Saturday, September 6
Ẹ jẹ́ àpẹẹrẹ fún agbo.—1 Pét. 5:3.
Tí ọ̀dọ́ kan bá ṣiṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà, á jẹ́ kó mọ bó ṣe lè bá onírúurú èèyàn ṣiṣẹ́. Yàtọ̀ síyẹn, á jẹ́ kó mọ bá a ṣe ń ṣówó ná. (Fílí. 4:11-13) Tó o bá fẹ́ ṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún, iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà olùrànlọ́wọ́ lo máa kọ́kọ́ fi bẹ̀rẹ̀, ìyẹn sì máa jẹ́ kó rọrùn fún ẹ láti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà déédéé. Tó o bá ṣiṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà, á jẹ́ kó o láǹfààní láti ṣiṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún míì. Bí àpẹẹrẹ, o lè di ọ̀kan lára àwọn tó ń kọ́lé ètò Ọlọ́run tàbí kó o máa sìn ní Bẹ́tẹ́lì. Ó yẹ káwọn arákùnrin máa ṣiṣẹ́ kára kí wọ́n lè kúnjú ìwọ̀n láti di alàgbà, á sì jẹ́ kí wọ́n lè sin àwọn ará nínú ìjọ. Bíbélì sọ pé táwọn arákùnrin bá ń ṣiṣẹ́ kára láti di alábòójútó, ‘iṣẹ́ rere ni wọ́n fẹ́ ṣe.’ (1 Tím. 3:1) Ohun àkọ́kọ́ ni pé kó kúnjú ìwọ̀n láti di ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́. Onírúurú ọ̀nà làwọn ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ ń gbà ran àwọn alàgbà lọ́wọ́. Torí pé àwọn alàgbà àtàwọn ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ nírẹ̀lẹ̀, wọ́n ń ran àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin lọ́wọ́, wọ́n sì ń fìtara wàásù pẹ̀lú wọn. w23.12 28 ¶14-16
Sunday, September 7
Nígbà tó ṣì jẹ́ ọ̀dọ́kùnrin, ó bẹ̀rẹ̀ sí í wá Ọlọ́run Dáfídì baba ńlá rẹ̀.—2 Kíró. 34:3.
Ọ̀dọ́ ni Ọba Jòsáyà nígbà tó bẹ̀rẹ̀ sí í wá Jèhófà. Ó fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, kó sì máa ṣohun tó fẹ́. Àmọ́ nǹkan ò rọrùn fún ọba tó jẹ́ ọ̀dọ́ yìí. Nígbà yẹn, ìjọsìn èké lọ̀pọ̀ èèyàn ń ṣe. Torí náà, ó di dandan pé kí Jòsáyà fìgboyà gbèjà ìjọsìn tòótọ́, ohun tó sì ṣe gan-an nìyẹn. Kódà, kí Jòsáyà tó pé ọmọ ogún (20) ọdún ló ti bẹ̀rẹ̀ sí í mú ìjọsìn èké kúrò lórílẹ̀-èdè náà. (2 Kíró. 34:1, 2) Tó o bá jẹ́ ọ̀dọ́, o lè fara wé Jòsáyà tó o bá ń wá Jèhófà, tó o sì ń fàwọn ànímọ́ ẹ̀ ṣèwà hù. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, á wù ẹ́ láti ya ara ẹ sí mímọ́ fún Jèhófà. Kí nìyẹn máa mú kó o ṣe lójoojúmọ́? Arákùnrin Luke tó ṣèrìbọmi nígbà tó wà lọ́mọ ọdún mẹ́rìnlá (14) sọ pé: “Àtìgbà tí mo ti ya ara mi sí mímọ́ ni mo ti pinnu pé ìfẹ́ Jèhófà ló máa gbawájú láyé mi, màá sì máa múnú ẹ̀ dùn.” (Máàkù 12:30) Tíwọ náà bá pinnu pé ohun tó o máa ṣe nìyẹn, wàá láyọ̀! w23.09 11 ¶12-13
Monday, September 8
Ẹ máa bọ̀wọ̀ fún àwọn tó ń ṣiṣẹ́ kára láàárín yín, tí wọ́n ń ṣe àbójútó yín nínú Olúwa.—1 Tẹs. 5:12.
Kò tíì pé ọdún kan tí wọ́n dá ìjọ Tẹsalóníkà sílẹ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ lẹ́tà rẹ̀ sí wọn. Torí náà, àwọn alábòójútó tí wọ́n yàn síbẹ̀ lè má fi bẹ́ẹ̀ nírìírí, wọ́n sì lè ṣe àwọn àṣìṣe kan. Síbẹ̀, àwọn ará ìjọ náà ń bọ̀wọ̀ fún wọn. Bí ìpọ́njú ńlá ṣe ń sún mọ́lé, ó máa gba pé ká túbọ̀ máa ṣe ohun táwọn alàgbà ìjọ wa bá sọ fún wa ju bá a ṣe ń ṣe lọ báyìí. Ìdí ni pé ó lè má ṣeé ṣe láti kàn sí orílé iṣẹ́ wa tàbí ẹ̀ka ọ́fíìsì wa mọ́ nígbà yẹn. Torí náà, ó ṣe pàtàkì pé ká nífẹ̀ẹ́, ká sì máa bọ̀wọ̀ fáwọn alàgbà ìjọ wa báyìí. Ohun yòówù kó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ ká máa ronú bó ṣe tọ́. Ká má máa wo kùdìẹ̀-kudiẹ wọn. Ohun tó yẹ ká máa wò ni pé Jèhófà ti yan Kristi láti máa darí àwọn ọkùnrin olóòótọ́ yìí. Bí akoto ṣe máa ń dáàbò bo orí ọmọ ogun kan, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí tá a ní pé Jèhófà máa gbà wá là lọ́jọ́ iwájú máa ń dáàbò bò wá ká lè máa ronú bó ṣe tọ́. A mọ̀ pé kò sóhun rere kankan tí ayé yìí lè fún wa. (Fílí. 3:8) Ìrètí yìí ló ń fi wá lọ́kàn balẹ̀. w23.06 11-12 ¶11-12