ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • my ìtàn 91
  • Jésù Kọ́ Àwọn Èèyàn Lórí Òkè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jésù Kọ́ Àwọn Èèyàn Lórí Òkè
  • Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Yíyan Awọn Apọsiteli Rẹ̀
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • Jésù Yan Àwọn Àpọ́sítélì Méjìlá
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Jésù Yan Àwọn Àpọ́sítélì Méjìlá
    Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àwọn Tó Di Ọmọ Ẹ̀yìn Jésù
    Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Olùkọ́ Ńlá Náà
Àwọn Míì
Ìwé Ìtàn Bíbélì
my ìtàn 91
Jésù ń kọ́ àwọn èèyàn ní Ìwàásù Lórí Òkè

ÌTÀN 91

Jésù Kọ́ Àwọn Èèyàn Lórí Òkè

JÉSÙ ló jókòó yẹn. Ó ń kọ́ gbogbo àwọn èèyàn wọ̀nyí lórí òkè kan ní Gálílì. Àwọn tó jókòó sún mọ́ ọn wọ̀nyẹn làwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀. Ó yan méjìlá [12] nínú wọn láti jẹ́ àpọ́sítélì. Àwọn àpọ́sítélì ni àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù pàtàkì. Ǹjẹ́ o mọ orúkọ wọn?

Símónì Pétérù àti Áńdérù tí wọ́n jẹ́ tẹ̀gbọ́n-tàbúrò wà nínú wọn. Jákọ́bù àti Jòhánù táwọn pẹ̀lú jẹ́ tẹ̀gbọ́n-tàbúrò wà lára wọn. Àpọ́sítélì mìíràn tún wà tó ń jẹ́ Jákọ́bù, òmíràn sì tún wà tó ń jẹ́ Símónì. Àwọn méjì ló ń jẹ́ Júdásì. Èyí àkọ́kọ́ ni Júdásì Ísíkáríótù, èkejì la tún ń pè ní Tádéọ́sì. Fílípì àti Nàtáníẹ́lì (tó tún ń jẹ́ Bátólómíù) wà tó fi mọ́ Mátíù àti Tọ́másì.

Lẹ́yìn tí Jésù ti Samáríà dé, ó bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù fún ìgbà àkọ́kọ́ pé: ‘Ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ǹjẹ́ o mọ ohun tí ìjọba yẹn jẹ́? Ìjọba gidi ti Ọlọ́run ni. Jésù ni ọba rẹ̀. Láti ọ̀run láá ti máa ṣàkóso á sì mú àlàáfíà wá sí ayé. Ìjọba Ọlọ́run á sọ gbogbo ayé di Párádísè ẹlẹ́wà.

Ẹ̀kọ́ nípa Ìjọba Ọlọ́run ni Jésù ń kọ́ àwọn èèyàn níbí yìí. Ó ṣàlàyé pé, ‘Bí ẹ óò ti máa gbàdúrà nìyí: Bàbá wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Kí ìjọba rẹ dé. Kí ìfẹ́ rẹ ṣẹ, bíi ti ọ̀run, lórí ilẹ̀ ayé pẹ̀lú.’ ‘Àdúrà Olúwa’ ni ọ̀pọ̀ máa ń pè é. Àwọn míì máa ń pè é ní ‘Bàbá Wa Tí Ń Bẹ ní Ọ̀run.’ Ǹjẹ́ o lè ka gbogbo àdúrà yẹn?

Àwọn èèyàn ń gbọ́ Ìwáásù Jésù Lórí Òkè

Jésù tún ń kọ́ àwọn èèyàn yẹn ní bó ṣe yẹ kí wọ́n máa ṣe sáwọn ẹlòmíì. Ó sọ pé: ‘Ṣe fún àwọn ẹlòmíràn ohun tó o fẹ́ kí wọ́n ṣe fún ọ.’ Ṣé ìwọ náà ò fẹ́ káwọn ẹlòmíràn máa ṣe dáadáa sí ẹ? Nítorí náà, ohun tí Jésù ń wí ni pé, a ní láti máa ṣe dáadáa sáwọn ẹlòmíì. Nígbà tí gbogbo èèyàn bá wá ń ṣe báyìí nínú Párádísè lórí ilẹ̀ ayé, ǹjẹ́ o ò rí i pé nǹkan á dáa gan-an?

Mátíù orí 5 sí 7; 10:1-4.

Àwọn Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́