẹ kó mi sí yìí.—Jẹ́n. 34:30.

Ọ̀pọ̀ ìṣòro ni Jékọ́bù fara dà. Àwọn ọmọkùnrin Jékọ́bù tó ń jẹ́ Síméónì àti Léfì dójú ti ilé bàbá wọn, wọ́n sì kó ẹ̀gàn bá orúkọ Jèhófà. Yàtọ̀ síyẹn, Réṣẹ́lì tí Jékọ́bù fẹ́ràn gan-an kú nígbà tó fẹ́ bímọ kejì. Nítorí ìyàn tó mú ní ilẹ̀ náà, ó di dandan kí Jékọ́bù àti ìdílé ẹ̀ ṣí lọ sí Íjíbítì nígbà tó darúgbó. (Jẹ́n. 35:​16-19; 37:28; 45:​9-11, 28) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ìṣòro dé bá Jékọ́bù, kò fi Jèhófà sílẹ̀, ó nígbàgbọ́ nínú àwọn ìlérí tó ṣe, Jèhófà náà sì jẹ́ kó mọ̀ pé òun wà pẹ̀lú ẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, Jèhófà bù kún Jékọ́bù, ó sì jẹ́ kó lóhun ìní tó pọ̀. Ó dájú pé inú Jékọ́bù máa dùn, ó sì máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà gan-an nígbà tó pa dà rí Jósẹ́fù tó rò pé ó ti kú! Torí pé àjọṣe tó dáa wà láàárín Jékọ́bù àti Jèhófà, ìyẹn jẹ́ kó lè borí àwọn ìṣòro tó ní. (Jẹ́n. 30:43; 32:​9, 10; 46:​28-30) Táwa náà bá ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà, àá borí ìṣòro èyíkéyìí tó bá dé bá wa. w23.04 15 ¶6-7

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́