-
Àìsáyà 9:6, 7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
Orúkọ rẹ̀ á máa jẹ́ Àgbàyanu Agbani-nímọ̀ràn,+ Ọlọ́run Alágbára,+ Baba Ayérayé, Ọmọ Aládé Àlàáfíà.
7 Àkóso* rẹ̀ á máa gbilẹ̀ títí lọ,
Àlàáfíà kò sì ní lópin,+
Lórí ìtẹ́ Dáfídì+ àti lórí ìjọba rẹ̀,
Kó lè fìdí rẹ̀ múlẹ̀ gbọn-in,+ kó sì gbé e ró,
Nípasẹ̀ ìdájọ́+ tí ó tọ́ àti òdodo,+
Láti ìsinsìnyí lọ àti títí láé.
Ìtara Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun máa ṣe èyí.
-
-
Àìsáyà 16:5Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ máa wá mú kí ìtẹ́ kan fìdí múlẹ̀ gbọn-in.
-
-
Ìsíkíẹ́lì 37:24, 25Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
24 “‘“Dáfídì ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ́ ọba wọn,+ gbogbo wọn á sì ní olùṣọ́ àgùntàn kan.+ Wọ́n á máa tẹ̀ lé àwọn ìdájọ́ mi, wọ́n á sì máa rí i pé àwọn ń pa àwọn àṣẹ mi mọ́.+ 25 Wọn yóò máa gbé lórí ilẹ̀ tí mo fún Jékọ́bù ìránṣẹ́ mi, ibi tí àwọn baba ńlá yín gbé,+ wọn yóò sì máa gbé lórí rẹ̀ títí láé,+ àwọn àti àwọn ọmọ* wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn;+ Dáfídì ìránṣẹ́ mi ni yóò sì jẹ́ ìjòyè* wọn títí láé.+
-