ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 6/96 ojú ìwé 2
  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Rí Ẹni Tí Yóò Fetí Sílẹ̀?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Rí Ẹni Tí Yóò Fetí Sílẹ̀?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bá A Ṣe Lè Dẹni Tó Lẹ́bùn Fífarabalẹ̀ Títẹ́tí Síni
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Lìdíà—Aláájò Àlejò Olùjọ́sìn Ọlọ́run
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
  • Àwòkọ́ṣe—Lìdíà
    Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Àwọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá Kejì
  • Máa Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Jésù Tó Jẹ́ Ọ̀gá Nínú Iṣẹ́ Sísọni Dọmọ Ẹ̀yìn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
km 6/96 ojú ìwé 2

Báwo Ni Mo Ṣe Lè Rí Ẹni Tí Yóò Fetí Sílẹ̀?

1 Ní ìlú Fílípì, “obìnrin kan báyìí tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Lìdíà, ẹni tí ń ta ohun aláwọ̀ àlùkò, . . . ń fetísílẹ̀, Jèhófà sì ṣí ọkàn-àyà rẹ̀ sílẹ̀ gbayawu láti fiyè sí àwọn ohun tí Pọ́ọ̀lù ń sọ.” (Ìṣe 16:14) Kí ni ìròyìn ìṣẹ̀lẹ̀ yìí fi kọ́ wa? Fífetí sílẹ̀ ni ó ń ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún ẹnì kan láti kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́. Àṣeyọrí wa nínú ṣíṣàjọpín ìhìn iṣẹ́ Ìjọba náà sinmi ní pàtàkì lórí ìmúratán onílé láti fetí sílẹ̀. Gbàrà tí a bá ti rí ẹni tẹ́tí sílẹ̀, ó túbọ̀ ń rọrùn láti sọ ìhìn iṣẹ́ wa. Ṣùgbọ́n rírí ẹni fetí sílẹ̀ lè jẹ́ ìpèníjà kan. Kí ni a lè ṣe?

2 Ṣáájú nínípìn-ín nínú iṣẹ́ ìsìn, ó yẹ kí á fún ìrísí wa àti àwọn irin iṣẹ́ tí a óò lò ní àfiyèsí. Èé ṣe? Àwọn ènìyàn túbọ̀ ní ìtẹ̀sí láti fetí sílẹ̀ sí ẹnì kan tí ó fi ara rẹ̀ hàn pẹ̀lú iyì. A ha múra lọ́nà tí ó fani mọ́ra, síbẹ̀ tí ó wà ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì bí? Bí ìmúra wúruwùru tilẹ̀ lè gbajúmọ̀ nínú ayé, a ń yẹra fún irú àìbìkítà bẹ́ẹ̀ nítorí pé a jẹ́ òjíṣẹ́ tí ń ṣojú fún Ìjọba Ọlọ́run. Ìrísí wa tí ó mọ́ tónítóní, tí ó sì jẹ́ ti afínjú, ń fi ẹ̀rí rere kún ìhìn iṣẹ́ Ìjọba tí à ń wàásù rẹ̀.

3 Jẹ́ Ẹni Tí Ń Yá Mọ́ni Kí O Sì Fi Ọ̀wọ̀ Hàn: Láìka ìṣarasíhùwà tí ń yí padà lónìí sí, ọ̀pọ̀ ènìyàn ṣì ní ọ̀wọ̀ fún Bíbélì, wọn yóò sì dáhùn padà lọ́nà rere sí ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ tí ó ní ọ̀wọ̀, tí ó sì jẹ́ ti ọlọ́rẹ̀ẹ́sọ́rẹ̀ẹ́, nípa ohun tí ó wà nínú Bíbélì. Ẹ̀rín músẹ́ ọlọ́yàyà, tí ó sì jẹ́ àtọkànwá, lè mú ara tu onílé, kí ó sì ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún ìjíròrò tí ó gbádùn mọ́ni. Òtítọ́ inú àti ìwà rere wa tún yẹ kí ó fara hàn nínú ìsọ̀rọ̀ wa àti ìwà wa, èyí tí ó kan fífetí sílẹ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ sí àwọn ìlóhùnsí onílé.

4 Ète wá jẹ́ láti ṣàjọpín ìrètí Bíbélì pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn. Pẹ̀lú èyí lọ́kàn, ó yẹ kí á rí i dájú pé ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ wa ń fani lọ́kàn mọ́ra, kì í ṣe èyí tí ń ṣàtakò tàbí peni níjà. Kò sí ìdí láti fi àkókò ṣòfò ní jíjiyàn pẹ̀lú ẹni tí ó hàn kedere pé ó ń ṣàtakò ni. (2 Tim. 2:23-25) A lè yàn láti inú onírúurú àwọn ìgbékalẹ̀ tí ń fúnni níṣìírí, tí ó sì bá ìgbà mu, tí a pèsè fún wa nínú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa àti ìwé Reasoning. Àmọ́ ṣáá o, a ní láti múra ìwọ̀nyí sílẹ̀ dáradára, kí a baà lè sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ìtara, àti lọ́nà tí ń yíni lérò padà.—1 Pet. 3:15.

5 Lẹ́yìn ìkésíni wa, díẹ̀ nínú àwọn onílé ni ó lè rántí gbogbo ohun tí a sọ. Bí ó ti wù kí ó rí, ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo wọn ni ó lè rántí ọ̀nà tí a gbà sọ ọ́. A kò gbọdọ̀ fojú tín-ínrín agbára tí ìwà rere àti inú rere ní láé. Dájúdájú, àwọn ẹni-bí-àgùntàn kún inú ìpínlẹ̀ wa, tí wọn yóò fetí sílẹ̀ sí òtítọ́ gan-an gẹ́gẹ́ bí Lìdíà ti ṣe ní ọ̀rúndún kìíní. Fífún ìrísí wa àti ọ̀nà tí a ń gbà sọ̀rọ̀ ní àfiyèsí kínníkínní, lè fún àwọn olóòótọ́ inú níṣìírí láti fetí sílẹ̀ sí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, kí wọ́n sì tẹ́wọ́ gbà á lọ́nà rere.—Mak. 4:20.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́