ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Friday, July 25

Mo wà pẹ̀lú yín ní gbogbo ọjọ́ títí dé ìparí ètò àwọn nǹkan.—Mát. 28:20.

Àtìgbà Ogun Àgbáyé Kejì làwa èèyàn Jèhófà ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ti ń gbádùn àlàáfíà déwọ̀n àyè kan, a sì lómìnira láti wàásù. Kódà, kárí ayé làwa èèyàn Jèhófà ti ń wàásù, ọ̀pọ̀ èèyàn sì ti wá mọ Jèhófà. Lónìí, àwọn arákùnrin tó wà nínú Ìgbìmọ̀ Olùdarí náà ń jẹ́ kí Kristi tọ́ àwọn sọ́nà. Tí wọ́n bá fẹ́ ṣèpinnu nípa ohun táwọn ará máa ṣe, wọ́n máa ń fẹ́ kó jẹ́ pé ohun tí Jèhófà àti Kristi fẹ́ làwọn máa sọ fáwọn ará. Lẹ́yìn tí wọ́n bá ṣèpinnu náà tán, wọ́n máa ń ní káwọn alábòójútó àyíká àtàwọn alàgbà fi jíṣẹ́ fáwọn ará nínú ìjọ. Ó ṣe tán, àwọn alàgbà tó jẹ́ ẹni àmì òróró títí kan gbogbo àwọn alàgbà tó wà nínú ìjọ ló wà ní “ọwọ́ ọ̀tún” Kristi. (Ìfi. 2:1) Ká sòótọ́, aláìpé làwọn alàgbà yìí, wọ́n sì máa ń ṣàṣìṣe. Àwọn ìgbà kan wà tí Mósè àti Jóṣúà ṣàṣìṣe, àwọn àpọ́sítélì náà sì ṣàṣìṣe. (Nọ́ń. 20:12; Jóṣ. 9:​14, 15; Róòmù 3:23) Síbẹ̀, Kristi ṣì ń fìfẹ́ bójú tó ẹrú olóòótọ́ àtàwọn alàgbà, á sì máa ṣe bẹ́ẹ̀ nìṣó. Torí náà, kò sídìí tí ò fi yẹ ká ṣe ohun tí wọ́n bá sọ fún wa torí Kristi ló ń darí wọn. w24.02 23-24 ¶13-14

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, July 26

Ẹ máa fara wé Ọlọ́run, bí àwọn àyànfẹ́ ọmọ.—Éfé. 5:1.

Lónìí, a lè múnú Jèhófà dùn tá a bá ń dúpẹ́ oore tó ṣe wá, tá a sì ń jẹ́ káwọn èèyàn mọ bó ṣe nífẹ̀ẹ́ wa tó. Ohun tó ṣe pàtàkì jù tá a bá ń wàásù ni pé ká ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ láti wá sin Jèhófà, ká sì jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé ó nífẹ̀ẹ́ wa gan-an. (Jém. 4:8) Inú wa máa ń dùn láti jẹ́ káwọn èèyàn mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa Jèhófà pé ó nífẹ̀ẹ́ wa, onídàájọ́ òdodo ni, ó gbọ́n, ó lágbára, ó sì tún láwọn ànímọ́ míì tó jẹ́ ká lè sún mọ́ ọn. A tún máa ń yin Jèhófà, a sì máa ń múnú ẹ̀ dùn bá a ṣe ń sapá láti fara wé e. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn èèyàn máa kíyè sí pé ìwà wa yàtọ̀ sí tàwọn tí ò mọ Jèhófà nínú ayé burúkú yìí. (Mát. 5:​14-16) Bá a ṣe ń báwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójoojúmọ́, á ṣeé ṣe fún wa láti ṣàlàyé ìdí tí ìwà wa fi yàtọ̀, ìyẹn á sì mú káwọn olóòótọ́ ọkàn wá sin Jèhófà. Tá a bá ń yin Jèhófà lọ́nà yìí, inú ẹ̀ á máa dùn sí wa.—1 Tím. 2:​3, 4. w24.02 10 ¶7

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, July 27

Kó lè gbani níyànjú, kó sì báni wí.—Títù 1:9.

Kó o tó lè di ọkùnrin Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀, o gbọ́dọ̀ kọ́ àwọn nǹkan tó máa ṣe ẹ́ láǹfààní. Ìyẹn máa jẹ́ kó o lè bójú tó iṣẹ́ tí wọ́n bá gbé fún ẹ dáadáa nínú ìjọ, á jẹ́ kó o ríṣẹ́ tí wàá fi máa bójú tó ara ẹ tàbí ìdílé ẹ, á sì jẹ́ kí àjọṣe àárín ìwọ àtàwọn ẹlòmíì gún. Bí àpẹẹrẹ, kọ́ bó o ṣe lè mọ̀wé kọ, kó o sì mọ̀ ọ́n kà dáadáa. Bíbélì sọ pé tí ẹnì kan bá ń ka Bíbélì lójoojúmọ́ tó sì ń ṣàṣàrò lórí ẹ̀, ó máa láyọ̀, gbogbo ohun tó bá ń ṣe á sì máa yọrí sí rere. (Sm. 1:​1-3) Torí náà, tó bá ń ka Bíbélì lójoojúmọ́, á máa ṣe nǹkan lọ́nà tí Jèhófà fẹ́, á sì jẹ́ kó mọ bó ṣe máa fi àwọn nǹkan tó ń kọ́ sílò. (Òwe 1:​3, 4) Àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin nílò àwọn ọkùnrin tó lè fi Bíbélì kọ́ni dáadáa, kí wọ́n sì fi gbà wọ́n níyànjú. Tó o bá mọ̀wé kọ tó o sì mọ̀ ọ́n kà dáadáa, wàá lè múra àsọyé àti ìdáhùn tó máa gbé ìgbàgbọ́ àwọn ará ró, tí wọ́n á sì rí ẹ̀kọ́ kọ́ nínú ẹ̀. Yàtọ̀ síyẹn, wàá lè ṣàkọsílẹ̀ àwọn nǹkan tó máa mú kí ìgbàgbọ́ ẹ túbọ̀ lágbára, wàá sì lè fún àwọn ẹlòmíì níṣìírí. w23.12 26-27 ¶9-11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́