-
Jẹ́nẹ́sísì 15:18-21Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Ní ọjọ́ yẹn, Jèhófà bá Ábúrámù dá májẹ̀mú+ kan pé: “Ọmọ* rẹ ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ yìí,+ láti odò Íjíbítì dé odò ńlá náà, ìyẹn odò Yúfírétì:+ 19 ilẹ̀ àwọn Kénì,+ àwọn ọmọ Kénásì, àwọn Kádímónì, 20 àwọn ọmọ Hétì,+ àwọn Pérísì,+ àwọn Réfáímù,+ 21 àwọn Ámórì, àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn Gẹ́gáṣì àti àwọn ará Jébúsì.”+
-
-
Ẹ́kísódù 23:23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Torí áńgẹ́lì mi yóò ṣáájú yín, yóò sì mú yín wá sọ́dọ̀ àwọn Ámórì, àwọn ọmọ Hétì, àwọn Pérísì, àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn Hífì àti àwọn ará Jébúsì, màá sì pa wọ́n run.+
-
-
Diutarónómì 7:1Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 “Tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ tí o fẹ́ wọ̀ tí o sì máa gbà,+ ó máa mú àwọn orílẹ̀-èdè tí èèyàn wọn pọ̀ kúrò níwájú rẹ:+ àwọn ọmọ Hétì, àwọn Gẹ́gáṣì, àwọn Ámórì,+ àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn Pérísì, àwọn Hífì àti àwọn ará Jébúsì,+ àwọn orílẹ̀-èdè méje tí èèyàn wọn pọ̀ tí wọ́n sì lágbára jù ọ́ lọ.+
-