ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 19
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jeremáyà

      • Ọlọ́run sọ pé kí Jeremáyà fọ́ ṣágo amọ̀ (1-15)

        • Wọ́n fi ọmọ rúbọ sí Báálì (5)

Jeremáyà 19:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, ohun tí a fi amọ̀ ṣe tó dà bí ìgò ńlá.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 18:2

Jeremáyà 19:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 15:8, 12; 2Kr 28:1, 3; Jer 7:31

Jeremáyà 19:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 22:16, 17; Ais 65:11
  • +2Kr 33:1, 4
  • +2Ọb 21:16; Ais 59:7; Jer 2:34; Ida 4:13; Mt 23:34, 35

Jeremáyà 19:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí mi ò ronú nípa rẹ̀ rí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 28:1, 3; 33:1, 6; Ais 57:5
  • +Le 18:21; Jer 7:31; 32:35

Jeremáyà 19:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 7:32

Jeremáyà 19:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:25, 26; Sm 79:2; Jer 7:33; 16:4

Jeremáyà 19:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 9:8; Jer 18:16; Ida 2:15

Jeremáyà 19:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:29; Di 28:53; Ida 2:20; 4:10; Isk 5:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 154-155

Jeremáyà 19:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 7:32

Jeremáyà 19:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 79:1
  • +Jer 8:1, 2; Sef 1:4, 5
  • +Jer 7:18; 32:29

Jeremáyà 19:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “mú ọrùn wọn le.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 9:17, 29; Sek 7:12

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 159

Àwọn míì

Jer. 19:1Jer 18:2
Jer. 19:2Joṣ 15:8, 12; 2Kr 28:1, 3; Jer 7:31
Jer. 19:42Ọb 22:16, 17; Ais 65:11
Jer. 19:42Kr 33:1, 4
Jer. 19:42Ọb 21:16; Ais 59:7; Jer 2:34; Ida 4:13; Mt 23:34, 35
Jer. 19:52Kr 28:1, 3; 33:1, 6; Ais 57:5
Jer. 19:5Le 18:21; Jer 7:31; 32:35
Jer. 19:6Jer 7:32
Jer. 19:7Di 28:25, 26; Sm 79:2; Jer 7:33; 16:4
Jer. 19:81Ọb 9:8; Jer 18:16; Ida 2:15
Jer. 19:9Le 26:29; Di 28:53; Ida 2:20; 4:10; Isk 5:10
Jer. 19:11Jer 7:32
Jer. 19:13Sm 79:1
Jer. 19:13Jer 8:1, 2; Sef 1:4, 5
Jer. 19:13Jer 7:18; 32:29
Jer. 19:15Ne 9:17, 29; Sek 7:12
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jeremáyà 19:1-15

Jeremáyà

19 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Lọ ra ṣágo* amọ̀ lọ́dọ̀ amọ̀kòkò.+ Mú lára àwọn àgbààgbà àwọn èèyàn náà àti lára àwọn àgbààgbà nínú àwọn àlùfáà, 2 kí o sì jáde lọ sí Àfonífojì Ọmọ Hínómù,+ tó wà ní ibi àtiwọ Ẹnubodè Èéfọ́ Ìkòkò. Ibẹ̀ sì ni kí o ti kéde àwọn ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún ọ. 3 Kí o sọ pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà, ẹ̀yin ọba Júdà àti ẹ̀yin tó ń gbé Jerúsálẹ́mù. Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí:

“‘“Màá tó mú àjálù kan wá bá ibí yìí, etí ẹnikẹ́ni tó bá sì gbọ́ nípa rẹ̀ máa hó yee. 4 Nítorí pé wọ́n ti fi mí sílẹ̀,+ wọ́n sì ti sọ ibí yìí di ibi tí kò ṣeé dá mọ̀.+ Ibẹ̀ ni wọ́n ti ń rú ẹbọ sí àwọn ọlọ́run míì, tí àwọn pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn àti àwọn ọba Júdà kò mọ̀, wọ́n sì ti fi ẹ̀jẹ̀ àwọn aláìṣẹ̀ kún ibí yìí.+ 5 Wọ́n kọ́ àwọn ibi gíga Báálì láti sun àwọn ọmọ wọn nínú iná bí odindi ẹbọ sísun sí Báálì,+ ohun tí mi ò pa láṣẹ tàbí sọ nípa rẹ̀, tí kò sì wá sí mi lọ́kàn rí.”’*+

6 “‘“Nítorí náà, wò ó! ọjọ́ ń bọ̀,” ni Jèhófà wí, “tí a kò ní pe ibí yìí ní Tófétì tàbí Àfonífojì Ọmọ Hínómù mọ́, àmọ́ Àfonífojì Ìpànìyàn la ó máa pè é.+ 7 Màá sọ ohun tí Júdà àti Jerúsálẹ́mù ń gbèrò di asán ní ibí yìí, màá jẹ́ kí àwọn ọ̀tá fi idà pa wọ́n, màá sì jẹ́ kí àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí* wọn rí wọn pa. Màá jẹ́ kí òkú wọn di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀.+ 8 Màá sọ ìlú yìí di ohun àríbẹ̀rù àti ohun àrísúfèé. Gbogbo ẹni tó bá ń gba ibẹ̀ kọjá á wò ó, ẹ̀rù á bà á, á sì súfèé nítorí ìyọnu rẹ̀.+ 9 Màá sì mú kí wọ́n jẹ ẹran ara àwọn ọmọkùnrin wọn àti ti àwọn ọmọbìnrin wọn, kálukú wọn á sì jẹ ẹran ara ọmọnìkejì rẹ̀, nítorí ogun tó dó tì wọ́n àti ìdààmú tó bá wọn nígbà tí àwọn ọ̀tá wọn àti àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí* wọn há wọn mọ́.”’+

10 “Lẹ́yìn náà, fọ́ ṣágo náà mọ́lẹ̀ lójú àwọn ọkùnrin tó tẹ̀ lé ọ lọ, 11 kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí: “Bí màá ṣe fọ́ àwọn èèyàn yìí àti ìlú yìí nìyẹn bí ìgbà tí èèyàn fọ́ ohun tí amọ̀kòkò ṣe mọ́lẹ̀, tí kò fi ní àtúnṣe mọ́. Wọ́n á sì sin òkú ní Tófétì títí kò fi ní sí àyè mọ́ láti sìnkú.”’+

12 “‘Ohun tí màá ṣe sí ibí yìí rèé,’ ni Jèhófà wí, ‘àti sí àwọn tó ń gbé ibẹ̀, láti ṣe ìlú yìí bíi Tófétì. 13 Àwọn ilé Jerúsálẹ́mù àti ilé àwọn ọba Júdà á sì di aláìmọ́ bí ibí yìí, bíi Tófétì,+ àní títí kan gbogbo ilé tí wọ́n ń rú ẹbọ ní òrùlé rẹ̀ sí gbogbo ọmọ ogun ọ̀run,+ tí wọ́n sì ti ń da ọrẹ ohun mímu sí àwọn ọlọ́run míì.’”+

14 Nígbà tí Jeremáyà dé láti Tófétì, níbi tí Jèhófà rán an lọ láti sọ tẹ́lẹ̀, ó dúró ní àgbàlá ilé Jèhófà, ó sì sọ fún gbogbo àwọn èèyàn náà pé: 15 “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí, ‘Wò ó, màá mú gbogbo àjálù tí mo sọ nípa rẹ̀ wá sórí ìlú yìí àti sórí gbogbo ìlú tó yí i ká, nítorí wọ́n ti ya alágídí,* wọn kò sì ṣègbọràn sí ọ̀rọ̀ mi.’”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́