Thursday, July 24
Jèhófà ni Olùṣọ́ Àgùntàn mi. Èmi kì yóò ṣaláìní.—Sm. 23:1.
Sáàmù 23 jẹ́ ká rí i pé òótọ́ ni Jèhófà nífẹ̀ẹ́ wa, ó sì ń bójú tó wa. Dáfídì tó kọ Sáàmù yìí ṣàlàyé bí ìfẹ́ tó wà láàárín òun àti Jèhófà tó ń ṣọ́ ọ bí Olùṣọ́ àgùntàn ṣe lágbára tó. Ọkàn Dáfídì balẹ̀ bó ṣe jẹ́ kí Jèhófà máa tọ́ òun sọ́nà, ìyẹn sì jẹ́ kó gbẹ́kẹ̀ lé e pátápátá. Torí náà, ó dá Dáfídì lójú pé ojoojúmọ́ ni Jèhófà á máa nífẹ̀ẹ́ òun. Kí ló mú kó dá a lójú? Dáfídì gbà pé Jèhófà bójú tó òun dáadáa torí gbogbo ìgbà ni Jèhófà pèsè ohun tó nílò. Yàtọ̀ síyẹn, Dáfídì gbádùn bóun àti Jèhófà ṣe jẹ́ ọ̀rẹ́, ó sì tún rí ojúure ẹ̀. Ìdí nìyẹn tó fi dá a lójú pé ohun yòówù kó ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú, Jèhófà máa bójú tó òun. Dáfídì gbà pé ìfẹ́ oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ tí Jèhófà ní sóun máa jẹ́ kóun borí ìṣòro yòówù kóun ní, ó sì máa jẹ́ kóun láyọ̀, kóun sì ní ìtẹ́lọ́rùn.—Sm. 16:11. w24.01 28-29 ¶12-13
Friday, July 25
Mo wà pẹ̀lú yín ní gbogbo ọjọ́ títí dé ìparí ètò àwọn nǹkan.—Mát. 28:20.
Àtìgbà Ogun Àgbáyé Kejì làwa èèyàn Jèhófà ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ti ń gbádùn àlàáfíà déwọ̀n àyè kan, a sì lómìnira láti wàásù. Kódà, kárí ayé làwa èèyàn Jèhófà ti ń wàásù, ọ̀pọ̀ èèyàn sì ti wá mọ Jèhófà. Lónìí, àwọn arákùnrin tó wà nínú Ìgbìmọ̀ Olùdarí náà ń jẹ́ kí Kristi tọ́ àwọn sọ́nà. Tí wọ́n bá fẹ́ ṣèpinnu nípa ohun táwọn ará máa ṣe, wọ́n máa ń fẹ́ kó jẹ́ pé ohun tí Jèhófà àti Kristi fẹ́ làwọn máa sọ fáwọn ará. Lẹ́yìn tí wọ́n bá ṣèpinnu náà tán, wọ́n máa ń ní káwọn alábòójútó àyíká àtàwọn alàgbà fi jíṣẹ́ fáwọn ará nínú ìjọ. Ó ṣe tán, àwọn alàgbà tó jẹ́ ẹni àmì òróró títí kan gbogbo àwọn alàgbà tó wà nínú ìjọ ló wà ní “ọwọ́ ọ̀tún” Kristi. (Ìfi. 2:1) Ká sòótọ́, aláìpé làwọn alàgbà yìí, wọ́n sì máa ń ṣàṣìṣe. Àwọn ìgbà kan wà tí Mósè àti Jóṣúà ṣàṣìṣe, àwọn àpọ́sítélì náà sì ṣàṣìṣe. (Nọ́ń. 20:12; Jóṣ. 9:14, 15; Róòmù 3:23) Síbẹ̀, Kristi ṣì ń fìfẹ́ bójú tó ẹrú olóòótọ́ àtàwọn alàgbà, á sì máa ṣe bẹ́ẹ̀ nìṣó. Torí náà, kò sídìí tí ò fi yẹ ká ṣe ohun tí wọ́n bá sọ fún wa torí Kristi ló ń darí wọn. w24.02 23-24 ¶13-14
Saturday, July 26
Ẹ máa fara wé Ọlọ́run, bí àwọn àyànfẹ́ ọmọ.—Éfé. 5:1.
Lónìí, a lè múnú Jèhófà dùn tá a bá ń dúpẹ́ oore tó ṣe wá, tá a sì ń jẹ́ káwọn èèyàn mọ bó ṣe nífẹ̀ẹ́ wa tó. Ohun tó ṣe pàtàkì jù tá a bá ń wàásù ni pé ká ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ láti wá sin Jèhófà, ká sì jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé ó nífẹ̀ẹ́ wa gan-an. (Jém. 4:8) Inú wa máa ń dùn láti jẹ́ káwọn èèyàn mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa Jèhófà pé ó nífẹ̀ẹ́ wa, onídàájọ́ òdodo ni, ó gbọ́n, ó lágbára, ó sì tún láwọn ànímọ́ míì tó jẹ́ ká lè sún mọ́ ọn. A tún máa ń yin Jèhófà, a sì máa ń múnú ẹ̀ dùn bá a ṣe ń sapá láti fara wé e. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn èèyàn máa kíyè sí pé ìwà wa yàtọ̀ sí tàwọn tí ò mọ Jèhófà nínú ayé burúkú yìí. (Mát. 5:14-16) Bá a ṣe ń báwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójoojúmọ́, á ṣeé ṣe fún wa láti ṣàlàyé ìdí tí ìwà wa fi yàtọ̀, ìyẹn á sì mú káwọn olóòótọ́ ọkàn wá sin Jèhófà. Tá a bá ń yin Jèhófà lọ́nà yìí, inú ẹ̀ á máa dùn sí wa.—1 Tím. 2:3, 4. w24.02 10 ¶7