ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • my ìtàn 66
  • Jésíbẹ́lì—Ayaba Búburú

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jésíbẹ́lì—Ayaba Búburú
  • Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ọlọ́run Fìyà Jẹ Ayaba Kan Tó Burú Gan-an
    Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àkókò Yìí Gan-an Ló Yẹ Kó O Gbé Ìgbésẹ̀ Kánkán
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Ó Fara Da Ìwà Ìrẹ́jẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • “Gbogbo Ilé Áhábù Ló Máa Ṣègbé”—2Ọb 9:8
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
Àwọn Míì
Ìwé Ìtàn Bíbélì
my ìtàn 66
Àwọn ọkùnrin tó wà ní ààfin fẹ́ ti Ayaba Jésíbẹ́lì síta láti ojú fèrèsé

ÌTÀN 66

Jésíbẹ́lì—Ayaba Búburú

LẸ́YÌN tí Jèróbóámù Ọba kú, gbogbo ọba yòókù tó jẹ lórí ẹ̀yà mẹ́wàá tó wà ní àríwá ló burú. Áhábù Ọba ló burú jù nínú gbogbo àwọn ọba yẹn. Ǹjẹ́ o mọ ìdí rẹ̀? Ìdí pàtàkì kan ni ti ìyàwó rẹ̀, Jésíbẹ́lì Ayaba búburú.

Jésíbẹ́lì kì í ṣe ọmọ Ísírẹ́lì. Ọmọbìnrin ọba Sídónì ni. Báálì, ọlọ́run èké, ló ń sìn, ó sì mú kí Áhábù àti ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa sin Báálì pẹ̀lú. Jésíbẹ́lì kórìíra Jèhófà ó sì pa púpọ̀ nínú àwọn wòlíì rẹ̀. Ṣe làwọn mìíràn ní láti sá pa mọ́ sínú ihò òkúta kó má bàa pa wọ́n. Bí Jésíbẹ́lì bá ń fẹ́ ohun kan, ó tiẹ̀ lè pa èèyàn kó bàa lè rí ohun náà.

Lọjọ́ kan, inú Áhábù bà jẹ́ gan-an. Nítorí náà, Jésíbẹ́lì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: ‘Kí ló dé tí inú rẹ fi bà jẹ́ lónìí?’

Áhábù dáhùn pé: ‘Nítorí ohun tí Nábótì sọ fún mi ni. Mo fẹ́ ra ọgbà àjàrà rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó sọ pé òun kò lè tà á fún mi.’

Jésíbẹ́lì fèsì pé: ‘Má dààmú ara rẹ. Màá gbà á fún ẹ.’

Nítorí náà, Jésíbẹ́lì kọ̀wé sí àwọn ìjòyè kan ní ìlú ibi tí ọkùnrin tó ń jẹ́ Nábótì yẹn ń gbé. Ó sọ fún wọn pé: ‘Ẹ mú kí àwọn èèyàn lásán kan wí pé Nábótì ti bú Ọlọ́run àti ọba. Lẹ́yìn náà, kẹ́ ẹ mú Nábótì kúrò ní ìlú kẹ́ ẹ sì sọ ọ́ lókùúta pa.’

Kété tí Jésíbẹ́lì gbọ́ pé Nábótì ti kú, ó sọ fún Áhábù pé: ‘Nísinsìnyí lọ gba ọgbà àjàrà rẹ̀.’ Ṣé o kò gbà pé ó yẹ kí Jésíbẹ́lì jẹ ìyà fún ṣíṣe irú ohun tó burú bẹ́ẹ̀?

Nítorí náà, nígbà tó yá, Jèhófà rán ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Jéhù láti jẹ ẹ́ ní ìyà. Nígbà tí Jésíbẹ́lì gbọ́ pé Jéhù ń bọ̀, ó kun ojú rẹ̀, ó sì gbìyànjú láti ṣe ara lọ́ṣọ̀ọ́. Ṣùgbọ́n nígbà tí Jéhù dé tó sì rí Jésíbẹ́lì ní ojú fèrèsé, ó ké sí àwọn ọkùnrin tó wà ní ààfin pé: ‘Ẹ jù ú sí ìsàlẹ̀!’ Àwọn èèyàn náà ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bó o ti ń wò ó nínú àwòrán yìí. Wọ́n jù ú sí ìsàlẹ̀, ó sì kú. Ìgbẹ̀yìn ayé Jésíbẹ́lì Ayaba búburú nìyẹn o.

1 Àwọn Ọba 16:29-33; 18:1-4; 21:1-16; 2 Àwọn Ọba 9:30-37.

Àwọn Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́