ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • sjj orin 44
  • Àdúrà Ẹni Tó Ní Ẹ̀dùn Ọkàn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àdúrà Ẹni Tó Ní Ẹ̀dùn Ọkàn
  • “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àdúrà Ẹni Rírẹlẹ̀
    Kọrin sí Jèhófà
  • Jọ̀wọ́ Gbọ́ Àdúrà Mi
    Kọrin sí Jèhófà
  • Jọ̀ọ́, Gbọ́ Àdúrà Mi
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jẹ́ Kí N Ní Ìgboyà
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
Àwọn Míì
“Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
sjj orin 44

ORIN 44

Àdúrà Ẹni Tó Ní Ẹ̀dùn Ọkàn

Bíi Ti Orí Ìwé

(Sáàmù 4:1)

  1. 1. Ẹ̀dùn ọkàn mi pọ̀, ọrùn wọ̀ mí,

    ayé sú mi.

    Jèhófà, jọ̀wọ́, “Gbọ́ àdúrà mi,”

    ràn mí lọ́wọ́.

    Àròkàn mú mi sọ̀rètí nù,

    mo rora mi pin.

    Ọlọ́run ìtùnú, jọ̀ọ́ fi

    ojúure hàn sí mi.

    (ÈGBÈ)

    Fún mi lókun, kí n má bọ́hùn,

    Tíyèméjì bá fẹ́ bò mí.

    Ràn mí lọ́wọ́; mo sá di ọ́.

    Ọlọ́run mi, fún mi lókun.

  2. 2. Bíbélì máa ń tù mí nínú

    tí mo bá rẹ̀wẹ̀sì.

    Ọ̀rọ̀ inú rẹ̀ tí mò ń kà

    máa ń mọ́kàn mi fúyẹ́.

    Jọ̀ọ́, jẹ́ kí n túbọ̀ gbẹ́kẹ̀ lé ọ,

    kí n sì nígbàgbọ́.

    Kí n mọ̀ pé o nífẹ̀ẹ́ mi gan-an

    ju bí mo ṣe rò lọ.

    (ÈGBÈ)

    Fún mi lókun, kí n má bọ́hùn,

    Tíyèméjì bá fẹ́ bò mí.

    Ràn mí lọ́wọ́; mo sá di ọ́.

    Ọlọ́run mi, fún mi lókun.

(Tún wo Sm. 42:6; 119:28; Róòmù 8:26; 2 Kọ́r. 4:16; 1 Jòh. 3:20.)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́