ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Tuesday, July 22

Ẹ jẹ́ ká máa yọ̀ nígbà tí a bá wà nínú ìpọ́njú.—Róòmù 5:3.

Gbogbo àwa ọmọlẹ́yìn Kristi la máa rí ìpọ́njú. Ẹ jẹ́ ká wo nǹkan tó ṣẹlẹ̀ sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù. Ó sọ fáwọn tó wà ní Tẹsalóníkà pé: “Nígbà tí a wà lọ́dọ̀ yín, a máa ń sọ fún yín pé a máa ní ìpọ́njú, ohun tó sì ṣẹlẹ̀ nìyẹn.” (1 Tẹs. 3:4) Ó sì sọ fáwọn ará Kọ́ríńtì pé: “A fẹ́ kí ẹ mọ̀ nípa ìpọ́njú tó bá wa . . . a ò tiẹ̀ mọ̀ pé ẹ̀mí wa ò ní bọ́.” (2 Kọ́r. 1:8; 11:​23-27) Àwa Kristẹni lónìí náà mọ̀ pé ìgbàkigbà ni ìpọ́njú lè dé bá wa. (2 Tím. 3:12) Àwọn ọ̀rẹ́ àtàwọn mọ̀lẹ́bí ẹ lè máa gbógun tì ẹ́ torí pé o nígbàgbọ́ nínú Jésù, o sì ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ẹ̀. Ṣé àwọn ará ibi iṣẹ́ ẹ ti ń fúngun mọ́ ẹ torí pé o jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun gbogbo? (Héb. 13:18) Àbí àwọn aláṣẹ ìjọba ń ta kò ẹ́ torí pé ò ń wàásù? Láìka ìpọ́njú yòówù kó dé bá wa sí, Pọ́ọ̀lù sọ pé ká máa yọ̀. w23.12 10-11 ¶9-10

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Wednesday, July 23

Wàhálà ńlá lẹ kó mi sí yìí.—Jẹ́n. 34:30.

Ọ̀pọ̀ ìṣòro ni Jékọ́bù fara dà. Àwọn ọmọkùnrin Jékọ́bù tó ń jẹ́ Síméónì àti Léfì dójú ti ilé bàbá wọn, wọ́n sì kó ẹ̀gàn bá orúkọ Jèhófà. Yàtọ̀ síyẹn, Réṣẹ́lì tí Jékọ́bù fẹ́ràn gan-an kú nígbà tó fẹ́ bímọ kejì. Nítorí ìyàn tó mú ní ilẹ̀ náà, ó di dandan kí Jékọ́bù àti ìdílé ẹ̀ ṣí lọ sí Íjíbítì nígbà tó darúgbó. (Jẹ́n. 35:​16-19; 37:28; 45:​9-11, 28) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ìṣòro dé bá Jékọ́bù, kò fi Jèhófà sílẹ̀, ó nígbàgbọ́ nínú àwọn ìlérí tó ṣe, Jèhófà náà sì jẹ́ kó mọ̀ pé òun wà pẹ̀lú ẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, Jèhófà bù kún Jékọ́bù, ó sì jẹ́ kó lóhun ìní tó pọ̀. Ó dájú pé inú Jékọ́bù máa dùn, ó sì máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà gan-an nígbà tó pa dà rí Jósẹ́fù tó rò pé ó ti kú! Torí pé àjọṣe tó dáa wà láàárín Jékọ́bù àti Jèhófà, ìyẹn jẹ́ kó lè borí àwọn ìṣòro tó ní. (Jẹ́n. 30:43; 32:​9, 10; 46:​28-30) Táwa náà bá ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà, àá borí ìṣòro èyíkéyìí tó bá dé bá wa. w23.04 15 ¶6-7

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Thursday, July 24

Jèhófà ni Olùṣọ́ Àgùntàn mi. Èmi kì yóò ṣaláìní.—Sm. 23:1.

Sáàmù 23 jẹ́ ká rí i pé òótọ́ ni Jèhófà nífẹ̀ẹ́ wa, ó sì ń bójú tó wa. Dáfídì tó kọ Sáàmù yìí ṣàlàyé bí ìfẹ́ tó wà láàárín òun àti Jèhófà tó ń ṣọ́ ọ bí Olùṣọ́ àgùntàn ṣe lágbára tó. Ọkàn Dáfídì balẹ̀ bó ṣe jẹ́ kí Jèhófà máa tọ́ òun sọ́nà, ìyẹn sì jẹ́ kó gbẹ́kẹ̀ lé e pátápátá. Torí náà, ó dá Dáfídì lójú pé ojoojúmọ́ ni Jèhófà á máa nífẹ̀ẹ́ òun. Kí ló mú kó dá a lójú? Dáfídì gbà pé Jèhófà bójú tó òun dáadáa torí gbogbo ìgbà ni Jèhófà pèsè ohun tó nílò. Yàtọ̀ síyẹn, Dáfídì gbádùn bóun àti Jèhófà ṣe jẹ́ ọ̀rẹ́, ó sì tún rí ojúure ẹ̀. Ìdí nìyẹn tó fi dá a lójú pé ohun yòówù kó ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú, Jèhófà máa bójú tó òun. Dáfídì gbà pé ìfẹ́ oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ tí Jèhófà ní sóun máa jẹ́ kóun borí ìṣòro yòówù kóun ní, ó sì máa jẹ́ kóun láyọ̀, kóun sì ní ìtẹ́lọ́rùn.—Sm. 16:11. w24.01 28-29 ¶12-13

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́