ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 9:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  6 Torí a ti bí ọmọ kan fún wa,+

      A ti fún wa ní ọmọkùnrin kan;

      Àkóso* sì máa wà ní èjìká rẹ̀.+

      Orúkọ rẹ̀ á máa jẹ́ Àgbàyanu Agbani-nímọ̀ràn,+ Ọlọ́run Alágbára,+ Baba Ayérayé, Ọmọ Aládé Àlàáfíà.

       7 Àkóso* rẹ̀ á máa gbilẹ̀ títí lọ,

      Àlàáfíà kò sì ní lópin,+

      Lórí ìtẹ́ Dáfídì+ àti lórí ìjọba rẹ̀,

      Kó lè fìdí rẹ̀ múlẹ̀ gbọn-in,+ kó sì gbé e ró,

      Nípasẹ̀ ìdájọ́+ tí ó tọ́ àti òdodo,+

      Láti ìsinsìnyí lọ àti títí láé.

      Ìtara Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun máa ṣe èyí.

  • Àìsáyà 16:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  5 Ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ máa wá mú kí ìtẹ́ kan fìdí múlẹ̀ gbọn-in.

      Ẹni tó jókòó sórí rẹ̀ nínú àgọ́ Dáfídì máa jẹ́ olóòótọ́;+

      Ó máa dá ẹjọ́ bó ṣe tọ́, ó sì máa yára ṣe òdodo.”+

  • Jeremáyà 23:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 “Wò ó! Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Jèhófà wí, “tí màá gbé èéhù* kan tó jẹ́ olódodo dìde fún Dáfídì.+ Ọba kan máa jẹ,+ á sì fi ìjìnlẹ̀ òye hùwà, á dá ẹjọ́ bó ṣe tọ́, á sì ṣe òdodo ní ilẹ̀ náà.+

  • Ìsíkíẹ́lì 37:24, 25
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 “‘“Dáfídì ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ́ ọba wọn,+ gbogbo wọn á sì ní olùṣọ́ àgùntàn kan.+ Wọ́n á máa tẹ̀ lé àwọn ìdájọ́ mi, wọ́n á sì máa rí i pé àwọn ń pa àwọn àṣẹ mi mọ́.+ 25 Wọn yóò máa gbé lórí ilẹ̀ tí mo fún Jékọ́bù ìránṣẹ́ mi, ibi tí àwọn baba ńlá yín gbé,+ wọn yóò sì máa gbé lórí rẹ̀ títí láé,+ àwọn àti àwọn ọmọ* wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn;+ Dáfídì ìránṣẹ́ mi ni yóò sì jẹ́ ìjòyè* wọn títí láé.+

  • Sekaráyà 12:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 Ní ọjọ́ yẹn, Jèhófà yóò dáàbò bo àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù;+ ní ọjọ́ yẹn, ẹni tó bá kọsẹ̀* nínú wọn yóò dà bíi Dáfídì, ilé Dáfídì yóò sì dà bí Ọlọ́run, bí áńgẹ́lì Jèhófà tó ń lọ níwájú wọn.+

  • Lúùkù 1:31-33
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 Wò ó! o máa lóyún,* o sì máa bí ọmọkùnrin kan,+ kí o pe orúkọ rẹ̀ ní Jésù.+ 32 Ẹni yìí máa jẹ́ ẹni ńlá,+ wọ́n á máa pè é ní Ọmọ Ẹni Gíga Jù Lọ,+ Jèhófà* Ọlọ́run sì máa fún un ní ìtẹ́ Dáfídì bàbá rẹ̀,+ 33 ó máa jẹ Ọba lórí ilé Jékọ́bù títí láé, Ìjọba rẹ̀ ò sì ní lópin.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́