Àwọn Onídàájọ́
3 Èyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Jèhófà fi sílẹ̀, láti dán gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wò, àwọn tí ogun kankan ò ṣẹlẹ̀ lójú wọn rí ní Kénáánì+ 2 (torí kí ìran àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó kàn lè mọ bí ogun ṣe rí, àwọn tí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ò ṣẹlẹ̀ sí rí): 3 àwọn alákòóso Filísínì+ márààrún àti gbogbo àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn ọmọ Sídónì+ àti àwọn Hífì+ tó ń gbé Òkè Lẹ́bánónì+ láti Òkè Baali-hámónì títí dé Lebo-hámátì.*+ 4 Àwọn la fi dán Ísírẹ́lì wò, láti mọ̀ bóyá Ísírẹ́lì á máa tẹ̀ lé àṣẹ Jèhófà tó fún àwọn bàbá wọn nípasẹ̀ Mósè.+ 5 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wá ń gbé láàárín àwọn ọmọ Kénáánì,+ àwọn ọmọ Hétì, àwọn Ámórì, àwọn Pérísì, àwọn Hífì àti àwọn ará Jébúsì. 6 Wọ́n ń fi àwọn ọmọbìnrin wọn ṣe aya, wọ́n sì ń fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní àwọn ọmọbìnrin tiwọn, wọ́n tún ń sin àwọn ọlọ́run wọn.+
7 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà, wọ́n gbàgbé Jèhófà Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin àwọn Báálì+ àti àwọn òpó òrìṣà.*+ 8 Ni Jèhófà bá bínú gidigidi sí Ísírẹ́lì, ó sì fi wọ́n lé Kuṣani-ríṣátáímù ọba Mesopotámíà* lọ́wọ́. Ọdún mẹ́jọ ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi sin Kuṣani-ríṣátáímù. 9 Nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ké pe Jèhófà pé kó ran àwọn lọ́wọ́,+ Jèhófà yan ẹnì kan tó máa gba àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀,+ ìyẹn Ótíníẹ́lì+ ọmọ Kénásì, àbúrò Kélẹ́bù. 10 Ẹ̀mí Jèhófà bà lé e,+ ó sì di onídàájọ́ Ísírẹ́lì. Nígbà tó lọ jagun, Jèhófà fi Kuṣani-ríṣátáímù ọba Mesopotámíà* lé e lọ́wọ́, ó sì ṣẹ́gun Kuṣani-ríṣátáímù. 11 Àlàáfíà wá wà ní ilẹ̀ náà* fún ogójì (40) ọdún. Lẹ́yìn náà, Ótíníẹ́lì ọmọ Kénásì wá kú.
12 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tún bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà.+ Torí náà, Jèhófà jẹ́ kí Ẹ́gílónì ọba Móábù+ lágbára lórí Ísírẹ́lì, torí wọ́n ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà. 13 Bákan náà, ó kó àwọn ọmọ Ámónì+ àti àwọn ọmọ Ámálékì+ lọ bá wọn jà. Wọ́n gbéjà ko Ísírẹ́lì, wọ́n sì gba ìlú ọlọ́pẹ.+ 14 Ọdún méjìdínlógún (18)+ ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi sin Ẹ́gílónì ọba Móábù. 15 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wá ké pe Jèhófà pé kó ran àwọn lọ́wọ́,+ torí náà, Jèhófà yan ẹnì kan tó máa gbà wọ́n sílẹ̀,+ ìyẹn Éhúdù+ ọmọ Gérà, ọmọ Bẹ́ńjámínì,+ ọkùnrin tó ń lo ọwọ́ òsì.+ Nígbà tó yá, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ìṣákọ́lẹ̀* rán an sí Ẹ́gílónì ọba Móábù. 16 Àmọ́ Éhúdù ti ṣe idà olójú méjì kan fún ara rẹ̀, gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́* kan, ó sì dè é mọ́ itan rẹ̀ ọ̀tún lábẹ́ aṣọ rẹ̀. 17 Ó wá fún Ẹ́gílónì ọba Móábù ní ìṣákọ́lẹ̀ náà. Ẹ́gílónì sanra gan-an.
18 Nígbà tí Éhúdù fi ìṣákọ́lẹ̀ náà jíṣẹ́ tán, ó ní kí àwọn tó gbé ìṣákọ́lẹ̀ náà máa lọ. 19 Àmọ́ nígbà tí wọ́n dé ibi àwọn ère gbígbẹ́* ní Gílígálì,+ òun nìkan pa dà, ó sì sọ pé: “Ọ̀rọ̀ àṣírí kan wà tí mo fẹ́ sọ fún ọ, ìwọ ọba.” Ọba wá sọ pé: “Ẹ dákẹ́!” Ni gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀. 20 Torí náà, Éhúdù lọ bá a níbi tó dá jókòó sí nínú yàrá tó tura lórí òrùlé rẹ̀. Éhúdù wá sọ pé: “Ọlọ́run rán mi sí ọ.” Ó wá dìde lórí ìtẹ́* rẹ̀. 21 Ni Éhúdù bá fi ọwọ́ òsì rẹ̀ fa idà náà yọ ní itan rẹ̀ ọ̀tún, ó sì fi gún un ní ikùn. 22 Idà náà wọlé tòun ti èèkù rẹ̀, ọ̀rá sì bo idà náà torí kò fa idà náà yọ ní ikùn rẹ̀, ìgbẹ́ sì tú jáde. 23 Éhúdù wá gba ibi àbáwọlé* jáde, ó pa ilẹ̀kùn yàrá orí òrùlé náà dé nígbà tó jáde, ó sì tì í pa. 24 Lẹ́yìn tó lọ, àwọn ìránṣẹ́ pa dà wá, wọ́n sì rí i pé ilẹ̀kùn yàrá orí òrùlé náà wà ní títì pa. Torí náà, wọ́n sọ pé: “Bóyá ó ń tura* nínú yàrá tó tura nínú lọ́hùn-ún.” 25 Wọ́n wá dúró títí ó fi sú wọn, àmọ́ nígbà tí wọ́n rí i pé síbẹ̀, kò ṣí ilẹ̀kùn yàrá orí òrùlé náà, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí i, ni wọ́n bá rí òkú ọ̀gá wọn nílẹ̀!
26 Ní gbogbo ìgbà tí wọ́n fi ń dúró, Éhúdù ti sá lọ, ó kọjá ibi àwọn ère gbígbẹ́,*+ ó sì dé Séírà láìséwu. 27 Nígbà tó débẹ̀, ó fun ìwo+ ní agbègbè olókè Éfúrémù;+ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì sọ̀ kalẹ̀ kúrò ní agbègbè olókè náà, òun ló ṣáájú wọn. 28 Ó wá sọ fún wọn pé: “Ẹ tẹ̀ lé mi, torí Jèhófà ti fi àwọn ọ̀tá yín, àwọn ọmọ Móábù, lé yín lọ́wọ́.” Torí náà, wọ́n tẹ̀ lé e, wọ́n sì gba ibi tó ṣeé fẹsẹ̀ gbà kọjá ní odò Jọ́dánì mọ́ àwọn ọmọ Móábù lọ́wọ́, wọn ò sì jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá. 29 Nígbà yẹn, wọ́n pa nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) àwọn ọmọ Móábù,+ alágbára ni gbogbo wọn, wọ́n sì lákíkanjú; àmọ́ ìkankan nínú wọn ò yè bọ́.+ 30 Ọjọ́ yẹn ni Ísírẹ́lì ṣẹ́gun Móábù; àlàáfíà wá wà ní ilẹ̀ náà* fún ọgọ́rin (80) ọdún.+
31 Lẹ́yìn Éhúdù ni Ṣámúgárì+ ọmọ Ánátì, tó fi ọ̀pá tí wọ́n fi ń da màlúù+ pa ọgọ́rùn-ún mẹ́fà (600) ọkùnrin Filísínì;+ òun náà gba Ísírẹ́lì sílẹ̀.