ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Sámúẹ́lì 17
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Sámúẹ́lì

      • Húṣáì sọ ìmọ̀ràn Áhítófẹ́lì di asán (1-14)

      • Wọ́n kìlọ̀ fún Dáfídì; ó bọ́ lọ́wọ́ Ábúsálómù (15-29)

        • Básíláì àti àwọn míì pèsè oúnjẹ (27-29)

2 Sámúẹ́lì 17:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ti rọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 16:14
  • +Sm 37:12; 41:9; 55:12, 13

2 Sámúẹ́lì 17:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 15:32; 16:16

2 Sámúẹ́lì 17:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 15:34

2 Sámúẹ́lì 17:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn wọn korò.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 16:18; 2Sa 15:18; 23:8, 18; 1Kr 11:26
  • +Owe 17:12
  • +1Sa 17:50; 18:7; 19:8; 2Sa 10:18

2 Sámúẹ́lì 17:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kòtò; àfonífojì tóóró.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 22:1; 23:19

2 Sámúẹ́lì 17:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 49:9; 2Sa 1:23; Ais 31:4
  • +1Sa 18:5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    7/15/1996, ojú ìwé 32

2 Sámúẹ́lì 17:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 20:1
  • +1Ọb 4:20

2 Sámúẹ́lì 17:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pàṣẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Owe 21:1
  • +2Sa 15:31, 34; 16:23; Owe 19:21; 21:30
  • +Di 2:30; 2Kr 25:20

2 Sámúẹ́lì 17:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:17; 15:35

2 Sámúẹ́lì 17:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, ibi tó ṣeé fẹsẹ̀ là kọjá lára odò.

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní.”

  • *

    Ní Héb., “gbé mì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 35:24, 25

2 Sámúẹ́lì 17:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 1:42
  • +2Sa 15:27, 36; 18:19
  • +Joṣ 15:7, 12; 18:16, 20; 1Ọb 1:9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    “Ilẹ̀ Dáradára,” ojú ìwé 20-21

2 Sámúẹ́lì 17:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 16:5; 19:16

2 Sámúẹ́lì 17:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 1:19; Joṣ 2:3-5; 1Sa 19:12, 14; 21:2

2 Sámúẹ́lì 17:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 17:1, 2

2 Sámúẹ́lì 17:23

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì.”

  • *

    Tàbí “fún ara rẹ̀ lọ́rùn pa.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 15:20, 51; 2Sa 15:12
  • +2Ọb 20:1
  • +1Sa 31:4; 1Ọb 16:18; Sm 5:10; 55:23; Mt 27:3, 5; Iṣe 1:18

2 Sámúẹ́lì 17:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 32:1, 2; Joṣ 13:24, 26

2 Sámúẹ́lì 17:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 19:13; 20:4, 10
  • +2Sa 8:16
  • +1Kr 2:16, 17

2 Sámúẹ́lì 17:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 32:1; Di 3:15

2 Sámúẹ́lì 17:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 3:11; Joṣ 13:24, 25; 2Sa 12:26, 29
  • +2Sa 9:3-5
  • +2Sa 19:31, 32; 1Ọb 2:7

2 Sámúẹ́lì 17:28

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “wíìtì.”

2 Sámúẹ́lì 17:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ìkẹ̀tẹ́ wàrà màlúù.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Owe 11:25
  • +1Sa 25:18; 2Sa 16:2

Àwọn míì

2 Sám. 17:22Sa 16:14
2 Sám. 17:2Sm 37:12; 41:9; 55:12, 13
2 Sám. 17:52Sa 15:32; 16:16
2 Sám. 17:72Sa 15:34
2 Sám. 17:81Sa 16:18; 2Sa 15:18; 23:8, 18; 1Kr 11:26
2 Sám. 17:8Owe 17:12
2 Sám. 17:81Sa 17:50; 18:7; 19:8; 2Sa 10:18
2 Sám. 17:91Sa 22:1; 23:19
2 Sám. 17:10Jẹ 49:9; 2Sa 1:23; Ais 31:4
2 Sám. 17:101Sa 18:5
2 Sám. 17:11Ond 20:1
2 Sám. 17:111Ọb 4:20
2 Sám. 17:14Owe 21:1
2 Sám. 17:142Sa 15:31, 34; 16:23; Owe 19:21; 21:30
2 Sám. 17:14Di 2:30; 2Kr 25:20
2 Sám. 17:152Sa 8:17; 15:35
2 Sám. 17:16Sm 35:24, 25
2 Sám. 17:171Ọb 1:42
2 Sám. 17:172Sa 15:27, 36; 18:19
2 Sám. 17:17Joṣ 15:7, 12; 18:16, 20; 1Ọb 1:9
2 Sám. 17:182Sa 16:5; 19:16
2 Sám. 17:20Ẹk 1:19; Joṣ 2:3-5; 1Sa 19:12, 14; 21:2
2 Sám. 17:212Sa 17:1, 2
2 Sám. 17:23Joṣ 15:20, 51; 2Sa 15:12
2 Sám. 17:232Ọb 20:1
2 Sám. 17:231Sa 31:4; 1Ọb 16:18; Sm 5:10; 55:23; Mt 27:3, 5; Iṣe 1:18
2 Sám. 17:24Jẹ 32:1, 2; Joṣ 13:24, 26
2 Sám. 17:252Sa 19:13; 20:4, 10
2 Sám. 17:252Sa 8:16
2 Sám. 17:251Kr 2:16, 17
2 Sám. 17:26Nọ 32:1; Di 3:15
2 Sám. 17:27Di 3:11; Joṣ 13:24, 25; 2Sa 12:26, 29
2 Sám. 17:272Sa 9:3-5
2 Sám. 17:272Sa 19:31, 32; 1Ọb 2:7
2 Sám. 17:29Owe 11:25
2 Sám. 17:291Sa 25:18; 2Sa 16:2
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Sámúẹ́lì 17:1-29

Sámúẹ́lì Kejì

17 Nígbà náà, Áhítófẹ́lì sọ fún Ábúsálómù pé: “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí n yan ẹgbẹ̀rún méjìlá (12,000) ọkùnrin, kí a sì gbéra láti lépa Dáfídì lálẹ́ òní. 2 Màá yọ sí i nígbà tó bá ti rẹ̀ ẹ́, tí kò sì ní agbára kankan,*+ màá mú kí ẹ̀rù bà á; gbogbo àwọn tó wà pẹ̀lú rẹ̀ á sá lọ, màá sì pa ọba nìkan.+ 3 Màá wá kó gbogbo àwọn èèyàn náà pa dà sọ́dọ̀ rẹ. Ohun tí ó bá ṣẹlẹ̀ sí ọkùnrin tí ò ń lépa yìí ló máa sọ bóyá àwọn èèyàn náà máa pa dà sọ́dọ̀ rẹ. Ìgbà náà ni gbogbo àwọn èèyàn náà yóò wà ní àlàáfíà.” 4 Àbá náà dára lójú Ábúsálómù àti gbogbo àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì.

5 Síbẹ̀, Ábúsálómù sọ pé: “Jọ̀wọ́, pe Húṣáì+ ará Áríkì pẹ̀lú, kí a lè gbọ́ ohun tó máa sọ.” 6 Torí náà, Húṣáì wọlé wá sọ́dọ̀ Ábúsálómù. Ni Ábúsálómù bá sọ fún un pé: “Ìmọ̀ràn tí Áhítófẹ́lì mú wá rèé. Ṣé kí a ṣe ohun tó dámọ̀ràn? Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, sọ ohun tí a máa ṣe.” 7 Ni Húṣáì bá sọ fún Ábúsálómù pé: “Ohun tí Áhítófẹ́lì dámọ̀ràn kò dára lọ́tẹ̀ yìí!”+

8 Húṣáì ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ, ó ní: “Ìwọ náà mọ̀ dáadáa pé akíkanjú ni bàbá rẹ àti àwọn ọkùnrin rẹ̀,+ kò sí ohun tí wọn ò lè ṣe,* wọ́n dà bíi bíárì tí àwọn ọmọ rẹ̀ sọ nù ní pápá.+ Yàtọ̀ síyẹn, jagunjagun ni bàbá rẹ,+ kò ní sùn mọ́jú lọ́dọ̀ àwọn èèyàn náà. 9 Lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí, inú ihò àpáta* tàbí àwọn ibòmíì ló máa fara pa mọ́ sí;+ tó bá jẹ́ pé òun ló kọ́kọ́ gbéjà kò wá, àwọn tó bá gbọ́ á sọ pé, ‘Wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn tó ń tẹ̀ lé Ábúsálómù!’ 10 Kódà ẹ̀rù á ba ọkùnrin tó láyà bíi kìnnìún,+ ọkàn rẹ̀ á sì domi, torí gbogbo Ísírẹ́lì ló mọ̀ pé akíkanjú ni bàbá rẹ+ àti pé àwọn ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní ìgboyà. 11 Ìmọ̀ràn mi ni pé: Jẹ́ kí a kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ sọ́dọ̀ rẹ, láti Dánì títí dé Bíá-ṣébà,+ kí wọ́n pọ̀ bí iyanrìn etíkun,+ kí o sì kó wọn lọ láti jà. 12 Ibikíbi tí a bá ti rí i la ti máa bá a jà, a ó sì ya bò ó bí ìrì ṣe máa ń sẹ̀ sórí ilẹ̀; ẹyọ kan lára wọn ò ní ṣẹ́ kù, àtòun àti àwọn ọkùnrin tó wà lọ́dọ̀ rẹ̀. 13 Tí ó bá sá sínú ìlú kan, àwa àti gbogbo Ísírẹ́lì á yọ okùn ti ìlú náà, a ó sì wọ́ ọ lọ sínú òkun, tí ò fi ní ku ẹyọ òkúta kan níbẹ̀.”

14 Nígbà náà, Ábúsálómù àti gbogbo ọkùnrin Ísírẹ́lì sọ pé: “Ìmọ̀ràn Húṣáì ará Áríkì dára ju+ ìmọ̀ràn Áhítófẹ́lì!” Nítorí Jèhófà ti pinnu* láti sọ ìmọ̀ràn rere Áhítófẹ́lì+ di asán, kí Jèhófà lè mú àjálù bá Ábúsálómù.+

15 Lẹ́yìn náà, Húṣáì sọ fún àlùfáà Sádókù àti Ábíátárì+ pé: “Ohun tí Áhítófẹ́lì dámọ̀ràn fún Ábúsálómù àti àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì nìyí, ohun tí mo sì dámọ̀ràn nìyí. 16 Ní báyìí, ẹ ránṣẹ́ sí Dáfídì kíákíá, kí ẹ sì kìlọ̀ fún un pé: ‘Má ṣe dúró ní ibi pẹ́ṣẹ́pẹ́ṣẹ́* odò* aginjù lálẹ́ òní o, ńṣe ni kí o sọdá, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀ ọba àti gbogbo àwọn èèyàn tó wà pẹ̀lú rẹ̀ ni a ó pa rẹ́.’”*+

17 Jónátánì+ àti Áhímáásì+ ń gbé ní Ẹ́ń-rógélì;+ ìránṣẹ́bìnrin kan lọ sọ ohun tó ṣẹlẹ̀ fún wọn, àwọn náà sì lọ sọ fún Ọba Dáfídì, nítorí ẹnikẹ́ni ò gbọ́dọ̀ rí wọn pé wọ́n wọnú ìlú. 18 Àmọ́, ọ̀dọ́kùnrin kan rí wọn, ó sì lọ sọ fún Ábúsálómù. Torí náà, àwọn méjèèjì lọ ní kíá, wọ́n sì dé ilé ọkùnrin kan ní Báhúrímù+ tí ó ní kànga ní àgbàlá rẹ̀. Wọ́n sọ̀ kalẹ̀ sínú rẹ̀, 19 ìyàwó ọkùnrin náà da nǹkan bo orí kànga náà, ó sì da ọkà tí wọ́n ti pa sórí rẹ̀, kò sì sẹ́ni tó mọ ohun tó ṣẹlẹ̀. 20 Àwọn ìránṣẹ́ Ábúsálómù wá sọ́dọ̀ obìnrin náà ní ilé rẹ̀, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: “Ibo ni Áhímáásì àti Jónátánì wà?” Obìnrin náà dá wọn lóhùn pé: “Wọ́n gba ibí lọ sọ́nà odò.”+ Ni àwọn ọkùnrin náà bá ń wá wọn kiri, àmọ́ wọn ò rí wọn, torí náà wọ́n pa dà sí Jerúsálẹ́mù.

21 Lẹ́yìn tí àwọn ọkùnrin náà ti lọ, wọ́n jáde nínú kànga náà, wọ́n sì lọ sọ fún Ọba Dáfídì. Wọ́n sọ fún un pé: “Ẹ gbéra, kí ẹ sì sọdá odò kíákíá, torí ohun tí Áhítófẹ́lì ti dámọ̀ràn láti ṣe sí yín nìyí.”+ 22 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, Dáfídì àti gbogbo àwọn tó wà pẹ̀lú rẹ̀ gbéra, wọ́n sì sọdá Jọ́dánì. Nígbà tí ilẹ̀ máa fi mọ́, kò sẹ́ni tó ṣẹ́ kù tí kò tíì sọdá Jọ́dánì.

23 Nígbà tí Áhítófẹ́lì rí i pé wọn ò tẹ̀ lé ìmọ̀ràn òun, ó de ohun tí wọ́n fi ń jókòó mọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,* ó sì lọ sí ilé rẹ̀ ní ìlú rẹ̀.+ Lẹ́yìn tó ti sọ ohun tí agbo ilé rẹ̀+ máa ṣe, ó pokùn so.*+ Torí náà, ó kú, wọ́n sì sin ín sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba ńlá rẹ̀ sí.

24 Ní àkókò yẹn, Dáfídì lọ sí Máhánáímù,+ Ábúsálómù sì sọdá Jọ́dánì pẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì. 25 Ábúsálómù fi Ámásà+ sí ipò Jóábù+ láti máa darí àwọn ọmọ ogun; Ámásà jẹ́ ọmọ ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ítírà, ọmọ Ísírẹ́lì ni Ítírà, òun ló ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú Ábígẹ́lì+ ọmọ Náháṣì, arábìnrin Seruáyà, ìyá Jóábù. 26 Gbogbo Ísírẹ́lì àti Ábúsálómù pàgọ́ sí ilẹ̀ Gílíádì.+

27 Gbàrà tí Dáfídì dé Máhánáímù, Ṣóbì ọmọkùnrin Náháṣì láti Rábà+ ti àwọn ọmọ Ámónì àti Mákírù+ ọmọkùnrin Ámíélì láti Lo-débà pẹ̀lú Básíláì+ ọmọ Gílíádì láti Rógélímù 28 kó ibùsùn wá, wọ́n tún kó bàsíà, ìkòkò, àlìkámà,* ọkà bálì, ìyẹ̀fun, àyangbẹ ọkà, ẹ̀wà pàkálà, ẹ̀wà lẹ́ńtìlì àti ẹ̀gbẹ ọkà wá, 29 wọ́n sì kó oyin, bọ́tà, àgùntàn àti wàrà wá.* Wọ́n kó gbogbo nǹkan yìí wá fún Dáfídì àti àwọn èèyàn tó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti jẹ,+ torí wọ́n sọ pé: “Ebi ń pa àwọn èèyàn náà, ó ti rẹ̀ wọ́n, òùngbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́