ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Àwọn Ọba

      • Jèhórámù di ọba Ísírẹ́lì (1-3)

      • Móábù ṣọ̀tẹ̀ sí Ísírẹ́lì (4-25)

      • Wọ́n ṣẹ́gun Móábù (26, 27)

2 Àwọn Ọba 3:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 1:17

2 Àwọn Ọba 3:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 16:30-33

2 Àwọn Ọba 3:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:28-30

2 Àwọn Ọba 3:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “owó òde.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1992, ojú ìwé 24

2 Àwọn Ọba 3:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 22:37
  • +2Sa 8:2

2 Àwọn Ọba 3:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 19:2
  • +1Ọb 22:3, 4

2 Àwọn Ọba 3:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:14

2 Àwọn Ọba 3:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tó jẹ́ ìránṣẹ́ Èlíjà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 22:7
  • +1Ọb 19:16; 2Ọb 2:15
  • +1Ọb 19:19, 21

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    8/15/2013, ojú ìwé 28-29

    11/1/1997, ojú ìwé 30-31

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 98

2 Àwọn Ọba 3:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Kí ló wà láàárín èmi àti ìwọ?”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 2:30; Isk 14:3
  • +Ond 10:14; 1Ọb 18:19; 22:6

2 Àwọn Ọba 3:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ẹni tí mo dúró níwájú rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 17:3, 4; 19:3, 4
  • +Owe 15:29

2 Àwọn Ọba 3:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “olórin kan.”

  • *

    Ní Héb., “ọwọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 10:5; 1Kr 25:1
  • +1Ọb 18:46; Isk 1:3; Iṣe 11:21

2 Àwọn Ọba 3:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 107:35

2 Àwọn Ọba 3:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 32:17; Mk 10:27
  • +Di 28:7

2 Àwọn Ọba 3:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 3:5
  • +2Ọb 3:25

2 Àwọn Ọba 3:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 29:39, 40

2 Àwọn Ọba 3:21

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tó ń de àmùrè.”

2 Àwọn Ọba 3:22

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    8/1/2005, ojú ìwé 10

2 Àwọn Ọba 3:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 15:9, 10

2 Àwọn Ọba 3:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:7

2 Àwọn Ọba 3:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 26:15; 2Kr 32:4
  • +2Ọb 3:19
  • +Ais 16:7

2 Àwọn Ọba 3:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 3:9

2 Àwọn Ọba 3:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 12:31; 2Kr 28:1, 3; Sm 106:37, 38

Àwọn míì

2 Ọba 3:12Ọb 1:17
2 Ọba 3:21Ọb 16:30-33
2 Ọba 3:31Ọb 12:28-30
2 Ọba 3:51Ọb 22:37
2 Ọba 3:52Sa 8:2
2 Ọba 3:72Kr 19:2
2 Ọba 3:71Ọb 22:3, 4
2 Ọba 3:92Sa 8:14
2 Ọba 3:111Ọb 22:7
2 Ọba 3:111Ọb 19:16; 2Ọb 2:15
2 Ọba 3:111Ọb 19:19, 21
2 Ọba 3:131Sa 2:30; Isk 14:3
2 Ọba 3:13Ond 10:14; 1Ọb 18:19; 22:6
2 Ọba 3:142Kr 17:3, 4; 19:3, 4
2 Ọba 3:14Owe 15:29
2 Ọba 3:151Sa 10:5; 1Kr 25:1
2 Ọba 3:151Ọb 18:46; Isk 1:3; Iṣe 11:21
2 Ọba 3:17Sm 107:35
2 Ọba 3:18Jer 32:17; Mk 10:27
2 Ọba 3:18Di 28:7
2 Ọba 3:19Di 3:5
2 Ọba 3:192Ọb 3:25
2 Ọba 3:20Ẹk 29:39, 40
2 Ọba 3:23Ẹk 15:9, 10
2 Ọba 3:24Le 26:7
2 Ọba 3:25Jẹ 26:15; 2Kr 32:4
2 Ọba 3:252Ọb 3:19
2 Ọba 3:25Ais 16:7
2 Ọba 3:262Ọb 3:9
2 Ọba 3:27Di 12:31; 2Kr 28:1, 3; Sm 106:37, 38
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Àwọn Ọba 3:1-27

Àwọn Ọba Kejì

3 Jèhórámù+ ọmọ Áhábù di ọba lórí Ísírẹ́lì ní Samáríà ní ọdún kejìdínlógún Jèhóṣáfátì ọba Júdà, ọdún méjìlá (12) ló sì fi ṣàkóso. 2 Ó ń ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà, àmọ́ kò ṣe tó ohun tí bàbá àti ìyá rẹ̀ ṣe, nítorí ó mú ọwọ̀n òrìṣà Báálì tí bàbá rẹ̀ ṣe kúrò.+ 3 Síbẹ̀, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí Jèróbóámù ọmọ Nébátì mú kí Ísírẹ́lì dá ni òun náà ń dá.+ Kò jáwọ́ nínú wọn.

4 Nígbà náà, Méṣà ọba Móábù máa ń sin àgùntàn, ó sì máa ń fi ọ̀kẹ́ márùn-ún (100,000) ọ̀dọ́ àgùntàn àti ọ̀kẹ́ márùn-ún (100,000) akọ àgùntàn tí a kò rẹ́ irun wọn san ìṣákọ́lẹ̀* fún ọba Ísírẹ́lì. 5 Kété lẹ́yìn ikú Áhábù,+ ọba Móábù ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Ísírẹ́lì.+ 6 Nítorí náà, Ọba Jèhórámù jáde ní Samáríà lákòókò yẹn, ó sì pe gbogbo Ísírẹ́lì jọ. 7 Ó tún ránṣẹ́ sí Jèhóṣáfátì ọba Júdà pé: “Ọba Móábù ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé wàá tẹ̀ lé mi, ká lọ bá Móábù jà?” Ó dáhùn pé: “Màá tẹ̀ lé ọ.+ Ìkan náà ni èmi àti ìwọ. Ìkan náà ni àwọn èèyàn mi àti àwọn èèyàn rẹ. Ìkan náà sì ni àwọn ẹṣin mi àti àwọn ẹṣin rẹ.”+ 8 Ó wá béèrè pé: “Ọ̀nà wo ni ká gbà lọ?” Ó dáhùn pé: “Ọ̀nà aginjù Édómù.”

9 Ọba Ísírẹ́lì bá gbéra pẹ̀lú ọba Júdà àti ọba Édómù.+ Lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ọjọ́ méje rìn yí ká, kò sí omi tí àwọn tó wà ní ibùdó àti àwọn ẹran ọ̀sìn tó wà pẹ̀lú wọn máa mu. 10 Ọba Ísírẹ́lì wá sọ pé: “Ó mà ṣe o! Jèhófà pe àwọn ọba mẹ́ta yìí kó lè fi wọ́n lé Móábù lọ́wọ́!” 11 Ni Jèhóṣáfátì bá sọ pé: “Ṣé kò sí wòlíì Jèhófà níbí tó lè bá wa wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà ni?”+ Torí náà, ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Ísírẹ́lì dáhùn pé: “Èlíṣà+ ọmọ Ṣáfátì, ẹni tó máa ń bu omi sí ọwọ́ Èlíjà*+ wà níbí.” 12 Lẹ́yìn náà, Jèhóṣáfátì sọ pé: “Ọ̀rọ̀ Jèhófà wà lẹ́nu rẹ̀.” Torí náà, ọba Ísírẹ́lì àti Jèhóṣáfátì àti ọba Édómù lọ bá a.

13 Èlíṣà sọ fún ọba Ísírẹ́lì pé: “Kí ló pa èmi àti ìwọ pọ̀?*+ Lọ bá àwọn wòlíì bàbá rẹ àti àwọn wòlíì ìyá rẹ.”+ Àmọ́ ọba Ísírẹ́lì sọ fún un pé: “Rárá, torí Jèhófà ló pe àwọn ọba mẹ́ta yìí kó lè fi wọ́n lé Móábù lọ́wọ́.” 14 Èlíṣà fèsì pé: “Bí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, ẹni tí mò ń sìn* ti wà láàyè, bí kò bá jẹ́ ti Jèhóṣáfátì+ ọba Júdà tí mo rò, mi ò tiẹ̀ ní wojú ẹ tàbí kí n fetí sí ọ.+ 15 Ní báyìí, ẹ bá mi pe ẹnì kan tó ń ta háàpù*+ wá.” Bí ẹni tó ń ta háàpù náà ṣe bẹ̀rẹ̀ sí í ta á, ẹ̀mí* Jèhófà bà lé e.+ 16 Ó sì sọ pé: “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: ‘Ẹ gbẹ́ àwọn kòtò sí àfonífojì yìí, 17 nítorí ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Ẹ kò ní rí ìjì, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rí òjò; síbẹ̀, omi máa kún àfonífojì yìí,+ ẹ ó sì mu látinú rẹ̀, ẹ̀yin àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín pẹ̀lú àwọn ẹran míì tí ẹ ní.”’ 18 Àmọ́ kékeré nìyẹn lójú Jèhófà,+ torí pé ó máa fi Móábù lé yín lọ́wọ́.+ 19 Kí ẹ pa gbogbo ìlú olódi run+ àti gbogbo ìlú tó dára jù lọ, gbogbo igi tó dára ni kí ẹ gé lulẹ̀, gbogbo orísun omi ni kí ẹ dí pa, gbogbo ilẹ̀ tó dára sì ni kí ẹ fi òkúta bà jẹ́.”+

20 Nígbà tó di àárọ̀, ní àsìkò tí wọ́n máa ń fi ọrẹ ọkà òwúrọ̀ rúbọ,+ ṣàdédé ni omi ń ṣàn bọ̀ láti apá Édómù, omi sì kún gbogbo ilẹ̀ náà.

21 Gbogbo àwọn ọmọ Móábù gbọ́ pé àwọn ọba náà ti wá láti bá wọn jà, torí náà, wọ́n pe gbogbo àwọn èèyàn tó lè lo nǹkan ìjà* jọ, wọ́n sì to ara wọn sójú ààlà. 22 Nígbà tí wọ́n dìde ní àárọ̀ kùtù, oòrùn ń ràn sórí omi náà, àmọ́ lójú àwọn ọmọ Móábù, ní òdìkejì, ńṣe ni omi náà pupa bí ẹ̀jẹ̀. 23 Wọ́n sọ pé: “Ẹ wo ẹ̀jẹ̀! Ó dájú pé àwọn ọba náà ti fi idà ṣá ara wọn pa. Torí náà, lọ kó ẹrù ogun,+ ìwọ Móábù!” 24 Nígbà tí wọ́n wọ ibùdó Ísírẹ́lì, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dìde, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àwọn ọmọ Móábù, tí wọ́n fi sá kúrò níwájú wọn.+ Wọ́n wọ inú Móábù, wọ́n sì ń pa àwọn ọmọ Móábù bí wọ́n ṣe ń lọ. 25 Wọ́n wó ìlú náà palẹ̀, àwọn ọkùnrin náà lọ́kọ̀ọ̀kan sì ju òkúta sórí gbogbo ilẹ̀ tó dára, títí òkúta fi kún gbogbo ilẹ̀ náà; wọ́n dí gbogbo orísun omi pa,+ wọ́n sì gé gbogbo igi tó dára lulẹ̀.+ Níkẹyìn, àwọn ògiri olókùúta Kiri-hárésétì+ nìkan ló ṣẹ́ kù ní ìdúró, àwọn tó ń ta kànnàkànnà yí i ká, wọ́n sì wó o lulẹ̀.

26 Nígbà tí ọba Móábù rí i pé apá òun ò ká ogun náà mọ́, ó kó ọgọ́rùn-ún méje (700) ọkùnrin tó ń lo idà jọ, kí wọ́n lè kọjá sọ́dọ̀ ọba Édómù;+ àmọ́ wọn ò lè kọjá. 27 Torí náà, ó mú ọmọ rẹ̀ àkọ́bí tó máa jọba ní ipò rẹ̀, ó sì fi rú ẹbọ sísun+ lórí ògiri. Wọ́n bínú sí Ísírẹ́lì gan-an, torí náà, àwọn èèyàn Ísírẹ́lì pa dà lẹ́yìn ọba Móábù, wọ́n sì pa dà sí ilẹ̀ wọn.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́