ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Àìsáyà

      • Àwọn olórí Júdà kó àwọn èèyàn ṣìnà (1-15)

      • A dá àwọn ọmọbìnrin Síónì oníṣekúṣe lẹ́jọ́ (16-26)

Àìsáyà 3:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:26; Di 28:49, 51; Jer 37:21; Isk 4:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 56-57

Àìsáyà 3:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 13:9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 56-57

Àìsáyà 3:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 18:21
  • +Di 18:10, 12; Ais 8:19

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 56-57

Àìsáyà 3:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Àwọn tí èrò wọn ò dúró sójú kan.”

Àìsáyà 3:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 9:4, 5; Mik 3:2, 3
  • +Le 19:32

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 56-57

Àìsáyà 3:6

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 56-57

Àìsáyà 3:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Mi ò ní wò ọ́ sàn.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 56-57

Àìsáyà 3:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ní ojú ògo rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 33:1, 6; Isk 9:9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 57

Àìsáyà 3:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Ọkàn wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 18:20; Ais 1:10; Jud 7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 57

Àìsáyà 3:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Wọ́n máa jẹ èso iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Onw 8:12; Sef 2:3

Àìsáyà 3:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 5:31; Hab 1:4

Àìsáyà 3:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 1:23; Jer 5:26-28; Mik 2:1, 2; 6:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 57-58

Àìsáyà 3:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mik 3:2, 3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 57-58

Àìsáyà 3:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Tí wọ́n ń na ọrùn (ọ̀fun) síwájú.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 58-59

Àìsáyà 3:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 3:24

Àìsáyà 3:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 8:26

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/15/2003, ojú ìwé 28

Àìsáyà 3:19

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ohun ọ̀ṣọ́ tí wọ́n ń so mọ́ ẹ̀gbà ọrùn.”

Àìsáyà 3:20

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìborùn.”

  • *

    Ní Héb., “Àwọn ilé ọkàn.”

  • *

    Tàbí “àwọn karawun tó ń dún tí wọ́n fi ṣe ọ̀ṣọ́.”

Àìsáyà 3:23

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọ̀tẹ́lẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 38:8

Àìsáyà 3:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “aṣọ àpò ìdọ̀họ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹst 2:12
  • +Mik 1:16
  • +Ida 2:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 59

Àìsáyà 3:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ida 2:21

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 59-60

Àìsáyà 3:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ida 1:4
  • +Ida 2:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 59-60

Àwọn míì

Àìsá. 3:1Le 26:26; Di 28:49, 51; Jer 37:21; Isk 4:16
Àìsá. 3:2Isk 13:9
Àìsá. 3:3Ẹk 18:21
Àìsá. 3:3Di 18:10, 12; Ais 8:19
Àìsá. 3:5Jer 9:4, 5; Mik 3:2, 3
Àìsá. 3:5Le 19:32
Àìsá. 3:82Kr 33:1, 6; Isk 9:9
Àìsá. 3:9Jẹ 18:20; Ais 1:10; Jud 7
Àìsá. 3:10Onw 8:12; Sef 2:3
Àìsá. 3:12Jer 5:31; Hab 1:4
Àìsá. 3:14Ais 1:23; Jer 5:26-28; Mik 2:1, 2; 6:10
Àìsá. 3:15Mik 3:2, 3
Àìsá. 3:17Ais 3:24
Àìsá. 3:18Ond 8:26
Àìsá. 3:23Ẹk 38:8
Àìsá. 3:24Ẹst 2:12
Àìsá. 3:24Mik 1:16
Àìsá. 3:24Ida 2:10
Àìsá. 3:25Ida 2:21
Àìsá. 3:26Ida 1:4
Àìsá. 3:26Ida 2:10
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Àìsáyà 3:1-26

Àìsáyà

3 Wò ó! Olúwa tòótọ́, Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun,

Ó ń mú gbogbo ìtìlẹ́yìn àtàwọn ohun tí wọ́n nílò ní Jerúsálẹ́mù àti Júdà kúrò,

Gbogbo ìtìlẹ́yìn oúnjẹ àti omi,+

 2 Akíkanjú ọkùnrin àti jagunjagun,

Adájọ́ àti wòlíì,+ woṣẹ́woṣẹ́ àtàwọn àgbààgbà,

 3 Olórí àádọ́ta (50),+ èèyàn pàtàkì àti agbani-nímọ̀ràn,

Onídán tó gbówọ́ àti atujú tó gbóná.+

 4 Àwọn ọmọdékùnrin ni màá fi ṣe olórí wọn,

Àwọn aláìnípinnu* ló sì máa ṣàkóso wọn.

 5 Àwọn èèyàn náà máa fìyà jẹ ara wọn,

Kálukú máa fìyà jẹ ọmọnìkejì rẹ̀.+

Ọmọdékùnrin máa lu àgbà ọkùnrin,

Ẹni tí wọn ò fi bẹ́ẹ̀ kà sí sì máa fojú di ẹni táwọn èèyàn bọ̀wọ̀ fún.+

 6 Kálukú máa mú arákùnrin rẹ̀ nínú ilé bàbá rẹ̀, á sì sọ pé:

“O ní aṣọ àwọ̀lékè, wá ṣe olórí wa.

Jẹ́ kí àwókù ibi tí a ṣẹ́gun yìí wà níkàáwọ́ rẹ.”

 7 Àmọ́ ó máa kọ̀ jálẹ̀ ní ọjọ́ yẹn pé:

“Mi ò ní wẹ ọgbẹ́ rẹ;*

Mi ò ní oúnjẹ tàbí aṣọ nínú ilé mi.

Ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn èèyàn náà.”

 8 Torí Jerúsálẹ́mù ti kọsẹ̀,

Júdà sì ti ṣubú,

Torí wọ́n ta ko Jèhófà nínú ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn;

Wọ́n ya aláìgbọràn níwájú ògo rẹ̀.*+

 9 Ìrísí ojú wọn ta kò wọ́n,

Wọ́n sì ń kéde ẹ̀ṣẹ̀ wọn bíi ti Sódómù;+

Wọn ò fi bò rárá.

Wọ́n* gbé, torí wọ́n ń mú àjálù wá sórí ara wọn!

10 Sọ fún àwọn olódodo pé nǹkan máa lọ dáadáa fún wọn;

Wọ́n máa jèrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn.*+

11 Ẹni burúkú gbé!

Àjálù máa dé bá a,

Torí ohun tó fi ọwọ́ ara rẹ̀ ṣe ni wọ́n máa ṣe fún un!

12 Ní ti àwọn èèyàn mi, àwọn tó ń kó wọn ṣiṣẹ́ ń fìyà jẹ wọ́n,

Àwọn obìnrin sì ń jọba lé wọn lórí.

Ẹ̀yin èèyàn mi, àwọn olórí yín ń mú kí ẹ rìn gbéregbère,

Wọ́n sì ń da ọ̀nà rú mọ́ yín lójú.+

13 Jèhófà dúró sí àyè rẹ̀ láti fẹ̀sùn kàn wọ́n;

Ó dìde dúró láti ṣèdájọ́ àwọn èèyàn.

14 Jèhófà máa dá àwọn àgbààgbà àtàwọn olórí àwọn èèyàn rẹ̀ lẹ́jọ́.

“Ẹ ti dáná sun ọgbà àjàrà.

Ohun tí ẹ jí lọ́dọ̀ aláìní sì wà nínú àwọn ilé yín.+

15 Kí ló kì yín láyà tí ẹ fi ń tẹ àwọn èèyàn mi rẹ́,

Tí ẹ sì ń fi ojú àwọn aláìní gbolẹ̀?”+ ni Olúwa Ọba Aláṣẹ, Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

16 Jèhófà sọ pé: “Torí pé àwọn ọmọbìnrin Síónì ń gbéra ga,

Tí wọ́n ń gbé orí wọn sókè* bí wọ́n ṣe ń rìn,

Tí wọ́n ń sejú, tí wọ́n sì ń ṣakọ lọ,

Wọ́n ń mú kí ẹ̀gbà ẹsẹ̀ wọn máa dún woroworo,

17 Jèhófà tún máa fi èépá kọ lu àwọn ọmọbìnrin Síónì ní orí,

Jèhófà sì máa mú kí iwájú orí wọn pá.+

18 Ní ọjọ́ yẹn, Jèhófà ò ní mú kí àwọn ẹ̀gbà ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn rẹwà mọ́,

Àwọn aṣọ ìwérí àtàwọn ohun ọ̀ṣọ́ tó rí bí òṣùpá,+

19 Àwọn yẹtí,* àwọn ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,

20 Àwọn ìwérí, àwọn ẹ̀gbà ẹsẹ̀ àtàwọn ọ̀já ìgbàyà,*

Àwọn ìgò lọ́fínńdà* àtàwọn oògùn,*

21 Àwọn òrùka ọwọ́ àti òrùka imú,

22 Àwọn aṣọ oyè, àwọn aṣọ àwọ̀lékè, àwọn aṣọ ìlékè àtàwọn àpò,

23 Àwọn dígí ọwọ́+ àtàwọn aṣọ ọ̀gbọ̀,*

Àwọn láwàní àtàwọn ìbòjú.

24 Dípò òróró básámù,+ òórùn ohun tó jẹrà ló máa wà;

Dípò àmùrè, okùn;

Dípò irun tó rẹwà, orí pípá;+

Dípò aṣọ olówó ńlá, aṣọ ọ̀fọ̀;*+

Àpá tí wọ́n fi sàmì dípò ẹwà.

25 Wọ́n máa fi idà pa àwọn ọkùnrin rẹ,

Àwọn akíkanjú ọkùnrin rẹ sì máa kú sójú ogun.+

26 Àwọn ẹnu ọ̀nà rẹ̀ máa ṣọ̀fọ̀, wọ́n á sì kẹ́dùn,+

Ó sì máa jókòó sí ilẹ̀, ó máa di ahoro.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́