Wednesday, September 24
Níbi tí a tẹ̀ síwájú dé, ẹ jẹ́ kí a máa rìn létòlétò ní ọ̀nà kan náà.—Fílí. 3:16.
Látìgbàdégbà, wàá máa gbọ́ ìrírí àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin tó ti pinnu láti ṣe púpọ̀ sí i nínú iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ lè lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run tàbí kí wọ́n kó lọ síbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù púpọ̀ sí i. Tí ipò ẹ bá gbà ẹ́ láyè, irú àwọn nǹkan tó yẹ kíwọ náà fi ṣe àfojúsùn ẹ nìyẹn. Ìdí sì ni pé àwa èèyàn Jèhófà máa ń sapá láti ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wa. (Ìṣe 16:9) Àmọ́ ká sọ pé o ò tíì lè ṣe bẹ́ẹ̀ báyìí ńkọ́? Má ṣe rò pé o ò dáa tó àwọn tó ń ṣe bẹ́ẹ̀. Ohun tó ṣe pàtàkì jù ni pé kó o máa fi ìfaradà sá eré ìje náà nìṣó. (Mát. 10:22) Má gbàgbé pé ohun tó máa múnú Jèhófà dùn ni pé kó o máa ṣe nǹkan tágbára ẹ gbé lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ẹ̀. Ọ̀kan lára ohun tó dáa jù tó o lè ṣe láti máa tẹ̀ lé Jésù nìyẹn lẹ́yìn tó o bá ṣèrìbọmi.—Sm. 26:1. w24.03 10 ¶11
Thursday, September 25
Ó dárí gbogbo àṣemáṣe wa jì wá tinútinú.—Kól. 2:13.
Jèhófà Bàbá wa ọ̀run ṣèlérí pé òun máa dárí jì wá tá a bá ronú pìwà dà. (Sm. 86:5) Torí náà, tá a bá ronú pìwà dà tọkàntọkàn torí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tá a ti dá, ó yẹ ká gbà pé òótọ́ ni Jèhófà sọ pé òun ti dárí jì wá. Máa rántí pé Jèhófà máa ń gba tiwa rò. Kì í retí pé ká ṣe ju agbára wa lọ. Ó mọyì ohunkóhun tá a bá ṣe, tó bá ṣáà ti jẹ́ pé gbogbo ohun tágbára wa gbé là ń ṣe. Bákan náà, a tún lè ronú nípa àwọn tó sin Jèhófà tọkàntọkàn nínú Bíbélì. Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù. Ọ̀pọ̀ ọdún ló fi lo ìtara lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, ó rin ìrìn ọ̀pọ̀ máìlì, ó sì dá ìjọ tó pọ̀ sílẹ̀. Síbẹ̀, nígbà tí ò lè ṣe tó ti tẹ́lẹ̀ mọ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, ṣé ìyẹn wá túmọ̀ sí pé inú Jèhófà ò dùn sí i mọ́? Rárá o. Ó ń ṣe gbogbo ohun tó lè ṣe, Jèhófà sì bù kún un. (Ìṣe 28:30, 31) Lọ́nà kan náà, àwọn ìgbà míì wà tá a lè má lè ṣe tó bá a ṣe fẹ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. Àmọ́ ohun tó ṣe pàtàkì jù lójú Jèhófà ni ìdí tá a fi ń ṣe é. w24.03 27 ¶7, 9
Friday, September 26
Ní àárọ̀ kùtù, tí ilẹ̀ ò tíì mọ́, [Jésù] dìde, ó jáde lọ síbi tó dá, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í gbàdúrà níbẹ̀.—Máàkù 1:35.
Jésù fi àpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ nígbà tó gbàdúrà sí Jèhófà. Jálẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀, gbogbo ìgbà ni Jésù máa ń gbàdúrà. Ńṣe ni Jésù máa ń wáyè gbàdúrà torí pé ọwọ́ ẹ̀ máa ń dí gan-an, ọ̀pọ̀ èèyàn sì máa ń wà lọ́dọ̀ ẹ̀. (Máàkù 6:31, 45, 46) Ó máa ń jí láàárọ̀ kùtù láti lọ dá gbàdúrà. Kódà, ìgbà kan wà tó fi gbogbo òru gbàdúrà nígbà tó fẹ́ ṣe ìpinnu pàtàkì kan. (Lúùkù 6:12, 13) Yàtọ̀ síyẹn, ní alẹ́ tó ṣáájú ikú Jésù, léraléra ló gbàdúrà sí Jèhófà bó ṣe ń ronú nípa bó ṣe máa parí èyí tó le jù lára iṣẹ́ tó wá ṣe láyé. (Mát. 26:39, 42, 44) Àpẹẹrẹ Jésù kọ́ wa pé bó ti wù kí ọwọ́ wa dí tó, ó yẹ ká máa wáyè gbàdúrà. Bíi ti Jésù, ó yẹ káwa náà ya àkókò sọ́tọ̀ láti máa gbàdúrà, ó sì lè gba pé ká tètè jí láàárọ̀ tàbí ká gbàdúrà ká tó lọ sùn lálẹ́. Tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀, àá fi hàn pé a mọyì àǹfààní tí Jèhófà fún wa láti gbàdúrà. w23.05 3 ¶4-5