ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nehemáyà 8
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Nehemáyà

      • Wọ́n ka ìwé Òfin, wọ́n sì ṣàlàyé rẹ̀ fáwọn èèyàn (1-12)

      • Wọ́n ṣe Àjọyọ̀ Àtíbàbà (13-18)

Nehemáyà 8:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “akọ̀wé òfin.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 3:26; 12:37
  • +Ẹsr 7:6
  • +Di 31:9; Joṣ 1:8
  • +Le 27:34

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ìwé Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́,

    2/2016, ojú ìwé 3

Nehemáyà 8:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìjọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:24; 1Ọb 8:2
  • +Di 31:12; 2Kr 17:8, 9; Mal 2:7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/1998, ojú ìwé 20

Nehemáyà 8:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Iṣe 13:15; 15:21
  • +Iṣe 16:14; 17:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 21-22

Nehemáyà 8:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “akọ̀wé òfin.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 12:40, 42

Nehemáyà 8:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Bẹ́ẹ̀ ni kí ó rí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 27:26

Nehemáyà 8:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 9:4
  • +Ẹsr 8:33; Ne 11:16
  • +Di 33:8, 10

Nehemáyà 8:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Lk 24:27; Iṣe 8:30, 31

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!, ẹ̀kọ́ 10

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2006, ojú ìwé 11

    5/15/1996, ojú ìwé 16

Nehemáyà 8:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Tíṣátà,” orúkọ oyè tí àwọn ará Páṣíà fún gómìnà ìpínlẹ̀.

  • *

    Tàbí “akọ̀wé òfin.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 7:11
  • +Le 23:24

Nehemáyà 8:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ohun tó lọ́ràá.”

  • *

    Tàbí “agbára.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹst 9:19

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 22

    12/15/2008, ojú ìwé 32

    10/15/1998, ojú ìwé 20

    1/15/1995, ojú ìwé 11

    9/1/1994, ojú ìwé 13-14

    3/15/1992, ojú ìwé 19

Nehemáyà 8:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 126:1-3
  • +Ne 8:8

Nehemáyà 8:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “akọ̀wé òfin.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/1998, ojú ìwé 20-21

Nehemáyà 8:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:34, 42; Di 16:13, 16; Jo 7:2

Nehemáyà 8:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:4

Nehemáyà 8:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 6:36; 7:12; 2Kr 4:9; 20:5
  • +Ne 3:26; 8:1, 3
  • +2Ọb 14:13; Ne 12:38, 39

Nehemáyà 8:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìjọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 1:1
  • +Di 16:14, 15

Nehemáyà 8:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:10-12
  • +Le 23:34, 36

Àwọn míì

Neh. 8:1Ne 3:26; 12:37
Neh. 8:1Ẹsr 7:6
Neh. 8:1Di 31:9; Joṣ 1:8
Neh. 8:1Le 27:34
Neh. 8:2Le 23:24; 1Ọb 8:2
Neh. 8:2Di 31:12; 2Kr 17:8, 9; Mal 2:7
Neh. 8:3Iṣe 13:15; 15:21
Neh. 8:3Iṣe 16:14; 17:11
Neh. 8:4Ne 12:40, 42
Neh. 8:6Di 27:26
Neh. 8:7Ne 9:4
Neh. 8:7Ẹsr 8:33; Ne 11:16
Neh. 8:7Di 33:8, 10
Neh. 8:8Lk 24:27; Iṣe 8:30, 31
Neh. 8:9Ẹsr 7:11
Neh. 8:9Le 23:24
Neh. 8:10Ẹst 9:19
Neh. 8:12Sm 126:1-3
Neh. 8:12Ne 8:8
Neh. 8:14Le 23:34, 42; Di 16:13, 16; Jo 7:2
Neh. 8:15Le 23:4
Neh. 8:161Ọb 6:36; 7:12; 2Kr 4:9; 20:5
Neh. 8:16Ne 3:26; 8:1, 3
Neh. 8:162Ọb 14:13; Ne 12:38, 39
Neh. 8:17Joṣ 1:1
Neh. 8:17Di 16:14, 15
Neh. 8:18Di 31:10-12
Neh. 8:18Le 23:34, 36
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Nehemáyà 8:1-18

Nehemáyà

8 Gbogbo àwọn èèyàn náà kóra jọ ní ìṣọ̀kan sí gbàgede ìlú tó wà níwájú Ẹnubodè Omi,+ wọ́n sì sọ fún Ẹ́sírà+ adàwékọ* pé kó mú ìwé Òfin Mósè+ wá, èyí tí Jèhófà pa láṣẹ fún Ísírẹ́lì.+ 2 Torí náà, ní ọjọ́ kìíní oṣù keje,+ àlùfáà Ẹ́sírà mú ìwé Òfin náà wá síwájú àpéjọ*+ àwọn ọkùnrin àti àwọn obìnrin pẹ̀lú gbogbo àwọn tó lè lóye ohun tí wọ́n bá gbọ́. 3 Ó sì kà á sókè+ ní gbàgede ìlú tó wà níwájú Ẹnubodè Omi, láti àfẹ̀mọ́jú títí di ọ̀sán gangan, fún àwọn ọkùnrin àti àwọn obìnrin àti gbogbo àwọn tí ọ̀rọ̀ náà lè yé; gbogbo àwọn èèyàn náà sì fetí sílẹ̀ dáadáa+ sí ìwé Òfin náà. 4 Ẹ́sírà adàwékọ* dúró lórí pèpéle onígi tí wọ́n ṣe fún àpéjọ náà; àwọn tó dúró sápá ọ̀tún rẹ̀ ni Matitáyà, Ṣímà, Ánáyà, Ùráyà, Hilikáyà àti Maaseáyà; àwọn tó sì wà lápá òsì rẹ̀ ni Pedáyà, Míṣáẹ́lì, Málíkíjà,+ Háṣúmù, Haṣi-bádánà, Sekaráyà àti Méṣúlámù.

5 Ẹ́sírà ṣí ìwé náà lójú gbogbo èèyàn, nítorí ó yọ sókè ju gbogbo wọn lọ. Bí ó sì ṣe ṣí i, gbogbo àwọn èèyàn náà dìde. 6 Nígbà náà, Ẹ́sírà yin Jèhófà Ọlọ́run tòótọ́, Ẹni ńlá, gbogbo àwọn èèyàn náà sọ pé, “Àmín!* Àmín!”+ wọ́n sì gbé ọwọ́ wọn sókè. Wọ́n tẹrí ba, wọ́n wólẹ̀, wọ́n sì dojú bolẹ̀ fún Jèhófà. 7 Jéṣúà, Bánì, Ṣerebáyà,+ Jámínì, Ákúbù, Ṣábétáì, Hodáyà, Maaseáyà, Kélítà, Asaráyà, Jósábádì,+ Hánánì àti Pẹláyà, tí wọ́n jẹ́ ọmọ Léfì, ń ṣàlàyé Òfin náà fún àwọn èèyàn náà,+ orí ìdúró sì ni àwọn èèyàn náà wà. 8 Wọ́n ń ka ìwé náà sókè nìṣó látinú Òfin Ọlọ́run tòótọ́, wọ́n ń ṣàlàyé rẹ̀ lọ́nà tó ṣe kedere, wọ́n sì ń túmọ̀ rẹ̀; torí náà, wọ́n jẹ́ kí àwọn èèyàn náà lóye ohun tí wọ́n kà.+

9 Nehemáyà tó jẹ́ gómìnà* nígbà yẹn, Ẹ́sírà + tó jẹ́ àlùfáà àti adàwékọ* pẹ̀lú àwọn ọmọ Léfì tí wọ́n ń kọ́ àwọn èèyàn sọ fún gbogbo àwọn èèyàn náà pé: “Ọjọ́ yìí jẹ́ mímọ́ lójú Jèhófà Ọlọ́run yín.+ Ẹ má ṣọ̀fọ̀, ẹ má sì sunkún.” Nítorí gbogbo àwọn èèyàn náà ń sunkún bí wọ́n ṣe gbọ́ ọ̀rọ̀ inú Òfin náà. 10 Ó sọ fún wọn pé: “Ẹ lọ, ẹ jẹ àwọn ohun tó dọ́ṣọ̀,* ẹ mu àwọn ohun dídùn, kí ẹ sì fi oúnjẹ ránṣẹ́+ sí àwọn tí kò ní nǹkan kan; nítorí ọjọ́ yìí jẹ́ mímọ́ lójú Olúwa wa, ẹ má sì banú jẹ́, nítorí ìdùnnú Jèhófà ni ibi ààbò* yín.” 11 Àwọn ọmọ Léfì sì ń fi gbogbo àwọn èèyàn náà lọ́kàn balẹ̀ pé: “Ẹ dákẹ́! nítorí ọjọ́ yìí jẹ́ mímọ́; ẹ má sì banú jẹ́.” 12 Torí náà, gbogbo àwọn èèyàn náà lọ, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu, wọ́n fi oúnjẹ ránṣẹ́ sí àwọn míì, inú wọn sì ń dùn gan-an,+ nítorí ọ̀rọ̀ tí wọ́n gbọ́ yé wọn.+

13 Ní ọjọ́ kejì, àwọn olórí agbo ilé gbogbo àwọn èèyàn náà, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì kóra jọ sọ́dọ̀ Ẹ́sírà adàwékọ,* kí wọ́n lè túbọ̀ lóye àwọn ọ̀rọ̀ inú Òfin náà. 14 Wọ́n wá rí i nínú Òfin pé Jèhófà pàṣẹ nípasẹ̀ Mósè pé inú àtíbàbà ni kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa gbé nígbà àjọyọ̀ ní oṣù keje+ 15 àti pé kí wọ́n polongo,+ kí wọ́n sì kéde káàkiri gbogbo ìlú wọn àti ní gbogbo Jerúsálẹ́mù pé: “Ẹ lọ sí àwọn agbègbè olókè, kí ẹ sì mú ẹ̀ka eléwé igi ólífì, ti igi ahóyaya, ti igi mátílì àti imọ̀ ọ̀pẹ pẹ̀lú ẹ̀ka àwọn igi míì tó léwé dáadáa wá láti fi wọ́n ṣe àtíbàbà, gẹ́gẹ́ bó ṣe wà lákọsílẹ̀.”

16 Ni àwọn èèyàn náà bá jáde lọ, wọ́n sì kó wọn wá láti fi wọ́n ṣe àtíbàbà fún ara wọn, kálukú sórí òrùlé rẹ̀ àti sí àgbàlá wọn àti àgbàlá ilé Ọlọ́run tòótọ́,+ bákan náà, wọ́n ṣe é sí gbàgede ìlú ní Ẹnubodè Omi+ àti gbàgede ìlú tó wà ní Ẹnubodè Éfúrémù.+ 17 Bí gbogbo àwùjọ* àwọn tó dé láti ìgbèkùn ṣe ṣe àwọn àtíbàbà nìyẹn, wọ́n sì ń gbé inú àwọn àtíbàbà náà, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò tíì ṣe é báyìí rí láti ìgbà ayé Jóṣúà+ ọmọ Núnì títí di ọjọ́ yẹn, ìdí nìyẹn tí ìdùnnú fi ṣubú layọ̀ láàárín wọn.+ 18 Ojoojúmọ́ ni wọ́n ń ka ìwé Òfin Ọlọ́run tòótọ́,+ láti ọjọ́ àkọ́kọ́ títí di ọjọ́ tó kẹ́yìn. Wọ́n sì fi ọjọ́ méje ṣe àjọyọ̀ náà, ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n ṣe àpéjọ ọlọ́wọ̀, gẹ́gẹ́ bí òfin ṣe sọ.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́