ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jóṣúà 20
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jóṣúà

      • Àwọn ìlú ààbò (1-9)

Jóṣúà 20:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 21:12, 13; Nọ 35:14, 15; Di 4:41

Jóṣúà 20:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pa ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 9:6; Ẹk 21:23; Nọ 35:26, 27

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    11/2017, ojú ìwé 11

Jóṣúà 20:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 19:3
  • +Owe 31:23

Jóṣúà 20:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kò mọ̀ọ́mọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 35:22-24; Di 19:4-6

Jóṣúà 20:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 35:12, 24
  • +Nọ 35:25
  • +Nọ 35:28

Jóṣúà 20:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wọ́n ka Kédéṣì ní Gálílì sí mímọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:32
  • +Jẹ 33:18; Joṣ 21:20, 21
  • +Joṣ 14:15; 21:13

Jóṣúà 20:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “òkè tí orí rẹ̀ rí pẹrẹsẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:8, 36; 1Kr 6:77, 78
  • +Joṣ 21:8, 38; 1Kr 6:77, 80
  • +Joṣ 21:27; 1Kr 6:71
  • +Di 4:41-43

Jóṣúà 20:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pa ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 35:11, 15
  • +Nọ 35:12, 24; Di 21:5

Àwọn míì

Jóṣ. 20:2Ẹk 21:12, 13; Nọ 35:14, 15; Di 4:41
Jóṣ. 20:3Jẹ 9:6; Ẹk 21:23; Nọ 35:26, 27
Jóṣ. 20:4Di 19:3
Jóṣ. 20:4Owe 31:23
Jóṣ. 20:5Nọ 35:22-24; Di 19:4-6
Jóṣ. 20:6Nọ 35:12, 24
Jóṣ. 20:6Nọ 35:25
Jóṣ. 20:6Nọ 35:28
Jóṣ. 20:7Joṣ 21:32
Jóṣ. 20:7Jẹ 33:18; Joṣ 21:20, 21
Jóṣ. 20:7Joṣ 14:15; 21:13
Jóṣ. 20:8Joṣ 21:8, 36; 1Kr 6:77, 78
Jóṣ. 20:8Joṣ 21:8, 38; 1Kr 6:77, 80
Jóṣ. 20:8Joṣ 21:27; 1Kr 6:71
Jóṣ. 20:8Di 4:41-43
Jóṣ. 20:9Nọ 35:11, 15
Jóṣ. 20:9Nọ 35:12, 24; Di 21:5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jóṣúà 20:1-9

Jóṣúà

20 Jèhófà wá sọ fún Jóṣúà pé: 2 “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Ẹ yan àwọn ìlú ààbò fún ara yín,+ èyí tí mo ní kí Mósè sọ fún yín nípa rẹ̀, 3 kí ẹni tí kò bá mọ̀ọ́mọ̀ pààyàn tàbí tó ṣèèṣì pa èèyàn* lè sá lọ síbẹ̀. Àwọn ìlú náà á sì jẹ́ ìlú ààbò fún yín lọ́wọ́ ẹni tó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀.+ 4 Kí ẹni náà sá lọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú yìí,+ kó dúró sí ẹnubodè ìlú náà,+ kó sì ro ẹjọ́ rẹ̀ ní etí àwọn àgbààgbà ìlú náà. Kí wọ́n wá gbà á sínú ìlú náà, kí wọ́n fún un ní ibì kan, kó sì máa bá wọn gbé. 5 Tí ẹni tó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lé e, kí wọ́n má fi apààyàn náà lé e lọ́wọ́, torí ṣe ló ṣèèṣì* pa ẹnì kejì rẹ̀, kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀.+ 6 Kó máa gbé ìlú náà, títí dìgbà tí wọ́n máa gbọ́ ẹjọ́ rẹ̀ níwájú àpéjọ,+ kó sì wà níbẹ̀ títí àlùfáà àgbà tí wọ́n yàn sípò nígbà yẹn fi máa kú.+ Lẹ́yìn náà, apààyàn náà lè pa dà sí ìlú tó ti sá kúrò, ó sì lè wọ ìlú rẹ̀ àti ilé rẹ̀.’”+

7 Torí náà, wọ́n ya Kédéṣì+ ní Gálílì sọ́tọ̀* ní agbègbè olókè Náfútálì, Ṣékémù+ ní agbègbè olókè Éfúrémù àti Kiriati-ábà,+ ìyẹn Hébúrónì, ní agbègbè olókè Júdà. 8 Ní agbègbè Jọ́dánì, lápá ìlà oòrùn Jẹ́ríkò, wọ́n yan Bésérì+ ní aginjù tó wà lórí ilẹ̀ tó tẹ́jú* látinú ilẹ̀ ẹ̀yà Rúbẹ́nì, Rámótì+ ní Gílíádì látinú ilẹ̀ ẹ̀yà Gádì àti Gólánì+ ní Báṣánì látinú ilẹ̀ ẹ̀yà Mánásè.+

9 Àwọn ìlú yìí ni wọ́n yàn fún gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì àtàwọn àjèjì tó ń gbé láàárín wọn, kí ẹnikẹ́ni tó bá ṣèèṣì pa èèyàn* lè sá lọ síbẹ̀,+ kí ẹni tó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má bàa pa á kí wọ́n tó gbọ́ ẹjọ́ rẹ̀ níwájú àpéjọ náà.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́