ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g16 No. 4 ojú ìwé 5
  • 2 Kíyè Sí Ohun Tó Ń Lọ Láyìíká Rẹ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • 2 Kíyè Sí Ohun Tó Ń Lọ Láyìíká Rẹ
  • Jí!—2016
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • 1 Má Tan Ara Rẹ
    Jí!—2016
  • Jẹ́ Kí Àwọn Àṣà Tó Ti Mọ́ Ọ Lára Ṣe Ọ́ Láǹfààní
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀
    Jí!—2016
  • Ǹjẹ́ Ó Ṣeé Ṣe Láti Jáwọ́ Nínú Àṣà Burúkú?
    Jí!—2004
Àwọn Míì
Jí!—2016
g16 No. 4 ojú ìwé 5
Aṣọ eré ìmárale, bàtà, ike omi, àti kọ̀ǹpútà kékeré tí wọ́n gbé kalẹ̀ lálẹ́

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ÀWỌN ÀṢÀ TÓ LÈ ṢE Ẹ́ LÁǸFÀÀNÍ

2 Kíyè Sí Ohun Tó Ń Lọ Láyìíká Rẹ

  • O pinnu pé wàá máa jẹun gidi síkùn, ṣùgbọ́n àwọn oúnjẹ pàrùpárù ṣì kún inú ilé rẹ.

  • O pinnu pé o ò ní fa sìgá mọ́, síbẹ̀ àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ṣì tún ń fi sìgá lọ̀ ẹ́.

  • O ti pinnu pé wàá ṣe eré ìmárale lónìí, àmọ́ ojú ń ro ẹ́ láti ṣẹ̀ṣẹ̀ máa wá aṣọ tó o máa wọ̀!

Ǹjẹ́ o rí ohun tó jọra nínú àwọn àpẹẹrẹ yìí? Ẹ̀rí ti fi hàn pé ohun tó wà ní àyíká wa àti àwọn tá à ń bá rìn ló máa ń pinnu bóyá a máa lè ní àṣà tó dáa, ká sì jáwọ́ nínú èyí tí kò dáa.

ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Afọgbọ́nhùwà ni ẹni tí ó ti rí ìyọnu àjálù, tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ara rẹ̀ pa mọ́, ṣùgbọ́n aláìní ìrírí gba ibẹ̀ kọjá, yóò sì jìyà àbájáde rẹ̀.”—Òwe 22:3.

Bíbélì gbà wá níyànjú pé ká máa ronú nípa àwọn ohun tó lè ṣẹlẹ̀. Tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀, àá lè yẹra fún àwọn nǹkan tí kò ní jẹ́ kí ọwọ́ wa tẹ àfojúsùn wa, àá sì lè máa ṣe ohun tó máa ràn wá lọ́wọ́. (2 Tímótì 2:22) Ní kúkúrú, ọlọ́gbọ́n ni wá tá a bá ń kíyè sí ohun tó n lọ láyìíká wa.

Yẹra fún nǹkan tó máa jẹ́ kó o ṣe ohun tí kò dáa, mú kí ṣíṣe ohun tó tọ́ rọrùn fún ẹ

OHUN TÓ O LÈ ṢE

  • Yẹra fún àwọn nǹkan tó máa jẹ́ kó o ṣe ohun tí kò dáa. Bí àpẹẹrẹ, tó o bá fẹ́ máa jẹ oúnjẹ tó ṣara lóore, rí i dájú pé o kò tọ́jú oúnjẹ pàrùpárù sílé. Ìyẹn ló máa jẹ́ kó o lè yẹra fún irú oúnjẹ bẹ́ẹ̀ lọ́jọ́ tó bá wù ẹ́ láti jẹ ẹ́.

  • Mú kí ṣíṣe ohun tó tọ́ rọrùn fún ẹ. Ká sọ pé o ti pinnu pé o máa ṣe eré ìmárale tílẹ̀ bá mọ́, ńṣe ni kó o kó àwọn aṣọ tó o máa lò sítòsí kó o tó lọ sùn. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, ó máa mú kó rọrùn fún ẹ láti ṣe ohun tó o fẹ́ ṣe láì lọ́ra.

  • Fara balẹ̀ yan àwọn tó o máa bá rìn. Kì í pẹ́ tá a fi máa ń mú ìwà àwọn ọ̀rẹ́ wa. (1 Kọ́ríńtì 15:33) Torí náà, dín wọléwọ̀de rẹ kù pẹ̀lú àwọn tó máa mú kó o ṣì tún máa hùwà tí o kò fẹ́, kó o sì yan àwọn tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ lọ́rẹ̀ẹ́.

ÀWỌN ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ MÍÌ

“Ẹni tí ó bá ń bá àwọn ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n.”​—Òwe 13:20.

“Àwọn ìwéwèé ẹni aláápọn máa ń yọrí sí àǹfààní.”​—Òwe 21:5.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́