Sunday, September 7
Nígbà tó ṣì jẹ́ ọ̀dọ́kùnrin, ó bẹ̀rẹ̀ sí í wá Ọlọ́run Dáfídì baba ńlá rẹ̀.—2 Kíró. 34:3.
Ọ̀dọ́ ni Ọba Jòsáyà nígbà tó bẹ̀rẹ̀ sí í wá Jèhófà. Ó fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, kó sì máa ṣohun tó fẹ́. Àmọ́ nǹkan ò rọrùn fún ọba tó jẹ́ ọ̀dọ́ yìí. Nígbà yẹn, ìjọsìn èké lọ̀pọ̀ èèyàn ń ṣe. Torí náà, ó di dandan pé kí Jòsáyà fìgboyà gbèjà ìjọsìn tòótọ́, ohun tó sì ṣe gan-an nìyẹn. Kódà, kí Jòsáyà tó pé ọmọ ogún (20) ọdún ló ti bẹ̀rẹ̀ sí í mú ìjọsìn èké kúrò lórílẹ̀-èdè náà. (2 Kíró. 34:1, 2) Tó o bá jẹ́ ọ̀dọ́, o lè fara wé Jòsáyà tó o bá ń wá Jèhófà, tó o sì ń fàwọn ànímọ́ ẹ̀ ṣèwà hù. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, á wù ẹ́ láti ya ara ẹ sí mímọ́ fún Jèhófà. Kí nìyẹn máa mú kó o ṣe lójoojúmọ́? Arákùnrin Luke tó ṣèrìbọmi nígbà tó wà lọ́mọ ọdún mẹ́rìnlá (14) sọ pé: “Àtìgbà tí mo ti ya ara mi sí mímọ́ ni mo ti pinnu pé ìfẹ́ Jèhófà ló máa gbawájú láyé mi, màá sì máa múnú ẹ̀ dùn.” (Máàkù 12:30) Tíwọ náà bá pinnu pé ohun tó o máa ṣe nìyẹn, wàá láyọ̀! w23.09 11 ¶12-13
Monday, September 8
Ẹ máa bọ̀wọ̀ fún àwọn tó ń ṣiṣẹ́ kára láàárín yín, tí wọ́n ń ṣe àbójútó yín nínú Olúwa.—1 Tẹs. 5:12.
Kò tíì pé ọdún kan tí wọ́n dá ìjọ Tẹsalóníkà sílẹ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ lẹ́tà rẹ̀ sí wọn. Torí náà, àwọn alábòójútó tí wọ́n yàn síbẹ̀ lè má fi bẹ́ẹ̀ nírìírí, wọ́n sì lè ṣe àwọn àṣìṣe kan. Síbẹ̀, àwọn ará ìjọ náà ń bọ̀wọ̀ fún wọn. Bí ìpọ́njú ńlá ṣe ń sún mọ́lé, ó máa gba pé ká túbọ̀ máa ṣe ohun táwọn alàgbà ìjọ wa bá sọ fún wa ju bá a ṣe ń ṣe lọ báyìí. Ìdí ni pé ó lè má ṣeé ṣe láti kàn sí orílé iṣẹ́ wa tàbí ẹ̀ka ọ́fíìsì wa mọ́ nígbà yẹn. Torí náà, ó ṣe pàtàkì pé ká nífẹ̀ẹ́, ká sì máa bọ̀wọ̀ fáwọn alàgbà ìjọ wa báyìí. Ohun yòówù kó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ ká máa ronú bó ṣe tọ́. Ká má máa wo kùdìẹ̀-kudiẹ wọn. Ohun tó yẹ ká máa wò ni pé Jèhófà ti yan Kristi láti máa darí àwọn ọkùnrin olóòótọ́ yìí. Bí akoto ṣe máa ń dáàbò bo orí ọmọ ogun kan, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí tá a ní pé Jèhófà máa gbà wá là lọ́jọ́ iwájú máa ń dáàbò bò wá ká lè máa ronú bó ṣe tọ́. A mọ̀ pé kò sóhun rere kankan tí ayé yìí lè fún wa. (Fílí. 3:8) Ìrètí yìí ló ń fi wá lọ́kàn balẹ̀. w23.06 11-12 ¶11-12
Tuesday, September 9
Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo. Òpè ni.—Òwe 9:13.
Àwọn tó ń gbọ́ ohun tí “òmùgọ̀ obìnrin” yẹn ń sọ máa ní láti ṣe ìpinnu: Ṣé wọ́n máa lọ sọ́dọ̀ ẹ̀ àbí wọn ò ní lọ? Ìdí pàtàkì wà tí ò fi yẹ ká ṣèṣekúṣe. Bíbélì ní “òmùgọ̀ obìnrin” ń sọ pé: “Omi tí a jí gbé máa ń dùn.” (Òwe 9:17) Kí ni “omi tí a jí gbé”? Bíbélì sọ pé ìbálòpọ̀ tó wà láàárín tọkọtaya dà bí omi tó ń tuni lára. (Òwe 5:15-18) Ọkùnrin àti obìnrin tó ti ṣègbéyàwó sì máa ń gbádùn ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ara wọn tí wọ́n bá ṣe é lọ́nà tó tọ́. Ẹ ò rí i pé ìyẹn yàtọ̀ pátápátá sí “omi tí a jí gbé,” tó ṣeé ṣe kó jẹ́ ìbálòpọ̀ tí ò bófin mu tó ń wáyé láàárín àwọn tí ò bá ara wọn ṣègbéyàwó. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ kì í jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé wọ́n ń bára wọn lò pọ̀. Ṣe ló dà bí olè tí kì í jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ tó bá fẹ́ jí nǹkan. “Omi tí a jí gbé” máa ń dùn lẹ́nu àwọn tó ń mu ún torí wọ́n rò pé wọn ò ní jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ẹ ò rí i pé wọ́n ń tan ara wọn jẹ ni! Jèhófà ń rí gbogbo ohun tí wọ́n ń ṣe. Kò sí nǹkan tó korò tó kéèyàn pàdánù ojú rere Jèhófà, torí náà kò sí adùn kankan níbẹ̀.—1 Kọ́r. 6:9, 10. w23.06 22 ¶7-9